Friday, August 29
Mo ti jẹ́ kí wọ́n mọ orúkọ rẹ.—Jòh. 17:26.
Jésù ò kàn sọ fáwọn èèyàn pé Jèhófà ni orúkọ Ọlọ́run torí pé àwọn Júù tí Jésù ń kọ́ ti mọ orúkọ Ọlọ́run tẹ́lẹ̀. Àmọ́ Jésù ni “ẹni tó ṣàlàyé” ẹni tí Jèhófà jẹ́ lọ́nà tó dáa jù. (Jòh. 1:17, 18) Bí àpẹẹrẹ, Ìwé Mímọ́ Lédè Hébérù jẹ́ ká mọ̀ pé Jèhófà jẹ́ aláàánú, ó sì máa ń gba tẹni rò. (Ẹ́kís. 34:5-7) Jésù jẹ́ kí ọ̀rọ̀ yìí yé wa dáadáa nígbà tó sọ àpèjúwe ọmọ onínàákúnàá àti bàbá ẹ̀. Àpèjúwe yìí jẹ́ ká mọ̀ pé Jèhófà jẹ́ aláàánú, ó sì ń gba tẹni rò. Nígbà tí bàbá yìí rí ọmọ ẹ̀ tó ti ronú pìwà dà tó “ń bọ̀ ní òkèèrè,” ó sáré lọ pàdé ẹ̀, ó dì mọ́ ọn, ó sì dárí jì í tọkàntọkàn. (Lúùkù 15:11-32) Torí náà, Jésù ló jẹ́ ká mọ irú ẹni tí Jèhófà jẹ́ gan-an. w24.02 10 ¶8-9
Saturday, August 30
Fi ìtùnú tí a gbà lọ́dọ̀ rẹ̀ tu àwọn míì nínú.—2 Kọ́r. 1:4.
Jèhófà máa ń tu àwọn tó níṣòro nínú, kára lè tù wọ́n. Báwo la ṣe lè fara wé Jèhófà bó ṣe ń ṣàánú àwọn èèyàn, tó sì ń tù wọ́n nínú? Ọ̀nà kan tá a lè gbà ṣe bẹ́ẹ̀ ni pé ká láwọn ànímọ́ táá jẹ́ ká máa tu àwọn èèyàn nínú. Kí ni díẹ̀ lára àwọn ànímọ́ náà? Kí lá jẹ́ ká máa fìfẹ́ hàn, ká sì ‘máa tu ara wa nínú’ lójoojúmọ́? (1 Tẹs. 4:18) Ohun táá jẹ́ ká lè ṣe bẹ́ẹ̀ ni pé ká máa bára wa kẹ́dùn, ká ní ìfẹ́ ará àti inú rere. (Kól. 3:12; 1 Pét. 3:8) Báwo làwọn ànímọ́ yìí ṣe máa ràn wá lọ́wọ́? Tá a bá lójú àánú, tá a sì tún láwọn ànímọ́ tá a ṣẹ̀ṣẹ̀ sọ yìí, kò sí bá ò ṣe ní máa tu àwọn tó níṣòro nínú. Jésù sọ pé “ọ̀pọ̀ nǹkan tó wà nínú ọkàn ni ẹnu ń sọ. Ẹni rere máa ń mú ohun rere jáde látinú ìṣúra rere rẹ̀.” (Mát. 12:34, 35) Torí náà, ọ̀nà pàtàkì tá a lè gbà fi hàn pé a nífẹ̀ẹ́ àwọn arákùnrin àtàwọn arábìnrin wa ni pé ká máa tù wọ́n nínú. w23.11 10 ¶10-11
Sunday, August 31
Àwọn tó ní ìjìnlẹ̀ òye máa lóye.—Dán. 12:10.
Ká tó lè lóye àsọtẹ́lẹ̀ Bíbélì, àfi kí ẹnì kan ràn wá lọ́wọ́. Ẹ jẹ́ ká wo àpèjúwe yìí ná. Ká sọ pé o fẹ́ lọ síbì kan tó ò mọ̀, àmọ́ ọ̀rẹ́ ẹ kan tó mọ ibẹ̀ dáadáa tẹ̀ lé ẹ lọ. Bẹ́ ẹ ṣe ń lọ, ó mọ ibi tẹ́ ẹ dé, ó sì mọ ibi tí ọ̀nà kọ̀ọ̀kan já sí. Ó dájú pé inú ẹ á dùn pé ọ̀rẹ́ ẹ bá ẹ lọ. Jèhófà ló dà bí ọ̀rẹ́ yẹn torí ó mọ ibi tí ọ̀rọ̀ ayé yìí dé àtohun tó máa ṣẹlẹ̀ lọ́jọ́ iwájú. Torí náà, ká lè lóye àsọtẹ́lẹ̀ Bíbélì, ó yẹ ká fìrẹ̀lẹ̀ bẹ Jèhófà pé kó ràn wá lọ́wọ́. (Dán. 2:28; 2 Pét. 1:19, 20) Bíi ti òbí rere kan, Jèhófà fẹ́ kí ọjọ́ ọ̀la àwọn ọmọ òun dáa. (Jer. 29:11) Àmọ́ Jèhófà yàtọ̀ sáwọn òbí wa torí pé òun lè sọ ohun tó máa ṣẹlẹ̀ lọ́jọ́ iwájú, táá sì rí bẹ́ẹ̀ gẹ́lẹ́. Ó ní kí wọ́n kọ àwọn àsọtẹ́lẹ̀ sínú Bíbélì ká lè mọ àwọn ìṣẹ̀lẹ̀ pàtàkì kí wọ́n tó ṣẹlẹ̀.—Àìsá. 46:10. w23.08 8-9 ¶3-4