ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • g96 1/8 ojú ìwé 31
  • Àlàyé Jessica

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

  • Àlàyé Jessica
  • Jí!—1996
  • Àpilẹ̀kọ Míì Tó Jọ ọ́
  • Ìtóye Ọ̀nà Ìwà Híhù tí Ó Yẹ Láti Bọ̀wọ̀ fún
    Àwọn Ẹlẹ́rìí Jèhófà àti Ìmọ̀ Ẹ̀kọ́
  • Kí Nìdí Táwa Ẹlẹ́rìí Jèhófà Fi Máa Ń Fi Tọ̀wọ̀tọ̀wọ̀ Kọ̀ Láti Ka Ẹ̀jẹ́ Tàbí Kọ Orin Orílẹ̀-Èdè?
    Àwọn Ìbéèrè Táwọn Èèyàn Sábà Máa Ń Béèrè Nípa Ẹlẹ́rìí Jèhófà
  • “Ìgbàlà Jẹ́ Ti Jèhófà”
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2002
  • Kíkí Àsíá, Dídìbò àti Sísin Ìlú Ẹni
    ‘Ẹ Dúró Nínú Ìfẹ́ Ọlọ́run’
Àwọn Míì
Jí!—1996
g96 1/8 ojú ìwé 31

Àlàyé Jessica

JESSICA, ọmọdébìnrin ọlọ́dún 13 kan láti United States, ni a yàn pẹ̀lú àwọn ẹlẹgbẹ́ rẹ̀ ní kíláàsì láti sọ̀rọ̀ lórí ẹṣin ọ̀rọ̀ náà, “Ọlọrun, Àsíá àti Orílẹ̀-Èdè.” Bí ó ti mọ̀ pé àwọn akẹ́kọ̀ọ́ ẹlẹgbẹ́ rẹ̀ ń tọpinpin nípa ìdí tí òun gẹ́gẹ́ bí ọ̀kan lára àwọn Ẹlẹ́rìí Jehofa kì í fi í kí àsíá, Jessica fi tìgboyàtìgboyà lo àǹfààní àyè tí ó ṣí sílẹ̀ yìí láti ṣàlàyé àwọn èrò ìgbàgbọ́ rẹ̀. Ohun tí ó tẹ̀ lé e yìí jẹ́ àyọkà láti inú àlàyé rẹ̀.

“Ní ìbẹ̀rẹ̀ ọjọ́ kọ̀ọ̀kan ní ilé ìwé, wọ́n máa ń sọ fún àwọn akẹ́kọ̀ọ́ láti ka ẹ̀jẹ́ ìtúúbá, ṣùgbọ́n nítorí ìgbàgbọ́ àti ìsìn mi, èmi kì í ṣe bẹ́ẹ̀. Ọ̀pọ̀ ènìyàn ń ṣe kàyéfì nípa ìdí rẹ̀. Èmi yóò sọ fún yín nísinsìnyí.

“Àwọn ọ̀rọ̀ tí ó ṣáájú nínú kíkí àsíá náà ni: ‘Mo jẹ́jẹ̀ẹ́ ìtúúbá fún àsíá.’ Ó dára, kí ni ìtúúbá? Ó jẹ́ ẹ̀jẹ́ ìtìlẹyìn, ìdúróṣinṣin àti ìfọkànsìn. Níwọ̀n bí mo ti jẹ́jẹ̀ẹ́ ìtúúbá mi fún Ọlọrun tẹ́lẹ̀tẹ́lẹ̀, n kò lè jẹ́jẹ̀ẹ́ ìtúúbá mi fún àsíá, n kì yóò sì ṣe bẹ́ẹ̀. Bí ó ti wù kí ó rí, pé n kò jọ́sìn tàbí jẹ́jẹ̀ẹ́ ìtúúbá mi fún àsíá kò túmọ̀ sí pé n kò bọ̀wọ̀ fún un.

“Ọlọrun ni ó ṣe pàtàkì jù lọ nínú ìgbésí ayé mi. Mo ń ṣe gbogbo ohun tí mo lè ṣe láti tẹ̀ lé àwọn òfin rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí a ti là á lẹ́sẹẹsẹ nínú Bibeli. Mo máa ń gbàdúrà sí i lójoojúmọ́, mo sì tún máa ń gbàdúrà nígbà tí mo bá nílò àfikún ìrànlọ́wọ́ tàbí ìṣírí. Mo sábà máa ń rí ìrànlọ́wọ́ àti ìṣírí yẹn gbà ní àkókò yíyẹ. Mo ti rí i pé, mo túbọ̀ ń láyọ̀ sí i nígbà tí mo bá fí Ọlọrun ṣáájú àti nígbà tí mo bá ṣe àwọn ohun tí òún ti pa láṣẹ fún wa láti ṣe.

“Nítorí náà, bí ó ti lẹ̀ jẹ́ pé, n kì í kí àsíá, mo bọ̀wọ̀ fún un, n kì yóò sì tàbùkù sí i lọ́nàkọnà. Ṣùgbọ́n, ìtúúbá mi wà fún Ọlọrun, ó sì rí bẹ́ẹ̀ gẹ́ẹ́, nítorí pé òun ni ó dá mi, mo sì jẹ ẹ́ ní gbèsè ìtúúbá yẹn.”

A béèrè pé kí àwọn akẹ́kọ̀ọ́ ní kíláàsì Jessica díye lé àlàyé tí wọ́n gbọ́. Ẹ wo bí Jessica ti láyọ̀ tó pé nítorí ìsapá rẹ̀, àwọn ẹlẹgbẹ́ rẹ̀ ní kíláàsì sọ pé, àwọn ti jèrè òye kíkún sí i nípa àwọn èrò ìgbàgbọ́ rẹ̀. Ní pàtàkì, àwọn èwe tí wọ́n ń fi tìgboyàtìgboyà sọ̀rọ̀ nípa àwọn ìlànà Bibeli ń mú ọkàn-àyà Jehofa Ọlọrun láyọ̀!—Owe 27:11.

    Yorùbá Publications (1987-2025)
    Jáde
    Wọlé
    • Yorùbá
    • Fi Ráńṣẹ́
    • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
    • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
    • Àdéhùn Nípa Lílò
    • Òfin
    • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
    • JW.ORG
    • Wọlé
    Fi Ráńṣẹ́