ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • Diutarónómì 31:16
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 16 Jèhófà sọ fún Mósè pé: “Wò ó! O ò ní pẹ́ kú,* àwọn èèyàn yìí á sì bẹ̀rẹ̀ sí í bá àwọn ọlọ́run àjèjì tó yí wọn ká ní ilẹ̀ tí wọ́n ń lọ ṣe àgbèrè ẹ̀sìn.+ Wọ́n á pa mí tì,+ wọ́n á sì da májẹ̀mú mi tí mo bá wọn dá.+

  • Diutarónómì 32:15
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    •  15 Nígbà tí Jéṣúrúnì* sanra tán, ó di ọlọ̀tẹ̀, ó sì ń tàpá.

      O ti sanra, o ti ki, o sì ti kún.+

      Ó wá pa Ọlọ́run tì, ẹni tó dá a,+

      Ó sì fojú àbùkù wo Àpáta ìgbàlà rẹ̀.

  • Àwọn Onídàájọ́ 2:11
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 11 Àwọn ọmọ Ísírẹ́lì ṣe ohun tó burú lójú Jèhófà, wọ́n sì sin* àwọn Báálì.+

  • 2 Sámúẹ́lì 20:1
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 20 Ọkùnrin oníwàhálà kan wà tó ń jẹ́ Ṣébà,+ ọmọ Bíkíráì láti ẹ̀yà Bẹ́ńjámínì ni. Ó fun ìwo,+ ó sì sọ pé: “Àwa kò ní ìpín kankan nínú Dáfídì, a kò sì ní ogún kankan nínú ọmọ Jésè.+ Ìwọ Ísírẹ́lì! Kí kálukú pa dà sọ́dọ̀ àwọn ọlọ́run* rẹ̀.”+

  • Nehemáyà 9:26
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 26 “Àmọ́, wọ́n ya aláìgbọràn, wọ́n ṣọ̀tẹ̀ sí ọ,+ wọ́n sì kẹ̀yìn sí Òfin rẹ.* Wọ́n pa àwọn wòlíì rẹ tó kìlọ̀ fún wọn láti mú wọn pa dà sọ́dọ̀ rẹ, wọ́n sì hu ìwà àìlọ́wọ̀ tó bùáyà.+

Yorùbá Publications (1987-2025)
Jáde
Wọlé
  • Yorùbá
  • Fi Ráńṣẹ́
  • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
  • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
  • Àdéhùn Nípa Lílò
  • Òfin
  • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
  • JW.ORG
  • Wọlé
Fi Ráńṣẹ́