Orí Kẹrìndínlógún
Wá Ọjọ́ Ọ̀la Wíwà Pẹ́ Títí fún Ìdílé Rẹ
1. Kí ni ète Jehofa fún ètò ìdílé?
NÍGBÀ tí Jehofa so Adamu àti Efa pọ̀ nínú ìgbéyàwó, Adamu fi ìdùnnú rẹ̀ hàn nípa kíkéwì Heberu tí àkọsílẹ̀ rẹ̀ lọ́jọ́ lórí jù lọ. (Genesisi 2:22, 23) Bí ó ti wù kí ó rí, Ẹlẹ́dàá ní púpọ̀ lọ́kàn ju mímú adùn wá fún àwọn ọmọ rẹ̀ ẹ̀dá ènìyàn lọ. Ó fẹ́ kí tọkọtaya àti ìdílé wọn ṣe ìfẹ́ rẹ̀. Ó sọ fún tọkọtaya àkọ́kọ́ pé: “Ẹ máa bí sí i, kí ẹ sì máa rẹ̀, kí ẹ sì gbilẹ̀, kí ẹ sì ṣe ìkáwọ́ rẹ̀; kí ẹ sì máa jọba lórí ẹja òkun, àti lórí ẹyẹ ojú ọ̀run, àti lórí ohun alààyè gbogbo tí ń rákò lórí ilẹ̀.” (Genesisi 1:28) Ẹ wo irú iṣẹ́ amérèwá gidi tí ìyẹn jẹ́! Ẹ sì wo bí àwọn àti àwọn ọmọ wọn ọjọ́ ọ̀la ì bá ti láyọ̀ tó ká ní Adamu àti Efa ti ṣe ìfẹ́ Jehofa nínú ìgbọràn kíkún rẹ́rẹ́!
2, 3. Báwo ni àwọn ìdílé ṣe lè rí ayọ̀ tí ó ga jù lọ lónìí?
2 Lónìí pẹ̀lú, ayọ̀ ìdílé máa ń kún nígbà tí wọ́n bá jùmọ̀ ṣiṣẹ́ láti ṣe ìfẹ́ Ọlọrun. Aposteli Paulu kọ̀wé pé: “Ìfọkànsin Ọlọrun ṣàǹfààní fún ohun gbogbo, bí ó ti ní ìlérí ìyè ti ìsinsìnyí ati ti èyíinì tí ń bọ̀.” (1 Timoteu 4:8) Ìdílé tí ń gbé pẹ̀lú ìfọkànsin Ọlọrun, tí ó sì ń tẹ̀ lé ìtọ́sọ́nà Jehofa, gẹ́gẹ́ bí ó ti wà nínú Bibeli, yóò rí ayọ̀ nínú “ìyè ti ìsinsìnyí.” (Orin Dafidi 1:1-3; 119:105; 2 Timoteu 3:16) Àní bí ó bá jẹ́ kìkì mẹ́ḿbà kan ṣoṣo nínú ìdílé ní ń lo àwọn ìlànà Bibeli, àwọn nǹkan máa ń dára ju ìgbà tí ẹnikẹ́ni kò bá lò ó lọ.
3 Ìwé yìí ti jíròrò ọ̀pọ̀ ìlànà Bibeli tí ń dá kún ayọ̀ ìdílé. Ó ṣeé ṣe kí o ti kíyè sí i pé díẹ̀ lára wọ́n fara hàn léraléra jálẹ̀ ìwé yìí. Èé ṣe? Nítorí wọ́n jẹ́ òtítọ́ lílágbára tí ó gbéṣẹ́ fún ire gbogbo mẹ́ḿbà ìdílé ní onírúurú apá ìgbésí ayé ìdílé. Ìdílé tí ó bá là kàkà láti lo àwọn ìlànà Bibeli wọ̀nyí, yóò rí i pé ìfọkànsin Ọlọrun “ní ìlérí ìyè ti ìsinsìnyí,” ní tòótọ́. Ẹ jẹ́ kí a wo mẹ́rin lára àwọn ìlànà pàtàkì wọ̀nyẹn lẹ́ẹ̀kan sí i.
ÀǸFÀÀNÍ ÌKÓRA-ẸNI-NÍJÀÁNU
4. Èé ṣe tí ìkóra-ẹni-níjàánu fi ṣe pàtàkì nínú ìgbéyàwó?
4 Ọba Solomoni sọ pé: “Ẹni tí kò lè ṣe àkóso ara rẹ̀, ó dà bí ìlú tí a wó lulẹ̀, tí kò sì ní odi.” (Owe 25:28; 29:11) ‘Ṣíṣàkóso ara ẹni,’ lílo ìkóra-ẹni-níjàánu, ṣe kókó fún àwọn tí ń fẹ́ ìgbéyàwó aláyọ̀. Jíjuwọ́ sílẹ̀ fún èrò ìmọ̀lára apanirun, irú bí ìbínú fùfù tàbí ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́, yóò ṣèpalára tí yóò gba ọ̀pọ̀ ọdún láti ṣàtúnṣe—bí ó bá ṣe é tún ṣe rárá.
5. Báwo ni ènìyàn aláìpé ṣe lè mú ìkóra-ẹni-níjàánu dàgbà, pẹ̀lú àwọn àǹfààní wo sì ni?
5 Àmọ́ ṣáá o, kò sí àtọmọdọ́mọ Adamu èyíkéyìí tí ó lè ṣàkóso ẹran ara rẹ̀ aláìpé délẹ̀délẹ̀. (Romu 7:21, 22) Síbẹ̀, ìkóra-ẹni-níjàánu jẹ́ ọ̀kan lára àwọn èso ẹ̀mí. (Galatia 5:22, 23) Nítorí náà, ẹ̀mí Ọlọrun yóò mú ìkóra-ẹni-níjàánu jáde nínú wa bí a bá gbàdúrà fún ànímọ́ yìí, bí a bá lo ìmọ̀ràn yíyẹ, tí a rí nínú Ìwé Mímọ́, bí a bá sì kẹ́gbẹ́ pọ̀ pẹ̀lú àwọn tí ń fi ànímọ́ yìí hàn, tí a sì yẹra fún àwọn tí kì í fi í hàn. (Orin Dafidi 119:100, 101, 130; Owe 13:20; 1 Peteru 4:7) Irú ìgbésẹ̀ bẹ́ẹ̀ yóò ràn wá lọ́wọ́ láti “sá fún àgbèrè,” àní nígbà tí a bá dẹ wá wò pàápàá. (1 Korinti 6:18) A óò kọ ìwà ipá sílẹ̀, a óò sì yẹra fún ìmukúmu tàbí kí a ṣẹ́pá rẹ̀. Gbogbo wa yóò sì lè fi pẹ̀lẹ́tù kojú ìsúnnibínú àti àwọn ipò tí kò rọrùn. Ǹjẹ́ kí gbogbo wa—títí kan àwọn ọmọdé—kọ́ láti mú èso ẹ̀mí ṣíṣeyebíye yìí dàgbà.—Orin Dafidi 119:1, 2.
OJÚ ÌWÒYE TÍ Ó TỌ́ NÍPA IPÒ ORÍ
6. (a) Kí ni ètò tí Ọlọrun fìdí rẹ̀ múlẹ̀ nípa ipò orí? (b) Kí ni ó yẹ kí ọkọ́ rántí bí ipò orí rẹ̀ yóò bá mú ayọ̀ wá fún ìdílé rẹ̀?
6 Mímọ ipò orí jẹ́ ìlànà kejì tí ó ṣe pàtàkì. Paulu ṣàpèjúwe ìṣètò àwọn nǹkan nígbà tí ó sọ pé: “Mo fẹ́ kí ẹ mọ̀ pé orí olúkúlùkù ọkùnrin ni Kristi; ẹ̀wẹ̀ orí obìnrin ni ọkùnrin; ẹ̀wẹ̀ orí Kristi ni Ọlọrun.” (1 Korinti 11:3) Èyí túmọ̀ sí pé ọkọ ní ń mú ipò iwájú nínú ìdílé, ìyàwó rẹ̀ ń fi ìṣòtítọ́ ṣètìlẹyìn, àwọn ọmọ sì ń ṣègbọràn sí àwọn òbí wọn. (Efesu 5:22-25, 28-33; 6:1-4) Àmọ́ ṣáá o, kíyè sí i pé ipò orí ń ṣamọ̀nà sí ayọ̀ kìkì nígbà tí a bá lò ó lọ́nà tí ó yẹ. Àwọn ọkọ tí ń gbé pẹ̀lú ìfọkànsin Ọlọrun mọ̀ pé ipò orí kì í ṣe ipò apàṣẹwàá. Wọ́n ń fara wé Jesu, Orí wọn. Bí Jesu yóò tilẹ̀ jẹ́ “orí lórí ohun gbogbo,” òún “wá, kì í ṣe kí a lè ṣe ìránṣẹ́ fún un, bíkòṣe kí ó lè ṣe ìránṣẹ́.” (Efesu 1:22; Matteu 20:28) Ní ọ̀nà kan náà, Kristian ọkọ kan ń lo ipò orí, kì í ṣe láti fi ṣe ara rẹ̀ láǹfààní, ṣùgbọ́n láti fi bójú tó ire ìyàwó àti àwọn ọmọ rẹ̀.—1 Korinti 13:4, 5.
7. Àwọn ìlànà Ìwé Mímọ́ wo ni yóò ran aya kan lọ́wọ́ láti mú ipa tí Ọlọrun fún un nínú ìgbéyàwó ṣẹ?
7 Ní tirẹ̀, aya kan tí ń gbé pẹ̀lú ìfọkànsin Ọlọrun kì í bá ọkọ rẹ̀ figa gbága tàbí wá ọ̀nà láti jẹ gàba lé e lórí. Inú rẹ̀ máa ń dùn láti tì í lẹ́yìn àti láti fọwọ́ sowọ́ pọ̀ pẹ̀lú rẹ̀. Nígbà míràn, Bibeli máa ń sọ̀rọ̀ nípa aya gẹ́gẹ́ bí “ẹni tí” ọkọ rẹ̀ “ni,” ní mímú un ṣe kedere pé ọkọ rẹ̀ ni orí rẹ̀. (Genesisi 20:3, NW) Nípasẹ̀ ìgbéyàwó, ó wá sábẹ́ “òfin ọkọ rẹ̀.” (Romu 7:2) Lọ́wọ́ kan náà, Bibeli pè é ní “olùrànlọ́wọ́” àti “àṣekún.” (Genesisi 2:20, NW) Ó ń pèsè àwọn ànímọ́ àti agbára àtilèṣe nǹkan tí ọkọ rẹ̀ ṣaláìní, ó sì ń fún ọkọ rẹ̀ ní ìtìlẹ́yìn tí ó nílò. (Owe 31:10-31) Bibeli tún sọ pé aya jẹ́ “alájọṣe,” ẹni tí ń ṣiṣẹ́ ní ìfẹ̀gbẹ́kẹ̀gbẹ́ pẹ̀lú alábàáṣègbéyàwó rẹ̀. (Malaki 2:14, NW) Àwọn ìlànà Ìwé Mímọ́ wọ̀nyí ń ran ọkọ àti aya lọ́wọ́ láti lóye ipò èkíní-kejì wọn, kí wọ́n sì fi iyì àti ọ̀wọ̀ yíyẹ hàn fún ara wọn.
“YÁRA NIPA Ọ̀RỌ̀ GBÍGBỌ́”
8, 9. Ṣàlàyé díẹ̀ lára àwọn ìlànà tí yóò ṣèrànwọ́ fún gbogbo mẹ́ḿbà ìdílé láti mú agbára ìjùmọ̀sọ̀rọ̀pọ̀ tí wọ́n ní sunwọ̀n sí i.
8 Nínú ìwé yìí, a tẹnu mọ́ ìjẹ́pàtàkì ìjùmọ̀sọ̀rọ̀pọ̀ léraléra. Èé ṣe? Nítorí pé ó máa ń rọrùn láti yanjú àwọn ìṣòro nígbà tí àwọn ènìyàn bá bá ara wọn sọ̀rọ̀ tí wọ́n sì fetí sílẹ̀ sí ara wọn ní tòótọ́. A tẹnu mọ́ ọn léraléra pé ìjùmọ̀sọ̀rọ̀pọ̀ jẹ́ sọ-sími-n-sọ-sí-ọ. Ọmọ ẹ̀yìn náà, Jakọbu, sọ ọ́ ní ọ̀nà yìí: “Olúkúlùkù ènìyàn gbọ́dọ̀ yára nipa ọ̀rọ̀ gbígbọ́, lọ́ra nipa ọ̀rọ̀ sísọ.”—Jakọbu 1:19.
9 Ó tún ṣe pàtàkì pé kí a ṣọ́ bí a ti ń sọ̀rọ̀. A kò lè ka àwọn ọ̀rọ̀ gbàkan-o-ṣubú, asọ̀, tàbí àwọn ọ̀rọ̀ rírorò sí ìjùmọ̀sọ̀rọ̀pọ̀ aláṣeyọrí. (Owe 15:1; 21:9; 29:11, 20) Bí ohun tí a sọ bá tilẹ̀ tọ̀nà, bí a bá sọ ọ́ láti pani lára, pẹ̀lú ìgbéraga, tàbí ní ọ̀nà rírorò, ó ṣeé ṣe kí ó ba nǹkan jẹ́ ju kí ó tún un ṣe lọ. Ó yẹ kí ọ̀rọ̀ ẹnu wá jẹ́ èyí tí ó dùn létí, “tí a fi iyọ̀ dùn.” (Kolosse 4:6) Ó yẹ kí ọ̀rọ̀ wá dà bí “èso igi wúrà nínú agbọ̀n fàdákà.” (Owe 25:11) Àwọn ìdílé tí ó ti kọ́ bí a ti ń jùmọ̀ sọ̀rọ̀ pọ̀ dáradára ti gbé ìgbésẹ̀ ńlá síhà jíjèrè ayọ̀.
IPA PÀTÀKÌ TÍ ÌFẸ́ Ń KÓ
10. Irú ìfẹ́ wo ni ó ṣe kókó nínú ìgbéyàwó?
10 Ọ̀rọ̀ náà “ìfẹ́” fara hàn léraléra jálẹ̀ ìwé yìí. Ìwọ́ ha rántí irú ìfẹ́ tí a mẹ́nu kàn jù lọ? Òtítọ́ ni pé òòfà ìfẹ́ (Gíríìkì, eʹros) ń kó ipa pàtàkì nínú ìgbéyàwó, àti nínú ìgbéyàwó aláṣeyọrí, ọkọ àti ayá máa ń mú ìfẹ́ni jíjinlẹ̀ àti ìbádọ́rẹ̀ẹ́ (Gíríìkì, phi·liʹa) dàgbà fún ara wọn. Ṣùgbọ́n ìfẹ́ tí ọ̀rọ̀ Gíríìkì náà, a·gaʹpe, dúró fún, ni ó ṣe pàtàkì jù lọ. Ìfẹ́ yìí ni a ń fi hàn sí Jehofa, sí Jesu, àti sí aládùúgbò wa. (Matteu 22:37-39) Ìfẹ́ yìí ni Jehofa fi hàn sí ìran ènìyàn. (Johannu 3:16) Ẹ wo bí ó ti dára tó pé a lè fi irú ìfẹ́ kan náà hàn sí alábàáṣègbéyàwó wa àti àwọn ọmọ wa!—1 Johannu 4:19.
11. Báwo ni ìfẹ́ ṣe ń ṣiṣẹ́ fún ire ìgbéyàwó?
11 Nínú ìgbéyàwó, ìfẹ́ tí a gbé ga yìí jẹ́ “ìdè ìrẹ́pọ̀ pípé” ní tòótọ́. (Kolosse 3:14) Ó ń so tọkọtaya pọ̀, ó sì ń mú wọn fẹ́ láti ṣe ohun tí ó dára jù lọ fún ara wọn àti fún àwọn ọmọ wọn. Nígbà tí àwọn ìdílé bá dojú kọ àwọn ipò líle koko, ìfẹ́ ń ràn wọ́n lọ́wọ́ láti para pọ̀ yanjú àwọn ìṣòro. Bí tọkọtaya kan ti ń dàgbà, ìfẹ́ ń ràn wọ́n lọ́wọ́ láti ti ara wọn lẹ́yìn, àti láti máa bá a lọ láti mọyì ara wọn. “Ìfẹ́ . . . kì í wá awọn ire tirẹ̀ nìkan. . . . A máa mú ohun gbogbo mọ́ra, a máa gba ohun gbogbo gbọ́, a máa retí ohun gbogbo, a máa farada ohun gbogbo. Ìfẹ́ kì í kùnà láé.”—1 Korinti 13:4-8.
12. Èé ṣe tí ìfẹ́ tí tọkọtaya kan ní fún Ọlọrun fi ń fún ìgbéyàwó wọn lókun?
12 Ìdè ìgbéyàwó túbọ̀ máa ń lágbára sí i nígbà tí kì í bá ṣe ìfẹ́ láàárín tọkọtaya nìkan ni ó dè é, ṣùgbọ́n nígbà tí ìfẹ́ fún Jehofa bá jẹ́ ohun pàtàkì tí ó dè é. (Oniwasu 4:9-12) Èé ṣe? Ó dára, aposteli Johannu kọ̀wé pé: “Èyí ni ohun tí ìfẹ́ fún Ọlọrun túmọ̀ sí, pé kí a pa awọn àṣẹ rẹ̀ mọ́.” (1 Johannu 5:3) Nípa báyìí, tọkọtaya kan ní láti fi ìfọkànsin Ọlọrun kọ́ àwọn ọmọ wọn, kì í ṣe kìkì nítorí pé wọ́n nífẹ̀ẹ́ àwọn ọmọ wọn gan-an, ṣùgbọ́n nítorí pé èyí jẹ́ àṣẹ Jehofa. (Deuteronomi 6:6, 7) Wọ́n ní láti kọ ìwà pálapàla sílẹ̀ kì í ṣe kìkì nítorí pé wọ́n nífẹ̀ẹ́ ara wọn nìkan ni, ṣùgbọ́n ní pàtàkì nítorí pé wọ́n nífẹ̀ẹ́ Jehofa, ẹni tí “yoo dá awọn àgbèrè ati awọn panṣágà lẹ́jọ́.” (Heberu 13:4) Àní tí alábàáṣègbéyàwó kan bá ń fa ìṣòro ńlá nínú ìgbéyàwó, ìfẹ́ fún Jehofa yóò sún ẹnì kejì rẹ̀ láti máa bá títẹ̀ lé ìlànà Bibeli nìṣó. Aláyọ̀, ní ti gidi, ni àwọn ìdílé tí ìfẹ́ fún Jehofa ti fún ìfẹ́ fún ara wọn lókun!
ÌDÍLÉ TÍ Ń ṢE ÌFẸ́ ỌLỌRUN
13. Báwo ni ìpinnu láti ṣe ìfẹ́ Ọlọrun yóò ṣe ran ẹnì kọ̀ọ̀kan lọ́wọ́ láti tẹjú mọ́ àwọn ohun tí ó ṣe pàtàkì ní tòótọ́?
13 Ìgbésí ayé Kristian látòkèdélẹ̀ rọ̀ mọ́ ṣíṣe ìfẹ́ Ọlọrun. (Orin Dafidi 143:10) Ohun tí ìfọkànsin Ọlọrun túmọ̀ sí nìyẹn. Ṣíṣe ìfẹ́ Ọlọrun ń ran ìdílé lọ́wọ́ láti tẹjú mọ́ àwọn ohun ṣíṣe pàtàkì ní tòótọ́. (Filippi 1:9, 10) Fún àpẹẹrẹ, Jesu kìlọ̀ pé: “Mo wá lati fa ìpínyà, bá ọkùnrin kan lòdì sí baba rẹ̀, ati ọmọbìnrin kan lòdì sí ìyá rẹ̀, ati ọ̀dọ́ aya kan lòdì sí ìyá ọkọ rẹ̀. Nítòótọ́, awọn ọ̀tá ènìyàn yoo jẹ́ awọn ènìyàn agbo ilé oun fúnra rẹ̀.” (Matteu 10:35, 36) Gẹ́gẹ́ bí Jesu ti kìlọ̀ gan-an, ọ̀pọ̀ àwọn ọmọ ẹ̀yìn rẹ̀ ni àwọn mẹ́ḿbà ìdílé wọn ti ṣe inúnibíni sí. Ẹ wo irú ipò bíbani nínú jẹ́, ríroni lára tí èyí jẹ́! Síbẹ̀, ìdè ìdílé kò gbọdọ̀ lágbára ju ìfẹ́ tí a ní fún Jehofa Ọlọrun àti fún Jesu Kristi lọ. (Matteu 10:37-39) Bí ènìyàn bá fara dà á, láìka àtakò ìdílé sí, àwọn tí ń ṣàtakò náà lè yíwà padà nígbà tí wọ́n bá rí èso rere tí ìfọkànsin Ọlọrun ń mú jáde. (1 Korinti 7:12-16; 1 Peteru 3:1, 2) Bí ìyẹn kò bá tilẹ̀ ṣẹlẹ̀, kò sí ire wíwà pẹ́ títí tí ń tìdí kíkọ iṣẹ́ ìsìn Ọlọrun sílẹ̀ nítorí àtakò wá.
14. Báwo ni ìfẹ́ ọkàn láti ṣe ìfẹ́ Ọlọrun yóò ṣe ran àwọn òbí lọ́wọ́ láti gbé ìgbésẹ̀ lọ́nà tí ó ṣàǹfààní jù lọ fún àwọn ọmọ wọn?
14 Ṣíṣe ìfẹ́ Ọlọrun ń ran àwọn òbí lọ́wọ́ láti ṣe ìpinnu títọ́. Fún àpẹẹrẹ, ní àwọn agbègbè kan, àwọn òbí nítẹ̀sí láti wo àwọn ọmọ gẹ́gẹ́ bí ìdókòwò kan, wọ́n sì gbára lé àwọn ọmọ wọn láti bójú tó wọn ní ọjọ́ ogbó wọn. Bí ó tilẹ̀ tọ̀nà, tí ó sì bójú mu fún àwọn ọmọ tí ó ti dàgbà láti ṣaájò àwọn òbí wọn àgbàlagbà, irú ìgbatẹnirò bẹ́ẹ̀ kò yẹ kí ó mú kí àwọn òbí sún àwọn ọmọ wọn láti lépa ọ̀nà ìgbésí ayé onífẹ̀ẹ́ ọrọ̀ àlùmọ́ọ́nì. Àwọn òbí kò ṣe àwọn ọmọ wọn ní àǹfààní kankan bí wọ́n bá tọ́ wọn dàgbà láti ka ohun ìní ti ara sí ohun tí ó ṣe pàtàkì ju àwọn ohun tẹ̀mí lọ.—1 Timoteu 6:9.
15. Báwo ni ìyá Timoteu, Eunike, ṣe jẹ́ àpẹẹrẹ òbí títayọ lọ́lá kan tí ó ṣe ìfẹ́ Ọlọrun?
15 Eunike, màmá Timoteu ọ̀dọ́, ọ̀rẹ Paulu, jẹ́ àpẹẹrẹ àtàtà ní ti èyí. (2 Timoteu 1:5) Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé aláìgbàgbọ́ ni ó fẹ́, Eunike, àti ìyá Timoteu àgbà, Loide, ṣe àṣeyọrí nínú títọ́ Timoteu dàgbà láti lépa ìfọkànsin Ọlọrun. (2 Timoteu 3:14, 15) Nígbà tí Timoteu dàgbà tó, Eunike yọ̀ǹda fún un láti fi ilé sílẹ̀, kí ó sì bẹ̀rẹ̀ iṣẹ́ ìwàásù Ìjọba gẹ́gẹ́ bí alábàáṣiṣẹ́pọ̀ Paulu nínú iṣẹ́ míṣọ́nnárì rẹ̀. (Ìṣe 16:1-5) Ẹ wo bí inú rẹ̀ yóò ti dùn tó nígbà tí ọmọ rẹ̀ di míṣọ́nnárì títayọ lọ́lá kan! Ẹ̀kọ́ tí ó rí gbà ní kékeré hàn dáradára nínú ìfọkànsin Ọlọrun tí ó ní gẹ́gẹ́ bí àgbàlagbà kan. Dájúdájú, Eunike rí ìtẹ́lọ́rùn àti ìdùnnú nínú gbígbọ́ ìròyìn nípa iṣẹ́ òjíṣẹ́ adúróṣinṣin Timoteu, bí ojú tilẹ̀ lè máa ro ó.—Filippi 2:19, 20.
ÌDÍLÉ ÀTI ỌJỌ́ Ọ̀LA RẸ
16. Gẹ́gẹ́ bí ọmọ, ìbìkítà yíyẹ wo ni Jesu fi hàn, ṣùgbọ́n ète ṣíṣe kí ni ó ga jù lọ lọ́kàn rẹ̀?
16 A tọ́ Jesu dàgbà nínú ìdílé oníwà-bí-Ọlọ́run, àti gẹ́gẹ́ bí àgbàlagbà kan, ó fi ìbìkítà yíyẹ tí ọmọ ń fi hàn sí ìyá rẹ̀ hàn. (Luku 2:51, 52; Johannu 19:26) Bí ó ti wù kí ó rí, ète ṣíṣe ìfẹ́ Ọlọrun ni ó ga jù lọ lọ́kàn Jesu, fún un, èyí sì ní ṣíṣí ọ̀nà sílẹ̀ fún aráyé láti gbádùn ìyè àìnípẹ̀kun nínú. Èyí ni ó ṣe nígbà tí ó fi ìwàláàyè rẹ̀ pípé lélẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ìràpadà fún ẹ̀ṣẹ̀ aráyé.—Marku 10:45; Johannu 5:28, 29.
17. Ìfojúsọ́nà ológo wo ni ipa ọ̀nà ìṣòtítọ́ Jesu ṣí sílẹ̀ fún àwọn tí ń ṣe ìfẹ́ Ọlọrun?
17 Lẹ́yìn ikú Jesu, Jehofa jí i dìde sí ìyè ní ọ̀run, ó sì fún un ní ọlá àṣẹ ńlá, ó sì fi í jẹ Ọba Ìjọba ọ̀run ní àsẹ̀yìnwá-àsẹ̀yìnbọ̀. (Matteu 28:18; Romu 14:9; Ìṣípayá 11:15) Ẹbọ Jesu mú kí ó ṣeé ṣe kí a yan àwọn ẹ̀dá ènìyàn kan láti ṣàkóso pẹ̀lú rẹ̀ nínú Ìjọba yẹn. Ó tún ṣí ọ̀nà sílẹ̀ fún ìyókù aráyé, tí ó lọ́kàn títọ́, láti gbádùn ìwàláàyè pípé nínú ayé kan tí a ti mú padà sí ipò paradise. (Ìṣípayá 5:9, 10; 14:1, 4; 21:3-5; 22:1-4) Lónìí, ọ̀kan lára àwọn àǹfààní gíga jù lọ tí a ní jẹ́ láti sọ ìhìn rere ológo yìí fún àwọn aládùúgbò wa.—Matteu 24:14.
18. Ìránnilétí àti ìṣírí wo ni a fún àwọn ìdílé àti ẹnì kọ̀ọ̀kan?
18 Gẹ́gẹ́ bí aposteli Paulu ti fi hàn, gbígbé ìgbésí ayé onífọkànsin Ọlọrun ní ìlérí pé àwọn ènìyàn lè jogún àwọn ìbùkún nínú ìyè “tí ń bọ̀.” Dájúdájú, ọ̀nà tí ó dára jù lọ nìyí láti rí ayọ̀! Rántí pé, “ayé ń kọjá lọ bẹ́ẹ̀ sì ni ìfẹ́-ọkàn rẹ̀, ṣugbọn ẹni tí ó bá ń ṣe ìfẹ́-inú Ọlọrun ni yoo dúró títí láé.” (1 Johannu 2:17) Nípa báyìí, bóyá ọmọ ni ọ́ tàbí òbí, ọkọ tàbí aya, tàbí àgbàlagbà àpọ́n tí ó ní ọmọ tàbí tí kò ní ọmọ, là kàkà láti ṣe ìfẹ́ Ọlọrun. Àní nígbà tí o bá wà lábẹ́ ìkìmọ́lẹ̀ tàbí tí o dojú kọ àwọn ìṣòro ńlá pàápàá, má ṣe gbàgbé láé pé ìránṣẹ́ Ọlọrun alààyè ni o jẹ́. Nípa báyìí, ǹjẹ́ kí àwọn ìgbésẹ̀ rẹ mú ìdùnnú wá fún Jehofa. (Owe 27:11) Ǹjẹ́ kí ìwà rẹ yọrí sí ayọ̀ fún ọ nísinsìnyí àti ìyè àìnípẹ̀kun nínú ayé tuntun tí ń bọ̀!
BÁWO NI ÀWỌN ÌLÀNÀ BIBELI WỌ̀NYÍ ṢE LÈ ṢÈRÀNWỌ́ FÚN . . . ÌDÍLÉ RẸ LÁTI LÁYỌ̀?
A lè mú ìkóra-ẹni-níjàánu dàgbà.—Galatia 5:22, 23.
Pẹ̀lú ojú ìwòye tí ó tọ̀nà nípa ipò orí, àti ọkọ àtiaya ń wá ire tí ó dára jù lọ fún ìdílé.—Efesu 5:22-25, 28-33; 6:4.
Ìjùmọ̀sọ̀rọ̀pọ̀ ní fífetí sílẹ̀ nínú.—Jakọbu 1:19.
Ìfẹ́ fún Jehofa yóò fún ìgbéyàwó lókun.—1 Johannu 5:3.
Ṣíṣe ìfẹ́ Ọlọrun ni góńgó tí ó ṣe pàtàkì jù lọ fún ìdílé.—Orin Dafidi 143:10; 1 Timoteu 4:8.
[Àpótí tó wà ní ojú ìwé 188]
Ẹ̀BÙN WÍWÀ NÍ ÀPỌ́N
Kì í ṣe gbogbo ènìyàn ní ń ṣègbéyàwó. Kì í sì í ṣe gbogbo tọkọtaya ní ń yàn láti bímọ. Àpọ́n ni Jesu, ó sì sọ nípa wíwà ní àpọ́n gẹ́gẹ́ bí ẹ̀bùn kan nígbà tí ó bá jẹ́ “nítìtorí ìjọba awọn ọ̀run.” (Matteu 19:11, 12) Aposteli Paulu pẹ̀lú yàn láti má ṣe gbéyàwó. Ó sọ nípa ipò wíwà ní àpọ́n àti ṣíṣègbéyàwó gẹ́gẹ́ bí “ẹ̀bùn.” (1 Korinti 7:7, 8, 25-28) Nípa báyìí, bí ìwé yìí tilẹ̀ ti sọ̀rọ̀ lọ́pọ̀lọpọ̀ nípa àwọn ohun tí ó ní í ṣe pẹ̀lú ìgbéyàwó àti títọ́ ọmọ dàgbà, kò yẹ kí a gbàgbé àwọn ìbùkún àti èrè tí wíwà ní àpọ́n tàbí ṣíṣègbéyàwó láìbímọ lè mú wá.