Nọ́ńbà
18 Jèhófà wá sọ fún Áárónì pé: “Ìwọ àti àwọn ọmọ rẹ àti agbo ilé bàbá rẹ pẹ̀lú rẹ ni yóò máa dáhùn fún ẹ̀ṣẹ̀ èyíkéyìí lòdì sí ibi mímọ́,+ ìwọ àti àwọn ọmọ rẹ pẹ̀lú rẹ ni yóò sì máa dáhùn fún ẹ̀ṣẹ̀ èyíkéyìí lòdì sí iṣẹ́ àlùfáà+ yín. 2 Kí o tún mú àwọn arákùnrin rẹ tí wọ́n jẹ́ ara ẹ̀yà Léfì sún mọ́ tòsí, ẹ̀yà baba ńlá rẹ, kí wọ́n lè dara pọ̀ mọ́ ọ, kí wọn sì máa bá ìwọ àti àwọn ọmọ rẹ ṣiṣẹ́+ níwájú àgọ́ Ẹ̀rí.+ 3 Kí wọ́n máa ṣe ojúṣe wọn fún ọ àti fún àgọ́ náà lódindi.+ Àmọ́, wọn ò gbọ́dọ̀ sún mọ́ àwọn ohun èlò ibi mímọ́ àti pẹpẹ kí ẹ̀yin tàbí àwọn má bàa kú.+ 4 Kí wọ́n dara pọ̀ mọ́ ọ, kí wọ́n sì máa ṣe ojúṣe wọn tó jẹ mọ́ àgọ́ ìpàdé àti gbogbo iṣẹ́ àgọ́ náà, ẹnikẹ́ni tí kò lẹ́tọ̀ọ́* sí i kò sì gbọ́dọ̀ sún mọ́ yín.+ 5 Kí ẹ máa ṣe ojúṣe yín tó jẹ mọ́ ibi mímọ́ + àti pẹpẹ,+ kí n má bàa tún bínú+ sí àwọn ọmọ Ísírẹ́lì. 6 Èmi fúnra mi ti mú àwọn arákùnrin yín, àwọn ọmọ Léfì, látinú àwọn ọmọ Ísírẹ́lì, mo sì fi wọ́n ṣe ẹ̀bùn fún yín.+ A ti fi wọ́n fún Jèhófà kí wọ́n lè máa bójú tó iṣẹ́ tó jẹ mọ́ àgọ́ ìpàdé.+ 7 Ojúṣe ìwọ àti àwọn ọmọ rẹ ni láti máa ṣe iṣẹ́ àlùfáà tó jẹ mọ́ pẹpẹ àtàwọn ohun tó wà lẹ́yìn aṣọ ìdábùú,+ ẹ̀yin ni kí ẹ máa ṣe iṣẹ́ yìí.+ Mo ti fi iṣẹ́ àlùfáà ṣe ẹ̀bùn fún yín, ṣe ni kí ẹ pa+ ẹnikẹ́ni tí kò lẹ́tọ̀ọ́* sí i tó bá sún mọ́ tòsí.”
8 Jèhófà tún sọ fún Áárónì pé: “Èmi fúnra mi fi gbogbo ọrẹ tí wọ́n bá ṣe fún mi+ sí ìkáwọ́ rẹ. Mo ti fún ìwọ àti àwọn ọmọ rẹ lára gbogbo ohun mímọ́ tí àwọn ọmọ Ísírẹ́lì bá fi ṣe ọrẹ, kó jẹ́ ìpín+ yín títí lọ. 9 Èyí ló máa jẹ́ tìrẹ nínú ọrẹ mímọ́ jù lọ tí wọ́n fi iná sun: gbogbo ọrẹ tí wọ́n bá mú wá, títí kan àwọn ọrẹ ọkà+ wọn àtàwọn ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀+ wọn pẹ̀lú àwọn ẹbọ ẹ̀bi+ wọn tí wọ́n mú wá fún mi. Ohun mímọ́ jù lọ ló jẹ́ fún ìwọ àti àwọn ọmọ rẹ. 10 Inú ibi mímọ́ jù lọ ni kí o ti jẹ ẹ́.+ Gbogbo ọkùnrin ló lè jẹ ẹ́. Kó jẹ́ ohun mímọ́ fún ọ.+ 11 Ìwọ náà lo tún ni èyí: àwọn ẹ̀bùn tí wọ́n mú+ wá pẹ̀lú gbogbo ọrẹ fífì+ tí àwọn ọmọ Ísírẹ́lì bá mú wá. Mo ti fún ìwọ àtàwọn ọmọkùnrin rẹ àti àwọn ọmọbìnrin rẹ pẹ̀lú rẹ, kó jẹ́ ìpín+ yín títí lọ. Gbogbo ẹni tó mọ́ nínú ilé rẹ ló lè jẹ ẹ́.+
12 “Mo fún ọ+ ní gbogbo òróró tó dáa jù àti gbogbo wáìnì tuntun tó dáa jù àti ọkà, àkọ́so+ wọn, èyí tí wọ́n fún Jèhófà. 13 Àkọ́pọ́n gbogbo ohun tó bá so nílẹ̀ wọn, tí wọ́n bá mú wá fún Jèhófà yóò di tìrẹ.+ Gbogbo ẹni tó mọ́ nínú ilé rẹ ló lè jẹ ẹ́.
14 “Gbogbo ohun tí wọ́n bá yà sọ́tọ̀* ní Ísírẹ́lì yóò di tìrẹ.+
15 “Àkọ́bí gbogbo ohun alààyè,*+ tí wọ́n bá mú wá fún Jèhófà, ì báà jẹ́ èèyàn tàbí ẹranko, yóò di tìrẹ. Àmọ́, o gbọ́dọ̀ ra àkọ́bí èèyàn+ pa dà, kí o sì tún ra àkọ́bí àwọn ẹran tó jẹ́ aláìmọ́ pa dà.+ 16 Tó bá ti pé oṣù kan tàbí jù bẹ́ẹ̀ lọ, kí o san owó ìràpadà láti rà á pa dà, kí o san ṣékélì*+ fàdákà márùn-ún tí wọ́n dá lé e, kó jẹ́ ìwọ̀n ṣékélì ibi mímọ́.* Ó jẹ́ ogún (20) òṣùwọ̀n gérà.* 17 Akọ màlúù tó jẹ́ àkọ́bí tàbí akọ ọ̀dọ́ àgùntàn tó jẹ́ àkọ́bí tàbí àkọ́bí ewúrẹ́ nìkan ni kí o má rà pa dà.+ Wọ́n jẹ́ ohun mímọ́. Kí o wọ́n ẹ̀jẹ̀ wọn sórí pẹpẹ,+ kí o sì mú kí ọ̀rá wọn rú èéfín bí ọrẹ àfinásun tó máa mú òórùn dídùn* jáde sí Jèhófà.+ 18 Kí ẹran wọn di tìrẹ. Kó di tìrẹ+ bí igẹ̀ ọrẹ fífì àti bí ẹsẹ̀ ọ̀tún. 19 Gbogbo ọrẹ mímọ́ tí àwọn ọmọ Ísírẹ́lì bá mú wá fún Jèhófà+ ni mo ti fún ìwọ àti àwọn ọmọkùnrin rẹ àti àwọn ọmọbìnrin rẹ pẹ̀lú rẹ, kó jẹ́ ìpín+ yín títí lọ. Ó jẹ́ májẹ̀mú iyọ̀* tó máa wà títí lọ níwájú Jèhófà fún ìwọ àti àwọn ọmọ rẹ pẹ̀lú rẹ.”
20 Jèhófà ń bá ọ̀rọ̀ tó ń sọ fún Áárónì lọ pé: “O ò ní ní ogún ní ilẹ̀ wọn, o ò sì ní ní ilẹ̀ kankan tó máa jẹ́ ìpín rẹ+ láàárín wọn. Èmi ni ìpín rẹ àti ogún rẹ láàárín àwọn ọmọ Ísírẹ́lì.+
21 “Wò ó, mo ti fún àwọn ọmọ Léfì ní gbogbo ìdá mẹ́wàá+ ní Ísírẹ́lì, kó jẹ́ ogún wọn torí iṣẹ́ tí wọ́n ń ṣe, iṣẹ́ àgọ́ ìpàdé. 22 Kí àwọn ọmọ Ísírẹ́lì má ṣe sún mọ́ àgọ́ ìpàdé mọ́, àìjẹ́ bẹ́ẹ̀, wọ́n ti dẹ́ṣẹ̀, wọ́n á sì kú. 23 Àwọn ọmọ Léfì fúnra wọn ni kó máa ṣiṣẹ́ ní àgọ́ ìpàdé, àwọn sì ni kó máa dáhùn fún ẹ̀ṣẹ̀ wọn.+ Àṣẹ tó máa wà títí lọ jálẹ̀ gbogbo ìran yín ni pé wọn ò gbọ́dọ̀ ní ogún láàárín àwọn ọmọ Ísírẹ́lì.+ 24 Torí mo ti fi ìdá mẹ́wàá tí àwọn ọmọ Ísírẹ́lì máa mú wá fún Jèhófà ṣe ogún fún àwọn ọmọ Léfì. Ìdí nìyẹn tí mo fi sọ fún wọn pé, ‘Wọn ò gbọ́dọ̀ ní ogún+ láàárín àwọn ọmọ Ísírẹ́lì.’”
25 Jèhófà wá sọ fún Mósè pé: 26 “Sọ fún àwọn ọmọ Léfì pé, ‘Ẹ ó máa gba ìdá mẹ́wàá lọ́wọ́ àwọn ọmọ Ísírẹ́lì, èyí tí mo fún yín láti ọwọ́ wọn kó lè jẹ́ ogún+ yín, kí ẹ sì fi ìdá mẹ́wàá lára ìdá mẹ́wàá náà ṣe ọrẹ fún Jèhófà.+ 27 Ìyẹn ló máa jẹ́ ọrẹ yín, bí ọkà láti ibi ìpakà+ tàbí ọ̀pọ̀ rẹpẹtẹ ohun tó jáde láti ibi tí wọ́n ti ń fún wáìnì tàbí òróró. 28 Báyìí ni ẹ̀yin náà á ṣe máa mú ọrẹ wá fún Jèhófà látinú gbogbo ìdá mẹ́wàá tí ẹ bá gbà lọ́wọ́ àwọn ọmọ Ísírẹ́lì, látinú wọn ni kí ẹ ti máa fún àlùfáà Áárónì ní ọrẹ tí ẹ mú wá fún Jèhófà. 29 Kí ẹ mú gbogbo onírúurú ọrẹ wá fún Jèhófà látinú ohun tó dáa jù nínú gbogbo ẹ̀bùn tí wọ́n fún yín+ bí ohun mímọ́.’
30 “Kí o sì sọ fún wọn pé, ‘Tí ẹ bá fi èyí tó dáa jù nínú wọn ṣe ọrẹ, yóò jẹ́ ti àwọn ọmọ Léfì bí ohun tó wá láti ibi ìpakà àti ohun tó wá láti ibi tí wọ́n ti ń fún wáìnì tàbí òróró. 31 Ibikíbi ni ẹ̀yin àti agbo ilé yín ti lè jẹ ẹ́, torí èrè iṣẹ́ tí ẹ̀ ń ṣe ní àgọ́ ìpàdé+ ló jẹ́. 32 Ẹ ò ní dẹ́ṣẹ̀ tí ẹ bá ṣe bẹ́ẹ̀, tó bá ṣáà ti jẹ́ èyí tó dáa jù lẹ́ fi ṣe ọrẹ, ẹ ò sì gbọ́dọ̀ sọ àwọn ohun mímọ́ àwọn ọmọ Ísírẹ́lì di aláìmọ́, àìjẹ́ bẹ́ẹ̀, ẹ máa kú.’”+