ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • w13 8/1 ojú ìwé 16
  • Ohun Tí Bíbélì Sọ

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

  • Ohun Tí Bíbélì Sọ
  • Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2013
  • Àpilẹ̀kọ Míì Tó Jọ ọ́
  • Sún Mọ́ Ọlọ́run Nípasẹ̀ Àdúrà
    Kí Ni Bíbélì Fi Kọ́ni Gan-an?
  • Àǹfààní Pàtàkì Ni Àdúrà Jẹ́
    Kí Ni Bíbélì Kọ́ Wa?
  • Adura Awọn Wo Ni A Ndahun?
    Ilé-Ìṣọ́nà Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—1991
  • Ǹjẹ́ Ó Tiẹ̀ Láǹfààní Tádùúrà Gbígbà Ń Ṣe?
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2000
Àwọn Míì
Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2013
w13 8/1 ojú ìwé 16
[Àwòrán tó wà ní ojú ìwé 16]

Ohun Tí Bíbélì Sọ

Ṣé gbogbo àdúrà ni Ọlọ́run máa ń gbọ́?

Ọlọ́run máa ń tẹ́tí sí àwọn èèyàn ní gbogbo orílẹ̀-èdè. (Sáàmù 145:18, 19) Bíbélì Ọ̀rọ̀ rẹ̀ rọ̀ wá pé ká máa sọ ohunkóhun tó bá ń jẹ wá lọ́kàn fún un. (Fílípì 4:6, 7) Síbẹ̀, àwọn àdúrà kan wà tí inú Ọlọ́run ò dùn sí. Bí àpẹẹrẹ, inú Ọlọ́run ò dùn sí kéèyàn máa gba àdúrà àkọ́sórí.—Ka Mátíù 6:7.

Bákan náà, inú Jèhófà kì í dùn sí àdúrà àwọn tó ń mọ̀ọ́mọ̀ rú òfin rẹ̀. (Òwe 28:9) Bí àpẹẹrẹ, láyé ìgbà tí wọ́n ń kọ Bíbélì, Ọlọ́run kò fetí sí àdúrà àwọn ọmọ Ísírẹ́lì tí wọ́n pààyàn. Èyí jẹ́ ká mọ̀ pé, tí a bá fẹ́ kí Ọlọ́run gbọ́ àdúrà wa àwọn ohun kan wà tí a gbọ́dọ̀ ṣe.—Ka Aísáyà 1:15.

Kí la gbọ́dọ̀ ṣe kí Ọlọ́run tó gbọ́ àdúrà wa?

Bí a kò bá ní ìgbàgbọ́, kò sí bí a ṣe lè sún mọ́ Ọlọ́run. (Jákọ́bù 1:5, 6) Ó gbọ́dọ̀ dá wa lójú pé Ọlọ́run wà àti pé ọ̀rọ̀ wa jẹ ẹ́ lógún. A gbọ́dọ̀ máa kẹ́kọ̀ọ́ kí ìgbàgbọ́ wa lè túbọ̀ jinlẹ̀ sí i, torí pé orí àwọn ẹ̀rí àti ìdánilójú tó wà nínú Ọ̀rọ̀ Ọlọ́run ni ìgbàgbọ́ tòótọ́ dá lé.—Ka Hébérù 11:1, 6.

Ó yẹ ká máa gbàdúrà tọkàntọkàn àti pẹ̀lú ìrẹ̀lẹ̀. Kódà, Jésù Ọmọ Ọlọ́run rẹ ara rẹ̀ sílẹ̀ nígbà tó ń gbàdúrà. (Lúùkù 22:41, 42) Torí náà, dípò ká máa yan ohun tí a fẹ́ lé Ọlọ́run lọ́wọ́, ṣe ló yẹ ká gbìyànjú láti mọ ohun tí ó fẹ́ ká ṣe, tí a bá sì ń ka Bíbélì la tó lè mọ̀ wọ́n. Èyí á jẹ́ kí àdúrà wa máa bá ìfẹ́ Ọlọ́run mu.—Ka 1 Jòhánù 5:14.

Tó o bá fẹ́ ìsọfúnni síwájú sí i, ka orí 17 nínú ìwé yìí. Àwa Ẹlẹ́rìí Jèhófà la ṣe é

O lè wà á jáde lórí www.jw.org/yo

    Yorùbá Publications (1987-2025)
    Jáde
    Wọlé
    • Yorùbá
    • Fi Ráńṣẹ́
    • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
    • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
    • Àdéhùn Nípa Lílò
    • Òfin
    • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
    • JW.ORG
    • Wọlé
    Fi Ráńṣẹ́