ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • 2 Àwọn Ọba 22:18, 19
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 18 Àmọ́, ní ti ọba Júdà tó rán yín pé kí ẹ lọ wádìí lọ́dọ̀ Jèhófà, ẹ sọ fún un pé, “Ohun tí Jèhófà Ọlọ́run Ísírẹ́lì sọ nìyí: ‘Ní ti àwọn ọ̀rọ̀ tí o gbọ́, 19 nítorí pé ọlọ́kàn tútù ni ọ́* tí o sì rẹ ara rẹ sílẹ̀+ níwájú Jèhófà bí o ṣe gbọ́ ohun tí mo sọ pé màá ṣe sí ibí yìí àti sí àwọn tó ń gbé ibẹ̀, pé wọ́n á di ohun àríbẹ̀rù àti ẹni ègún, tí o sì fa aṣọ rẹ ya,+ tí ò ń sunkún níwájú mi, èmi náà ti gbọ́ ohun tí o sọ, ni Jèhófà wí.

  • 2 Kíróníkà 33:13
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 13 Ó ń gbàdúrà sí Ọlọ́run, ẹ̀bẹ̀ rẹ̀ sì mú kí àánú ṣe Ọlọ́run, ó gbọ́ ẹ̀bẹ̀ rẹ̀ fún ojú rere, ó sì mú un pa dà sí Jerúsálẹ́mù sí ipò ọba rẹ̀.+ Mánásè sì wá mọ̀ pé Jèhófà ni Ọlọ́run tòótọ́.+

  • Sáàmù 22:24
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 24 Nítorí kò gbójú fo ìyà tó ń jẹ ẹni tí ara ń ni, kò sì ṣàìka ìpọ́njú rẹ̀ sí;+

      Kò gbé ojú rẹ̀ pa mọ́ fún un.+

      Nígbà tó ké pè é fún ìrànlọ́wọ́, ó gbọ́.+

  • Sáàmù 34:18
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 18 Jèhófà wà nítòsí àwọn tó ní ọgbẹ́ ọkàn;+

      Ó ń gba àwọn tí àárẹ̀ bá ẹ̀mí wọn* là.+

  • Òwe 28:13
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 13 Ẹni tó bá ń bo àwọn ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀ mọ́lẹ̀ kò ní ṣàṣeyọrí,+

      Àmọ́ ẹni tó bá jẹ́wọ́, tó sì fi wọ́n sílẹ̀ la ó fi àánú hàn sí.+

  • Àìsáyà 57:15
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 15 Torí ohun tí Ẹni Gíga àti Ẹni Tó Ta Yọ sọ nìyí,

      Tó wà láàyè* títí láé,+ tí orúkọ rẹ̀ sì jẹ́ mímọ́:+

      “Ibi gíga àti ibi mímọ́ ni mò ń gbé,+

      Àmọ́ mo tún ń gbé pẹ̀lú àwọn tí a tẹ̀ rẹ́, tí wọ́n sì rẹ̀wẹ̀sì ní ẹ̀mí,

      Láti mú kí ẹ̀mí ẹni tó rẹlẹ̀ sọ jí,

      Kí n sì mú kí ọkàn àwọn tí a tẹ̀ rẹ́ sọ jí.+

  • Lúùkù 15:22-24
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 22 Àmọ́ bàbá náà sọ fún àwọn ẹrú rẹ̀ pé, ‘Ó yá! ẹ mú aṣọ wá, aṣọ tó dáa jù, kí ẹ wọ̀ ọ́ fún un, kí ẹ fi òrùka sí i lọ́wọ́, kí ẹ sì wọ bàtà sí i lẹ́sẹ̀. 23 Kí ẹ tún mú ọmọ màlúù tó sanra wá, kí ẹ dúńbú rẹ̀, ká jọ jẹun, ká sì yọ̀, 24 torí pé ọmọ mi yìí kú, àmọ́ ó ti pa dà wà láàyè;+ ó sọ nù, a sì rí i.’ Wọ́n wá bẹ̀rẹ̀ sí í gbádùn ara wọn.

  • Lúùkù 18:13, 14
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 13 Àmọ́ agbowó orí náà dúró ní ọ̀ọ́kán, kò fẹ́ gbé ojú rẹ̀ sókè láti wo ọ̀run pàápàá, ṣùgbọ́n ó ń lu àyà rẹ̀ ṣáá, ó ń sọ pé, ‘Ọlọ́run, ṣàánú mi,* ẹlẹ́ṣẹ̀ ni mí.’+ 14 Mo sọ fún yín, ọkùnrin yìí sọ̀ kalẹ̀ lọ sílé rẹ̀, a sì kà á sí olódodo ju Farisí yẹn lọ.+ Torí pé gbogbo ẹni tó bá gbé ara rẹ̀ ga, a máa rẹ̀ ẹ́ sílẹ̀, àmọ́ ẹnikẹ́ni tó bá rẹ ara rẹ̀ sílẹ̀, a máa gbé e ga.”+

Yorùbá Publications (1987-2025)
Jáde
Wọlé
  • Yorùbá
  • Fi Ráńṣẹ́
  • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
  • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
  • Àdéhùn Nípa Lílò
  • Òfin
  • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
  • JW.ORG
  • Wọlé
Fi Ráńṣẹ́