Wednesday, September 3
Jósẹ́fù . . . ṣe ohun tí áńgẹ́lì Jèhófà ní kó ṣe, ó mú ìyàwó rẹ̀ lọ sílé.—Mát. 1:24.
Ìgbà gbogbo ni Jósẹ́fù máa ń fi ìmọ̀ràn Jèhófà sílò, ìyẹn ló sì mú kó jẹ́ ọkọ rere. Ó kéré tán, ẹ̀ẹ̀mẹta ọ̀tọ̀ọ̀tọ̀ ni Jèhófà sọ ohun tó máa ṣe nípa ìdílé ẹ̀ fún un. Ẹsẹ̀kẹsẹ̀ ló sì máa ń gbé ìgbésẹ̀ kódà nígbà tó ní láti ṣe àwọn àyípadà tó le gan-an. (Mát. 1:20; 2:13-15, 19-21) Torí pé Jósẹ́fù ṣe ohun tí Jèhófà sọ, ó dáàbò bo Màríà, ó ràn án lọ́wọ́, ó sì pèsè àwọn nǹkan tó nílò. Ẹ wo bí àwọn nǹkan tí Jósẹ́fù ṣe yẹn ṣe máa mú kí Màríà túbọ̀ nífẹ̀ẹ́ ẹ̀, kó sì bọ̀wọ̀ fún un! Ẹ̀yin ọkọ, ẹ lè kẹ́kọ̀ọ́ lára Jósẹ́fù tẹ́ ẹ bá ń tẹ̀ lé àwọn ìmọ̀ràn Bíbélì lórí bẹ́ ẹ ṣe máa bójú tó ìdílé yín. Tó o bá ń fi ìmọ̀ràn yìí sílò, tó bá tiẹ̀ máa gba pé kó o ṣe àwọn àyípadà kan, wàá fi hàn pé o nífẹ̀ẹ́ ìyàwó ẹ, okùn ìfẹ́ yín á sì máa lágbára sí i. Arábìnrin kan láti Vanuatu tó ti ṣègbéyàwó ní ohun tó lé lógún (20) ọdún sọ pé: “Gbogbo ìgbà tí ọkọ mi bá ní kí Jèhófà tọ́ òun sọ́nà, tó sì ṣe ohun tí Jèhófà sọ ni mo túbọ̀ máa ń bọ̀wọ̀ fún un. Ọkàn mi máa ń balẹ̀, mo sì máa ń fọkàn tán an pé ìpinnu tó dáa ló máa ṣe.” w23.05 21 ¶5
Thursday, September 4
Ọ̀nà kan sì máa wà níbẹ̀, àní, ọ̀nà tí à ń pè ní Ọ̀nà Ìjẹ́mímọ́.—Àìsá. 35:8.
Àwọn Júù tó pa dà sí ìlú ìbílẹ̀ wọn gbọ́dọ̀ jẹ́ “èèyàn mímọ́” lójú Ọlọ́run. (Diu. 7:6) Àmọ́ ìyẹn ò túmọ̀ sí pé wọn ò ní ṣe àyípadà kankan, kí wọ́n lè ṣe ohun tí Jèhófà fẹ́. Ìlú Bábílónì ni wọ́n bí ọ̀pọ̀ lára àwọn Júù yẹn sí, ọ̀nà táwọn ará Bábílónì sì ń gbà ronú àti bí wọ́n ṣe ń ṣe nǹkan ti mọ́ wọn lára. Nígbà táwọn kan lára àwọn Júù kọ́kọ́ pa dà sí Ísírẹ́lì, ó ya Gómìnà Nehemáyà lẹ́nu gan-an pé àwọn ọmọ táwọn Júù yẹn bí sí Ísírẹ́lì ò lè sọ èdè Júù. (Diu. 6:6, 7; Neh. 13:23, 24) Báwo làwọn ọmọ yẹn ṣe máa nífẹ̀ẹ́ Jèhófà, tí wọ́n á sì máa sìn ín tí wọn ò bá gbọ́ èdè Hébérù, ìyẹn èdè tí wọ́n fi kọ Ọ̀rọ̀ Ọlọ́run? (Ẹ́sírà 10:3, 44) Torí náà, ó hàn gbangba pé àwọn Júù yẹn gbọ́dọ̀ ṣe àwọn àyípadà kan, ìyẹn sì máa rọrùn torí ilẹ̀ Ísírẹ́lì ni wọ́n wà níbi tí ìjọsìn mímọ́ ti ń pa dà bọ̀ sípò.—Neh. 8:8, 9. w23.05 15 ¶6-7
Friday, September 5
Jèhófà ń gbé gbogbo àwọn tó ti fẹ́ ṣubú ró, ó sì ń gbé gbogbo àwọn tó dorí kodò dìde.—Sm. 145:14.
Ó bani nínú jẹ́ pé kò sí bá a ṣe ṣiṣẹ́ kára tó tàbí bá a ṣe kó ara wa níjàánu tó, àwọn nǹkan kan ṣì lè mú kọ́wọ́ wa má tètè tẹ àfojúsùn wa. Bí àpẹẹrẹ, “ìgbà àti èèṣì” lè má jẹ́ kọ́wọ́ wa tẹ ohun tá à ń lé. (Oníw. 9:11) Yàtọ̀ síyẹn, ìṣòro lè mú ká rẹ̀wẹ̀sì, ká má sì lókun mọ́. (Òwe 24:10) Torí pé aláìpé ni wá, a lè máa ṣe ohun tí ò ní jẹ́ kọ́wọ́ wa tẹ ohun tá à ń lé. (Róòmù 7:23) Gbogbo nǹkan sì lè tojú sú wa. (Mát. 26:43) Torí náà, kí ló máa ràn wá lọ́wọ́ láti borí àwọn ìṣòro yìí? Máa rántí pé tóhun kan ò bá jẹ́ kọ́wọ́ ẹ tètè tẹ nǹkan tó ò ń lé, ìyẹn ò túmọ̀ sí pé kó o pa nǹkan náà tì. Bíbélì sọ pé ìṣòro lè dé bá wa léraléra. Àmọ́, ó tún sọ pé Jèhófà máa ràn wá lọ́wọ́ láti borí àwọn ìṣòro náà. Ó dájú pé tó o bá ń ṣiṣẹ́ kára kọ́wọ́ ẹ lè tẹ àfojúsùn ẹ bó tiẹ̀ jẹ́ pé kò rọrùn, ìyẹn á jẹ́ kí Jèhófà mọ̀ pé o fẹ́ ṣohun tóun fẹ́. Wo bí inú Jèhófà ṣe máa dùn tó pé o ṣe gbogbo ohun tó o lè ṣe kọ́wọ́ ẹ lè tẹ ohun tó ò ń lé! w23.05 30 ¶14-15