ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • w10 7/1 ojú ìwé 3
  • Ǹjẹ́ Èèyàn Lè Mọ Orúkọ Ọlọ́run?

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

  • Ǹjẹ́ Èèyàn Lè Mọ Orúkọ Ọlọ́run?
  • Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2010
  • Àpilẹ̀kọ Míì Tó Jọ ọ́
  • Orúkọ Ọlọ́run
    Jí!—2017
  • Bí O Ṣe Lè Mọ Orúkọ Ọlọ́run
    Jí!—2004
  • Idi Tí A Fi Gbọdọ Mọ Orukọ Ọlọrun
    Orukọ Atọrunwa naa Tí Yoo Wà Titilae
  • Kí Nìdí Tó Fi Yẹ Ká Máa Lo Orúkọ Ọlọ́run?
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2012
Àwọn Míì
Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2010
w10 7/1 ojú ìwé 3

Ǹjẹ́ Èèyàn Lè Mọ Orúkọ Ọlọ́run?

Kò sí àní-àní pé àpọ́nlé ńlá ló jẹ́ tó o bá láǹfààní láti fi orúkọ tí ẹni pàtàkì kan ń jẹ́ pè é nígbà tó nawọ́ sí ẹ pé kí o kí òun. Ìdí tó fi rí bẹ́ẹ̀ ni pé orúkọ oyè bí “Ààrẹ,”  “Kábíyèsí,” tàbí  “Olóyè” la máa fi ń ṣáájú orúkọ àwọn ẹni pàtàkì. Torí náà, bí ẹnì kan tó wà ní ipò ọlá bá dìídì sọ fún ọ pé kó o máa fi orúkọ tóun ń jẹ́ gan-an pe òun tó o bá fẹ́ bá òun sọ̀rọ̀, wàá mọyì àǹfààní yìí gan-an.

ỌLỌ́RUN tòótọ́ sọ fún wa nínú Bíbélì Ọ̀rọ̀ rẹ̀ pé: “Èmi ni Jèhófà. Èyí ni orúkọ mi.” (Aísáyà 42:8) Bó tilẹ̀ jẹ́ pé ó tún ní ọ̀pọ̀ orúkọ oyè, irú bí “Ẹlẹ́dàá,” “Olódùmarè” àti “Olúwa Ọba Aláṣẹ,” síbẹ̀, ó fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ olóòótọ́ láǹfààní láti máa fi orúkọ tó ń jẹ́ gan-an pè é.

Bí àpẹẹrẹ, lákòókò kan tí wòlíì Mósè ń bẹ Ọlọ́run, ó bẹ̀rẹ̀ ọ̀rọ̀ rẹ̀ báyìí pé: “Dákun, Jèhófà.” (Ẹ́kísódù 4:10) Nígbà ìyàsímímọ́ tẹ́ńpìlì tó wà ní Jerúsálẹ́mù, Sólómọ́nì Ọba bẹ̀rẹ̀ àdúrà rẹ̀ pé: “Ìwọ Jèhófà.” (1 Àwọn Ọba 8:22, 23) Nígbà tí wòlíì Aísáyà ń gbàdúrà nítorí àwọn ọmọ Ísírẹ́lì, ó sọ pé: “Ìwọ, Jèhófà, ni Baba wa.” (Aísáyà 63:16) Kò sí iyè méjì pé, Bàbá wa ọ̀run ń fẹ́ ká máa fi orúkọ òun pe òun.

Bó tilẹ̀ jẹ́ pé ó ṣe pàtàkì láti máa pe orúkọ tí Ọlọ́run ń jẹ́, ìyẹn Jèhófà, ọ̀pọ̀ nǹkan ló rọ̀ mọ́ mímọ orúkọ yẹn. Nígbà tí Jèhófà ń sọ̀rọ̀ nípa ẹni tó nífẹ̀ẹ́ rẹ̀ tó sì gbẹ́kẹ̀ lé e, ó ṣèlérí pé: “Èmi yóò dáàbò bò ó nítorí pé ó ti wá mọ orúkọ mi.” (Sáàmù 91:14) Ó ṣe kedere pé àwọn nǹkan kan wà tó rọ̀ mọ́ mímọ orúkọ Ọlọ́run, wọ́n sì ṣe pàtàkì téèyàn bá fẹ́ rí ààbò Ọlọ́run. Kí ló wá yẹ kó o ṣe kó o tó lè mọ ẹni tó ń jẹ́ Jèhófà?

    Yorùbá Publications (1987-2025)
    Jáde
    Wọlé
    • Yorùbá
    • Fi Ráńṣẹ́
    • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
    • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
    • Àdéhùn Nípa Lílò
    • Òfin
    • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
    • JW.ORG
    • Wọlé
    Fi Ráńṣẹ́