ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • 2 Àwọn Ọba 20:16, 17
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 16 Àìsáyà wá sọ fún Hẹsikáyà pé: “Gbọ́ ọ̀rọ̀ Jèhófà,+ 17 ‘Wò ó! Ọjọ́ ń bọ̀ tí wọ́n máa kó gbogbo ohun tó wà nínú ilé* rẹ àti gbogbo ohun tí àwọn baba ńlá rẹ ti kó jọ títí di òní yìí lọ sí Bábílónì.+ Kò ní ku nǹkan kan,’ ni Jèhófà wí.

  • Àìsáyà 39:6
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 6 ‘Wò ó! Ọjọ́ ń bọ̀ tí wọ́n máa kó gbogbo ohun tó wà nínú ilé* rẹ àti gbogbo ohun tí àwọn baba ńlá rẹ ti kó jọ títí di òní yìí lọ sí Bábílónì. Kò ní ku nǹkan kan,’+ ni Jèhófà wí.+

  • Jeremáyà 27:19-22
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 19 “Nítorí ohun tí Jèhófà Ọlọ́run àwọn ọmọ ogun sọ nìyí nípa àwọn òpó,+ Òkun,*+ àwọn kẹ̀kẹ́ ẹrù+ àti àwọn nǹkan èlò tó ṣẹ́ kù nínú ìlú yìí, 20 èyí tí Nebukadinésárì ọba Bábílónì ò kó lọ nígbà tó mú Jekonáyà ọmọ Jèhóákímù, ọba Júdà, láti Jerúsálẹ́mù lọ sí ìgbèkùn ní Bábílónì pẹ̀lú gbogbo àwọn èèyàn pàtàkì Júdà àti Jerúsálẹ́mù.+ 21 Bẹ́ẹ̀ ni, ohun tí Jèhófà Ọlọ́run àwọn ọmọ ogun, Ọlọ́run Ísírẹ́lì, sọ nípa àwọn nǹkan èlò tó ṣẹ́ kù ní ilé Jèhófà àti ní ilé* ọba Júdà àti ní Jerúsálẹ́mù nìyí: 22 ‘“Bábílónì ni a ó kó wọn wá,+ ibẹ̀ sì ni wọ́n á máa wà títí di ọjọ́ tí màá yí ojú mi sí wọn,” ni Jèhófà wí. “Ìgbà náà ni màá mú wọn pa dà wá, tí màá sì mú wọn bọ̀ sípò ní ibí yìí.”’”+

  • Jeremáyà 52:17
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 17 Àwọn ará Kálídíà fọ́ àwọn òpó bàbà+ ilé Jèhófà àti àwọn kẹ̀kẹ́ ẹrù + àti Òkun bàbà+ tó wà ní ilé Jèhófà sí wẹ́wẹ́, wọ́n sì kó gbogbo bàbà náà lọ sí Bábílónì.+

Yorùbá Publications (1987-2025)
Jáde
Wọlé
  • Yorùbá
  • Fi Ráńṣẹ́
  • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
  • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
  • Àdéhùn Nípa Lílò
  • Òfin
  • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
  • JW.ORG
  • Wọlé
Fi Ráńṣẹ́