ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • w15 12/1 ojú ìwé 3
  • Kí Nìdí Tó Fi Yẹ Kó O Lóye Bíbélì?

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

  • Kí Nìdí Tó Fi Yẹ Kó O Lóye Bíbélì?
  • Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2015
  • Àpilẹ̀kọ Míì Tó Jọ ọ́
  • Ohun Tí Bíbélì Sọ
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2013
  • Ìwé Kan Tó Yẹ Ká Mọ̀ Dunjú
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2015
  • Bá A Ṣe Lè Ṣèrànwọ́ Fáwọn Tá Ò Tíì Lè Fi Ìwé Bíbélì Fi Kọ́ni Kọ́ Lẹ́kọ̀ọ́
    Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba Wa—2013
  • Ẹ̀kọ́ Òtítọ́ Tínú Ọlọ́run Dùn Sí
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2005
Àwọn Míì
Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2015
w15 12/1 ojú ìwé 3

KÓKÓ IWÁJÚ ÌWÉ | O LÈ LÓYE BÍBÉLÌ

Kí Nìdí Tó Fi Yẹ Kó O Lóye Bíbélì?

“Bíbélì gbayì gan-an nínú àwọn ìwé ìsìn. Àmọ́ ìwé àjèjì ni, kò sì wúlò fún àwa ọmọ ilẹ̀ Ṣáínà.”​—LIN, ṢÁÍNÀ.

“Mi ò lóye ohun tó wà nínú ìwé ìsìn Híńdù tí mò ń ṣe. Báwo ni màá ṣe wá lóye Bíbélì?”​—AMIT, INDIA.

“Mo gbà pé ọba ìwé ni Bíbélì, torí ó lọ́jọ́ lórí, ó sì ń tà gan-an. Àmọ́, mi ò ríkan rí.”​—YUMIKO, JAPAN.

Ọ̀pọ̀ èèyàn kárí ayé ló gbà pé ọba ìwé ni Bíbélì. Síbẹ̀, wọn ò mọ ohun tó wà nínú rẹ̀ tàbí kó jẹ́ díẹ̀ ni ohun tí wọ́n mọ̀ níbẹ̀. Ìṣòro yìí wọ́pọ̀ láàárín àwọn tó ń gbé ní ilẹ̀ Éṣíà, ó sì tún wà láwọn àgbègbè tí Bíbélì pọ̀ sí pàápàá.

Obìnrin kan ń ka Bíbélì

O lè máa ronú pé, ‘Kí nìdí tó fi yẹ kí n lóye Bíbélì?’ Tó o bá lóye ohun tó wà nínú Bíbélì:

  • Wàá ní ìtẹ́lọ́rùn, wàá sì láyọ̀

  • Wàá lè kojú àwọn ìṣòro ìdílé

  • Wàá lè gbé àwọn àníyàn ìgbésí ayé kúrò lọ́kàn

  • Àárín ìwọ àtàwọn èèyàn máa túbọ̀ gún

  • Wàá mọ bí èèyàn ṣe ń ṣọ́wó ná

Wo àpẹẹrẹ Yoshiko tó ń gbé ní Japan. Ó ti máa ń ṣe kàyéfì nípa ohun tó wà nínú Bíbélì, ló bá pinnu láti kà á. Kí ni àbájáde rẹ̀? Ó sọ pé: “Bíbélì ti jẹ́ káyé mi nítumọ̀, ó sì jẹ́ kí n mọ̀ pé ọ̀la ń bọ̀ wá dáa.” Ó wá fí kún un pé: “Ní báyìí, ọkàn mi balẹ̀.” Amit tá a sọ̀rọ̀ rẹ̀ lókè pinnu láti kẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì, ó wá sọ pé: “Ohun tí mo bá nínú rẹ̀ yà mí lẹ́nu. Mo rí i pé àwọn nǹkan tó máa ṣe gbogbo èèyàn láǹfààní ló wà nínú Bíbélì.”

Bíbélì ti tún ayé ọ̀pọ̀ àwọn èèyàn ṣe kárí ayé. Ìwọ náà lè yẹ̀ ẹ́ wò, kó o sì rí bó ṣe máa ṣe ẹ́ láǹfààní.

A Satisfying Life—How to Attain It

Tó o bá fẹ́ àlàyé sí i nípa bí Bíbélì ṣe lè ṣe ẹ́ láǹfààní, wo ìwé náà A Satisfying Life​—How to Attain It. Àwa Ẹlẹ́rìí Jèhófà la ṣe é.

    Yorùbá Publications (1987-2025)
    Jáde
    Wọlé
    • Yorùbá
    • Fi Ráńṣẹ́
    • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
    • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
    • Àdéhùn Nípa Lílò
    • Òfin
    • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
    • JW.ORG
    • Wọlé
    Fi Ráńṣẹ́