ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • w09 1/1 ojú ìwé 31
  • Ọ̀dọ́ Kan Tó Nígboyà

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

  • Ọ̀dọ́ Kan Tó Nígboyà
  • Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2009
  • Àpilẹ̀kọ Míì Tó Jọ ọ́
  • Bí Sódómù àti Gòmórà Ṣe Pa Run
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2008
  • Jésù Fi Iṣẹ́ Ìyanu Mú Àwọn Aláìsàn Lára Dá
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2008
  • Jésù Borí Ìdẹwò
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2009
  • Òye Jésù Ṣe Àwọn Tó Gbọ́rọ̀ Rẹ̀ Ní Kàyéfì
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2008
Àwọn Míì
Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2009
w09 1/1 ojú ìwé 31

Abala Àwọn Ọ̀dọ́

Ọ̀dọ́ Kan Tó Nígboyà

Ohun tó o máa ṣe: Ibi tí kò sáriwo ni kó o ti ṣe ìdánrawò yìí. Bó o bá ṣe ń ka àwọn ẹsẹ Ìwé Mímọ́ tó wà nísàlẹ̀ yìí, máa fojú inú wò ó bíi pé o wà níbi tọ́rọ̀ náà ti ń ṣẹlẹ̀, jẹ́ kó dà bíi pé ò ń gbọ́ báwọn èèyàn náà ṣe ń sọ̀rọ̀. Ronú nípa bóhun tó ò ń kà yẹn ṣe máa rí lára àwọn èèyàn wọ̀nyẹn. Kó o sì máa fojú inú wò ó bí ohun tó ń ṣẹlẹ̀ lọ́wọ́lọ́wọ́.

KA ÌTÀN NÁÀ DÁADÁA.—KA 1 SÁMÚẸ́LÌ 17:1-11, 26, 32-51.

Ṣàpèjúwe bó o ṣe rò pé Gòláyátì rí àti irú ohùn tó ní.

․․․․․

Bó tilẹ̀ jẹ́ pé Dáfídì kì í ṣe ọkàn lára àwọn ọmọ ogun Ísírẹ́lì, kí nìdí tó fi fẹ́ bá Gòláyátì jà? (Wo ẹsẹ 26.)

․․․․․

Kí ló fi Dáfídì lọ́kàn balẹ̀ pé Jèhófà máa ran òun lọ́wọ́? (Tún ka ẹsẹ 34 sí 37.)

․․․․․

ṢÈWÁDÌÍ KÓ O SÌ RONÚ JINLẸ̀.

Lo àwọn ìwé míì táwọn Ẹlẹ́rìí Jèhófà ṣe tó o ní lọ́wọ́ láti ṣèwádìí, kó o sì gbìyànjú láti mọ

(1) Bí Gòláyátì ṣe ga tó. (1 Sámúẹ́lì 17:4)

Ó lé díẹ̀ ní ẹsẹ bàtà mẹ́sàn-án = ․․․․․

(2) Bí ẹ̀wù Gòláyátì tí wọ́n fi àdàrọ irin ṣe ṣe wúwo tó. (1 Sámúẹ́lì 17:5)

Ó wúwo tó ẹgbẹ̀rún márùn-ún [5,000] ṣékélì bàbà = ․․․․․

(3) Bí ọ̀kọ̀ Gòláyátì ṣe wúwo tó. (1 Sámúẹ́lì 17:7)

Ọgọ́rùn-ún mẹ́fà [600] ṣékélì irin = ․․․․․

MÁA FOHUN TÓ O KỌ́ ṢÈWÀ HÙ. KỌ Ẹ̀KỌ́ TÓ O KỌ́ NÍPA . . .

Ìgboyà.

․․․․․

Gbígbẹ́kẹ̀lé Jèhófà dípò agbára ara rẹ.

․․․․․

ÀWỌN Ẹ̀KỌ́ MÍÌ.

Àwọn ohun ìdènà tó dà bíi Gòláyátì wo lò ń dojú kọ?

․․․․․

Kí ló ti ṣẹlẹ̀ sí ẹ (tàbí sáwọn ẹlòmíì) tó jẹ́ kó dá ẹ lójú pé Jèhófà ò ní pa ẹ́ tì?

․․․․․

KÍ LÓ WÚ Ẹ LÓRÍ JÙ LỌ NÍNÚ ÌTÀN INÚ BÍBÉLÌ YÌÍ, KÍ SÌ NÌDÍ?

․․․․․

    Yorùbá Publications (1987-2025)
    Jáde
    Wọlé
    • Yorùbá
    • Fi Ráńṣẹ́
    • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
    • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
    • Àdéhùn Nípa Lílò
    • Òfin
    • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
    • JW.ORG
    • Wọlé
    Fi Ráńṣẹ́