25 “Sọ fún Áárónì àti àwọn ọmọ rẹ̀ pé, ‘Òfin ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀+ nìyí: Ibi tí wọ́n ti ń pa ẹran ẹbọ sísun+ ni kí wọ́n ti pa ẹran ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ níwájú Jèhófà. Ohun mímọ́ jù lọ ni. 26 Àlùfáà tó fi rú ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ ló máa jẹ ẹ́.+ Ibi mímọ́ ni kó ti jẹ ẹ́, nínú àgbàlá àgọ́ ìpàdé.+
13 Kó wá pa ọmọ àgbò náà níbi tí wọ́n ti máa ń pa ẹran+ ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ àti ẹran ẹbọ sísun, ní ibi mímọ́, torí pé àlùfáà ló ni+ ẹbọ ẹ̀bi, bíi ti ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀. Ohun mímọ́ jù lọ ni.+