ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • Kẹ́kọ̀ọ́ Látinú ‘Kókó Òtítọ́’
    Ilé Ìṣọ́—2012 | January 15
    • Kẹ́kọ̀ọ́ Látinú ‘Kókó Òtítọ́’

      “[Ẹ̀yín ní] kókó ìmọ̀ àti ti òtítọ́ inú Òfin.”—RÓÒMÙ 2:20.

  • Kẹ́kọ̀ọ́ Látinú ‘Kókó Òtítọ́’
    Ilé Ìṣọ́—2012 | January 15
    • 4, 5. (a) Kí ni Òfin Mósè máa ń jẹ́ kí àwọn èèyàn Ọlọ́run rántí? (b) Kí ni òfin Ọlọ́run nípa ẹbọ rírú ṣàpẹẹrẹ?

      4 Ọ̀pọ̀ lára apá tí Òfin Mósè pín sí ló ń jẹ́ kí àwọn Júù ìgbàanì rántí pé ẹlẹ́ṣẹ̀ ni àwọn. Bí àpẹẹrẹ, bí ẹnì kan bá fọwọ́ kan òkú èèyàn, ó gbọ́dọ̀ ṣe ìwẹ̀nùmọ́. Kí àlùfáà bàa lè ṣe ìwẹ̀nùmọ́ fún un, ó máa mú màlúù pupa kan tí ara rẹ̀ dá ṣáṣá lọ sọ́dọ̀ àlùfáà. Àlùfáà á pa màlúù náà, á sì fi iná sun ún. Á wá tọ́jú eérú rẹ̀ kí wọ́n lè fi ṣe “omi ìwẹ̀nùmọ́” tí wọ́n máa wọ́n sára ẹni tí wọ́n fẹ́ ṣe ìwẹ̀nùmọ́ fún ní ọjọ́ kẹta àti ní ọjọ́ keje lẹ́yìn tó di aláìmọ́. (Núm. 19:1-13) Bákan náà, kí àwọn èèyàn lè máa rántí pé láti ìgbà tí obìnrin bá ti bímọ ni ọmọ náà ti jogún àìpé àti ẹ̀ṣẹ̀, òfin sọ pé kí irú obìnrin bẹ́ẹ̀ jẹ́ aláìmọ́ fún àwọn àkókò kan, lẹ́yìn ìyẹn ló máa wá lọ rú ẹbọ láti tọrọ ìdáríjì ẹ̀ṣẹ̀.—Léf. 12:1-8.

      5 Àwọn ọmọ Ísírẹ́lì tún máa ń fi ẹran rúbọ nítorí ọ̀pọ̀ nǹkan míì tó kan ìgbésí ayé wọn ojoojúmọ́ kí wọ́n lè ṣètùtù fún àwọn ẹ̀ṣẹ̀ wọn. Yálà àwọn olùjọ́sìn yìí mọ̀ bẹ́ẹ̀ tàbí wọn kò mọ̀ bẹ́ẹ̀, àwọn ẹbọ yìí àti àwọn tí wọ́n rú nínú tẹ́ńpìlì Jèhófà lẹ́yìn ìgbà náà jẹ́ “òjìji” ẹbọ pípé tí Jésù rú.—Héb. 10:1-10.

      OHUN TÍ ẸBỌ NÁÀ FI HÀN

      6, 7. (a) Àwọn nǹkan wo ni àwọn ọmọ Ísírẹ́lì máa ń gbé yẹ̀ wò kí wọ́n tó yan ohun tí wọ́n máa fi rúbọ, kí sì ni èyí ṣàpẹẹrẹ? (b) Àwọn ìbéèrè wo la lè bi ara wa?

      6 Ìlànà pàtàkì kan tí àwọn ọmọ Ísírẹ́lì máa ń tẹ̀ lé tí wọ́n bá fẹ́ pinnu irú ẹran tí wọ́n máa fi rúbọ sí Jèhófà ni pé kí ẹran náà jẹ́ èyí tí “ara rẹ̀ dá ṣáṣá” ní gbogbo ọ̀nà, kò gbọ́dọ̀ jẹ́ èyí tó fọ́jú, tó fara pa, tó lábùkù lára tàbí èyí tó ń ṣàìsàn. (Léf. 22:20-22) Bí àwọn ọmọ Ísírẹ́lì bá fi èso tàbí ọkà rúbọ sí Jèhófà, ó gbọ́dọ̀ jẹ́ “àkọ́so,” “èyí tí ó dára jù lọ” nínú irè oko wọn. (Núm. 18:12, 29) Jèhófà kò ní gba ẹbọ wọn bí wọ́n bá lo àwọn ohun tí kò dára. Ohun pàtàkì tí Ọlọ́run béèrè nípa fífi ẹran rúbọ fi hàn pé ẹbọ Jésù máa jẹ́ èyí tí kò lábààwọ́n àti èyí tí kò léèérí àti pé ohun tí Jèhófà kà sí ohun tó dára jù lọ tó sì ṣe pàtàkì jù lọ ló máa fi rúbọ kó bàa lè ra aráyé pa dà.—1 Pét. 1:18, 19.

Yorùbá Publications (1987-2025)
Jáde
Wọlé
  • Yorùbá
  • Fi Ráńṣẹ́
  • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
  • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
  • Àdéhùn Nípa Lílò
  • Òfin
  • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
  • JW.ORG
  • Wọlé
Fi Ráńṣẹ́