-
Jeremáyà 27:19-22Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
-
-
19 “Nítorí ohun tí Jèhófà Ọlọ́run àwọn ọmọ ogun sọ nìyí nípa àwọn òpó,+ Òkun,*+ àwọn kẹ̀kẹ́ ẹrù+ àti àwọn nǹkan èlò tó ṣẹ́ kù nínú ìlú yìí, 20 èyí tí Nebukadinésárì ọba Bábílónì ò kó lọ nígbà tó mú Jekonáyà ọmọ Jèhóákímù, ọba Júdà, láti Jerúsálẹ́mù lọ sí ìgbèkùn ní Bábílónì pẹ̀lú gbogbo àwọn èèyàn pàtàkì Júdà àti Jerúsálẹ́mù.+ 21 Bẹ́ẹ̀ ni, ohun tí Jèhófà Ọlọ́run àwọn ọmọ ogun, Ọlọ́run Ísírẹ́lì, sọ nípa àwọn nǹkan èlò tó ṣẹ́ kù ní ilé Jèhófà àti ní ilé* ọba Júdà àti ní Jerúsálẹ́mù nìyí: 22 ‘“Bábílónì ni a ó kó wọn wá,+ ibẹ̀ sì ni wọ́n á máa wà títí di ọjọ́ tí màá yí ojú mi sí wọn,” ni Jèhófà wí. “Ìgbà náà ni màá mú wọn pa dà wá, tí màá sì mú wọn bọ̀ sípò ní ibí yìí.”’”+
-