ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
Yorùbá Publications (1987-2025)
Jáde
Wọlé
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Ẹ Káàbọ̀.
Ìkànnì yìí wà fún ṣíṣe ìwádìí látinú àwọn ìwé tí àwa Ẹlẹ́rìí Jèhófà ṣe ní oríṣiríṣi èdè.
Bí o bá fẹ́ wa ìwé jáde, jọ̀wọ́ lọ sí jw.org.
  • Òní

Saturday, August 30

Fi ìtùnú tí a gbà lọ́dọ̀ rẹ̀ tu àwọn míì nínú.—2 Kọ́r. 1:4.

Jèhófà máa ń tu àwọn tó níṣòro nínú, kára lè tù wọ́n. Báwo la ṣe lè fara wé Jèhófà bó ṣe ń ṣàánú àwọn èèyàn, tó sì ń tù wọ́n nínú? Ọ̀nà kan tá a lè gbà ṣe bẹ́ẹ̀ ni pé ká láwọn ànímọ́ táá jẹ́ ká máa tu àwọn èèyàn nínú. Kí ni díẹ̀ lára àwọn ànímọ́ náà? Kí lá jẹ́ ká máa fìfẹ́ hàn, ká sì ‘máa tu ara wa nínú’ lójoojúmọ́? (1 Tẹs. 4:18) Ohun táá jẹ́ ká lè ṣe bẹ́ẹ̀ ni pé ká máa bára wa kẹ́dùn, ká ní ìfẹ́ ará àti inú rere. (Kól. 3:12; 1 Pét. 3:8) Báwo làwọn ànímọ́ yìí ṣe máa ràn wá lọ́wọ́? Tá a bá lójú àánú, tá a sì tún láwọn ànímọ́ tá a ṣẹ̀ṣẹ̀ sọ yìí, kò sí bá ò ṣe ní máa tu àwọn tó níṣòro nínú. Jésù sọ pé “ọ̀pọ̀ nǹkan tó wà nínú ọkàn ni ẹnu ń sọ. Ẹni rere máa ń mú ohun rere jáde látinú ìṣúra rere rẹ̀.” (Mát. 12:​34, 35) Torí náà, ọ̀nà pàtàkì tá a lè gbà fi hàn pé a nífẹ̀ẹ́ àwọn arákùnrin àtàwọn arábìnrin wa ni pé ká máa tù wọ́n nínú. w23.11 10 ¶10-11

Máa Ṣàyẹ̀wò Ìwé Mímọ́ Lójoojúmọ́—2025

Sunday, August 31

Àwọn tó ní ìjìnlẹ̀ òye máa lóye.—Dán. 12:10.

Ká tó lè lóye àsọtẹ́lẹ̀ Bíbélì, àfi kí ẹnì kan ràn wá lọ́wọ́. Ẹ jẹ́ ká wo àpèjúwe yìí ná. Ká sọ pé o fẹ́ lọ síbì kan tó ò mọ̀, àmọ́ ọ̀rẹ́ ẹ kan tó mọ ibẹ̀ dáadáa tẹ̀ lé ẹ lọ. Bẹ́ ẹ ṣe ń lọ, ó mọ ibi tẹ́ ẹ dé, ó sì mọ ibi tí ọ̀nà kọ̀ọ̀kan já sí. Ó dájú pé inú ẹ á dùn pé ọ̀rẹ́ ẹ bá ẹ lọ. Jèhófà ló dà bí ọ̀rẹ́ yẹn torí ó mọ ibi tí ọ̀rọ̀ ayé yìí dé àtohun tó máa ṣẹlẹ̀ lọ́jọ́ iwájú. Torí náà, ká lè lóye àsọtẹ́lẹ̀ Bíbélì, ó yẹ ká fìrẹ̀lẹ̀ bẹ Jèhófà pé kó ràn wá lọ́wọ́. (Dán. 2:28; 2 Pét. 1:​19, 20) Bíi ti òbí rere kan, Jèhófà fẹ́ kí ọjọ́ ọ̀la àwọn ọmọ òun dáa. (Jer. 29:11) Àmọ́ Jèhófà yàtọ̀ sáwọn òbí wa torí pé òun lè sọ ohun tó máa ṣẹlẹ̀ lọ́jọ́ iwájú, táá sì rí bẹ́ẹ̀ gẹ́lẹ́. Ó ní kí wọ́n kọ àwọn àsọtẹ́lẹ̀ sínú Bíbélì ká lè mọ àwọn ìṣẹ̀lẹ̀ pàtàkì kí wọ́n tó ṣẹlẹ̀.—Àìsá. 46:10. w23.08 8-9 ¶3-4

Máa Ṣàyẹ̀wò Ìwé Mímọ́ Lójoojúmọ́—2025

Monday, September 1

Ojúmọ́ kan máa mọ́ wa láti ibi gíga.—Lúùkù 1:78.

Ọlọ́run fún Jésù lágbára láti yanjú ìṣòro aráyé. Àwọn iṣẹ́ ìyanu tí Jésù ṣe fi hàn pé ó lágbára láti yanjú àwọn ìṣòro tá ò lè yanjú fúnra wa. Bí àpẹẹrẹ, ó lágbára láti gbà wá lọ́wọ́ ẹ̀ṣẹ̀ tá a jogún àtàwọn nǹkan tí ẹ̀ṣẹ̀ náà fà irú bí àìsàn àti ikú. (Mát. 9:​1-6; Róòmù 5:​12, 18, 19) Àwọn iṣẹ́ ìyanu tó ṣe fi hàn pé ó lè wo “onírúurú” àìsàn, ó sì lè jí òkú dìde. (Mát. 4:23; Jòh. 11:​43, 44) Bákan náà, ó lágbára láti dáwọ́ ìjì líle dúró, ó sì lágbára láti gba àwọn èèyàn sílẹ̀ lọ́wọ́ ẹ̀mí burúkú. (Máàkù 4:​37-39; Lúùkù 8:2) Àwọn nǹkan yìí jẹ́ kó dá wa lójú pé Jèhófà ti fún Ọmọ ẹ̀ lágbára láti yanjú àwọn ìṣòro wa! Ó dá wa lójú háún-háún pé Ọlọ́run máa ṣe àwọn ohun rere tó ṣèlérí nínú Ìjọba rẹ̀. Àwọn iṣẹ́ ìyanu tí Jésù ṣe jẹ́ ká mọ̀ pé tó bá bẹ̀rẹ̀ sí í ṣàkóso ayé, ó máa ṣe jù bẹ́ẹ̀ lọ torí pé òun ni Ọba Ìjọba Ọlọ́run. w23.04 3 ¶5-7

Máa Ṣàyẹ̀wò Ìwé Mímọ́ Lójoojúmọ́—2025
Ẹ Káàbọ̀.
Ìkànnì yìí wà fún ṣíṣe ìwádìí látinú àwọn ìwé tí àwa Ẹlẹ́rìí Jèhófà ṣe ní oríṣiríṣi èdè.
Bí o bá fẹ́ wa ìwé jáde, jọ̀wọ́ lọ sí jw.org.
  • Yorùbá
  • Fi Ráńṣẹ́
  • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
  • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
  • Àdéhùn Nípa Lílò
  • Òfin
  • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
  • JW.ORG
  • Wọlé
Fi Ráńṣẹ́