ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • w97 8/15 ojú ìwé 30
  • Ìbéèrè Láti Ọwọ́ Àwọn Òǹkàwé

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

  • Ìbéèrè Láti Ọwọ́ Àwọn Òǹkàwé
  • Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—1997
  • Àpilẹ̀kọ Míì Tó Jọ ọ́
  • Wíwá Jésù Tàbí Wíwà Níhìn-ín Jésù—Èwo Ni?
    Ilé-Ìṣọ́nà Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—1996
  • Orukọ Ọlọrun ati “Majẹmu Titun” Naa
    Orukọ Atọrunwa naa Tí Yoo Wà Titilae
  • A4 Orúkọ Ọlọ́run Nínú Ìwé Mímọ́ Lédè Hébérù
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
  • Kí Ni Ìwé Àwọn Masorete?
    Ilé-Ìṣọ́nà Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—1995
Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—1997
w97 8/15 ojú ìwé 30

Ìbéèrè Láti Ọwọ́ Àwọn Òǹkàwé

Ǹjẹ́ Júù oníṣègùn ti ọ̀rúndún kẹrìnlá náà, Shem-Tob ben Isaac Ibn Shaprut, ṣàdàkọ Tetragrammaton (lẹ́tà Hébérù mẹ́rin tí ó dúró fún orúkọ Ọlọ́run) tí a rí nínú ìwé Mátíù tí a fi èdè Hébérù kọ?

Rárá, kò ṣe bẹ́ẹ̀. Ṣùgbọ́n, ìwé Mátíù yí lo hash·Shem’ (tí a kọ tán tàbí tí a ké kúrú) ní ìgbà 19, gẹ́gẹ́ bí a ti sọ nínú Ilé Ìṣọ́ August 15, 1996, ní ojú ìwé 13.

Ọ̀rọ̀ Hébérù náà, hash·Shem’, túmọ̀ sí “Orúkọ náà,” tí ó tọ́ka sí orúkọ àtọ̀runwá náà láìsí àní-àní. Fún àpẹẹrẹ, nínú àkọsílẹ̀ Shem-Tob, ìkékúrú ẹ̀yà ọ̀rọ̀ hash·Shem’ fara hàn nínú Mátíù 3:3, ẹsẹ tí Mátíù ti fa ọ̀rọ̀ inú Aísáyà 40:3 yọ. Ó bọ́gbọ́n mu láti dé ìparí èrò náà pé, nígbà tí Mátíù fa ọ̀rọ̀ inú ẹsẹ kan yọ nínú Ìwé Mímọ́ Lédè Hébérù, níbi ti Tetragrammaton wà, ó fi orúkọ àtọ̀runwá náà sínú Ìhìn Rere rẹ̀. Nítorí náà, bí àkọsílẹ̀ Hébérù tí Shem-Tob gbé kalẹ̀ kò tilẹ̀ lo Tetragrammaton, lílò tí ó lo “Orúkọ náà,” gẹ́gẹ́ bí a ti lò ó nínú Mátíù 3:3, ti lílo “Jèhófà” lẹ́yìn nínú Ìwé Mímọ́ Kristẹni Lédè Gíríìkì.

Shem-Tob ṣàdàkọ ìwé Mátíù lédè Hébérù nínú iṣẹ́ alátakò gbígbóná janjan rẹ̀ náà, ʼEʹven boʹchan. Ṣùgbọ́n, kí ni orísun ìwé Hébérù náà? Ọ̀jọ̀gbọ́n George Howard, tí ó ti ṣèwádìí jinlẹ̀ lórí ọ̀ràn yí, dábàá pé “Ọjọ́ orí Ìwé Mímọ́ Mátíù Lédè Hébérù ti Shem-Tob tó nǹkan bí àárín ọ̀rúndún mẹ́rin àkọ́kọ́ ti sànmánì Kristẹni.”a Àwọn ẹlòmíràn lè ṣàìfohùn ṣọ̀kan pẹ̀lú rẹ lórí èyí.

Howard sọ pé: “Ìwé Mátíù Lédè Hébérù, tí a lò nínú àkọsílẹ̀ yí ní pàtàkì ni a fi ọ̀pọ̀ ohun tí ó fi yàtọ̀ sí ìwé Mátíù Lédè Gíríìkì dá mọ̀ yàtọ̀.” Fún àpẹẹrẹ, gẹ́gẹ́ bí ohun tí àkọsílẹ̀ Shem-Tob sọ, Jésù sọ nípa Jòhánù pé: “Ní òótọ́ ni mo wí fún yín pé, láàárín àwọn tí obìnrin bí kò sí ẹni kan tí ó dìde tí ó tóbi ju Jòhánù Oníbatisí lọ.” Ó fo ọ̀rọ̀ Jésù tí ó tẹ̀ lé e pé: “Ṣùgbọ́n ẹni kan tí ó jẹ́ ẹni tí ó kéré jù nínú ìjọba àwọn ọ̀run tóbi jù ú.” (Mátíù 11:11) Ní ọ̀nà tí ó jọra, ọ̀pọ̀ ìyàtọ̀ wà láàárín ẹsẹ Hébérù ti Ìwé Mímọ́ Lédè Hébérù tí kò sọnù àti ọ̀rọ̀ inú ẹsẹ kan náà nínú ìtumọ̀ ti Septuagint Lédè Gíríìkì. Bí a tilẹ̀ mọ̀ nípa ìyàtọ̀ tí ó wà láàárín wọn, irú àwọn ìwé àtijọ́ bẹ́ẹ̀ ní àyè tiwọn nínú ìkẹ́kọ̀ọ́ ìfiwéra.

Gẹ́gẹ́ bí a ti sọ ṣáájú, àkọsílẹ̀ Shem-Tob lórí Mátíù ní “Orúkọ náà” níbi tí a ní ẹ̀rí tí ó pọ̀ tó láti gbà gbọ́ pé Tetragrammaton gan-an ni Mátíù lò níbẹ̀. Nípa báyìí, láti 1950, a ti ń lo àkọsílẹ̀ Shem-Tob gẹ́gẹ́ bí ìtìlẹ́yìn fún lílo orúkọ àtọ̀runwá náà nínú Ìwé Mímọ́ Kristẹni Lédè Gíríìkì, a sì tọ́ka sí i nínú The New World Translation of the Holy Scriptures—With References.b

[Àwọ̀n Àlàyé ìsàlẹ̀ ìwé]

a Tún wo ìwé New Testament Studies, Ìdìpọ̀ 43, Nọ́ńbà 1, January 1997, ojú ìwé 58 sí 71.

b Tí Watchtower Bible and Tract Society of New York, Inc., tẹ̀ jáde ní 1984.

    Yorùbá Publications (1987-2025)
    Jáde
    Wọlé
    • Yorùbá
    • Fi Ráńṣẹ́
    • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
    • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
    • Àdéhùn Nípa Lílò
    • Òfin
    • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
    • JW.ORG
    • Wọlé
    Fi Ráńṣẹ́