-
Ìjàkadì Nítorí Ìhìn Rere Ní Ìlú TẹsalóníkàIlé Ìṣọ́—2012 | June 1
-
-
Tí Pọ́ọ̀lù bá ti dé ìlú kan, ó máa ń kọ́kọ́ lọ sọ́dọ̀ àwọn Júù nítorí pé, bí wọ́n ṣe ti mọ̀ nípa Ìwé Mímọ́, wọ́n á lè jọ sọ̀rọ̀ nípa rẹ̀, á sì tipa bẹ́ẹ̀ là wọ́n lóye nípa ìhìn rere. Ọ̀mọ̀wé kan sọ pé ohun tí Pọ́ọ̀lù sábà máa ń ṣe yìí fi hàn pé ọ̀rọ̀ àwọn Júù èèyàn rẹ̀ jẹ ẹ́ lógún gan-an, tàbí kó jẹ́ pé ó ń gbìyànjú láti kọ́kọ́ bẹ̀rẹ̀ ìwàásù lọ́dọ̀ àwọn Júù àti àwọn olùbẹ̀rù Ọlọ́run kó lè ráyè wàásù fún àwọn Kèfèrí.—Ìṣe 17:2-4.
Torí náà, nígbà tí Pọ́ọ̀lù dé Tẹsalóníkà, ó wọ inú sínágọ́gù lọ, ó ń “bá [àwọn Júù] fèrò-wérò láti inú Ìwé Mímọ́, ó ń ṣàlàyé, ó sì ń fi ẹ̀rí ìdánilójú hàn nípasẹ̀ àwọn ìtọ́ka pé ó pọndandan kí Kristi jìyà, kí ó sì dìde kúrò nínú òkú, ó sì wí pé: ‘Èyí ni Kristi náà, Jésù yìí tí mo ń kéde fún yín.’”—Ìṣe 17:2, 3, 10.
Ohun tó ṣì ń fa àríyànjiyàn ni Pọ́ọ̀lù sọ̀rọ̀ lé lórí, ìyẹn ẹni tó jẹ́ Mèsáyà àti ojúṣe rẹ̀. Àwọn Júù kò rò pé Mèsáyà máa wá jìyà tó bá dé. Ohun tí wọ́n retí ni pé ṣe lá máa jagun láti ṣẹ́gun àwọn ọ̀tá àwọn. Láti lè yí àwọn Júù lọ́kàn pa dà, Pọ́ọ̀lù “bá wọn fèrò-wérò,” ‘ó ṣàlàyé,’ ‘ó sì fi ẹ̀rí ìdánilójú hàn nípasẹ̀ àwọn ìtọ́ka’ láti inú Ìwé Mímọ́, ohun tí olùkọ́ tó pegedé sì máa ń ṣe nìyẹn.a Àmọ́, báwo wá ni gbogbo àlàyé kíkún tí Pọ́ọ̀lù ṣe yẹn ṣe rí lára àwọn tó ń bá sọ̀rọ̀?
-
-
Ìjàkadì Nítorí Ìhìn Rere Ní Ìlú TẹsalóníkàIlé Ìṣọ́—2012 | June 1
-
-
a Ó ṣeé ṣe kí Pọ́ọ̀lù tọ́ka sí àwọn ẹsẹ Ìwé Mímọ́ bíi Sáàmù 22:7; 69:21; Aísáyà 50:6; 53:2-7; àti Dáníẹ́lì 9:26.
-