ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • w11 5/1 ojú ìwé 10
  • Ohun Tó Dára Jù Ń Bọ̀ Lọ́jọ́ Iwájú!

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

  • Ohun Tó Dára Jù Ń Bọ̀ Lọ́jọ́ Iwájú!
  • Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2011
  • Àpilẹ̀kọ Míì Tó Jọ ọ́
  • Ohun Tí Bíbélì Sọ
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2015
  • Ìdí Tó Fi Dá Wa Lójú Pé Ọ̀la Máa Dáa
    Àkójọ Àpilẹ̀kọ àti Fídíò
  • Ayé Titun Iyanu naa ti Ọlọrun Ṣe
    Ọlọrun Ha Bikita Nipa Wa Niti Gidi Bi?
  • Ohun Tí Ijọba naa Tumọsi fun Ilẹ̀-ayé Wa
    “Kí Ijọba Rẹ Dé”
Àwọn Míì
Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2011
w11 5/1 ojú ìwé 10

Ohun Tó Dára Jù Ń Bọ̀ Lọ́jọ́ Iwájú!

“Àti pé ní ìgbà díẹ̀ sí i, ẹni burúkú kì yóò sì sí mọ́ . . . Ṣùgbọ́n àwọn ọlọ́kàn tútù ni yóò ni ilẹ̀ ayé, ní tòótọ́, wọn yóò sì rí inú dídùn kíkọyọyọ nínú ọ̀pọ̀ yanturu àlàáfíà.”—SÁÀMÙ 37:10, 11.

ṢÉ O fẹ́ kí àsọtẹ́lẹ̀ tó wà lókè yìí ṣẹ? Ó dájú pé wàá fẹ́ kó rí bẹ́ẹ̀. Àwọn ìdí tó lẹ́sẹ̀ nílẹ̀ wà pé ó máa tó ṣẹ.

Àwọn àpilẹ̀kọ tó ṣáájú èyí sọ nípa àwọn kan lára àwọn àsọtẹ́lẹ̀ Bíbélì tó fi hàn kedere pé “àwọn ọjọ́ ìkẹyìn” la wà yìí. (2 Tímótì 3:1-5) Ọlọ́run mí sí àwọn tó kọ Bíbélì láti sọ àsọtẹ́lẹ̀ àwọn ìṣẹ̀lẹ̀ yẹn kí á bàa lè ní ìrètí. (Róòmù 15:4) Bí àwọn àsọtẹ́lẹ̀ yẹn ṣe ń ṣẹ fi hàn pé àwọn ìṣòro tí à ń dojú kọ nísinsìnyí yóò dópin láìpẹ́.

Kí ló máa wáyé lẹ́yìn àwọn ọjọ́ ìkẹyìn? Ìjọba Ọlọ́run máa ṣàkóso gbogbo aráyé. (Mátíù 6:9) Wo ohun tí Bíbélì sọ nípa bí ipò ayé ṣe máa rí nígbà yẹn:

● Kò ní sí ebi mọ́. “Ọ̀pọ̀ rẹpẹtẹ ọkà yóò wá wà lórí ilẹ̀; àkúnwọ́sílẹ̀ yóò wà ní orí àwọn òkè ńlá.”—Sáàmù 72:16.

● Kò ní sí àrùn mọ́. “Kò sì sí olùgbé kankan tí yóò sọ pé: ‘Àìsàn ń ṣe mí.’”—Aísáyà 33:24.

● Ilẹ̀ ayé máa di ọ̀tun. “Aginjù àti ẹkùn ilẹ̀ aláìlómi yóò yọ ayọ̀ ńláǹlà, pẹ̀tẹ́lẹ̀ aṣálẹ̀ yóò sì kún fún ìdùnnú, yóò sì yọ ìtànná gẹ́gẹ́ bí sáfúrónì.”—Aísáyà 35:1.

Èyí jẹ́ díẹ̀ lára àsọtẹ́lẹ̀ amóríyá tí Bíbélì sọ, tí yóò ṣẹ láìpẹ́. O kò ṣe ní kí àwọn Ẹlẹ́rìí Jèhófà fi ìdí tó fi dá wọn lójú hàn ẹ́ pé ohun tó dára jù ń bọ̀ lọ́jọ́ iwájú.

    Yorùbá Publications (1987-2025)
    Jáde
    Wọlé
    • Yorùbá
    • Fi Ráńṣẹ́
    • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
    • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
    • Àdéhùn Nípa Lílò
    • Òfin
    • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
    • JW.ORG
    • Wọlé
    Fi Ráńṣẹ́