ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • 1 Àwọn Ọba 16:33
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 33 Áhábù tún ṣe òpó òrìṣà.*+ Áhábù sì ṣe ohun tó bí Jèhófà Ọlọ́run Ísírẹ́lì nínú ju gbogbo àwọn ọba Ísírẹ́lì tó jẹ ṣáájú rẹ̀ lọ.

  • 1 Àwọn Ọba 21:4
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 4 Torí náà, Áhábù wá sínú ilé rẹ̀, ó dì kunkun, ó sì dorí kodò nítorí èsì tí Nábótì ará Jésírẹ́lì fún un, nígbà tó sọ pé: “Mi ò ní fún ọ ní ogún àwọn baba ńlá mi.” Ó wá dùbúlẹ̀ sórí ibùsùn rẹ̀, ó gbé ojú sẹ́gbẹ̀ẹ́ kan, ó kọ̀, kò jẹun.

  • 1 Àwọn Ọba 21:20-22
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 20 Áhábù sọ fún Èlíjà pé: “O ti wá mi kàn, ìwọ ọ̀tá mi!”+ Ó dáhùn pé: “Mo ti wá ọ kàn. ‘Nítorí o ti pinnu* láti máa ṣe ohun tó burú lójú Jèhófà,+ 21 màá mú àjálù bá ọ, màá gbá ọ dà nù bí ẹni gbálẹ̀, màá sì pa gbogbo ọkùnrin* ilé Áhábù run,+ títí kan àwọn aláìní àti àwọn aláìníláárí ní Ísírẹ́lì.+ 22 Màá sì ṣe ilé rẹ bí ilé Jèróbóámù+ ọmọ Nébátì àti bí ilé Bááṣà+ ọmọ Áhíjà, nítorí o ti mú mi bínú, o sì ti mú kí Ísírẹ́lì ṣẹ̀.’

  • 2 Àwọn Ọba 10:1
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 10 Áhábù+ ní àádọ́rin (70) ọmọkùnrin ní Samáríà. Nítorí náà, Jéhù kọ àwọn lẹ́tà, ó sì fi wọ́n ránṣẹ́ sí Samáríà, sí àwọn ìjòyè Jésírẹ́lì, àwọn àgbààgbà+ àti àwọn tó ń tọ́jú àwọn ọmọ Áhábù,* ó sọ pé:

Yorùbá Publications (1987-2025)
Jáde
Wọlé
  • Yorùbá
  • Fi Ráńṣẹ́
  • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
  • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
  • Àdéhùn Nípa Lílò
  • Òfin
  • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
  • JW.ORG
  • Wọlé
Fi Ráńṣẹ́