ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • Sáàmù 115:4-8
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    •  4 Àwọn òrìṣà wọn jẹ́ fàdákà àti wúrà,

      Iṣẹ́ ọwọ́ èèyàn.+

       5 Wọ́n ní ẹnu, àmọ́ wọn ò lè sọ̀rọ̀;+

      Wọ́n ní ojú, àmọ́ wọn ò lè ríran;

       6 Wọ́n ní etí, àmọ́ wọn ò lè gbọ́ràn;

      Wọ́n ní imú, àmọ́ wọn ò lè gbóòórùn;

       7 Wọ́n ní ọwọ́, àmọ́ wọn ò lè fọwọ́ ba nǹkan;

      Wọ́n ní ẹsẹ̀, àmọ́ wọn ò lè rìn;+

      Wọn ò lè mú ìró kankan jáde láti ọ̀fun wọn.+

       8 Àwọn tó ń ṣe wọ́n yóò dà bíi wọn gẹ́lẹ́,+

      Bẹ́ẹ̀ ló sì ṣe máa rí fún gbogbo àwọn tó gbẹ́kẹ̀ lé wọn.+

  • Àìsáyà 46:6
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    •  6 Àwọn kan wà tó ń kó wúrà jáde yàlàyòlò látinú àpò wọn;

      Wọ́n ń wọn fàdákà lórí òṣùwọ̀n.

      Wọ́n gba oníṣẹ́ irin síṣẹ́, ó sì fi ṣe ọlọ́run.+

      Wọ́n wá wólẹ̀, àní, wọ́n jọ́sìn rẹ̀.*+

  • Ìṣe 17:29
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 29 “Nítorí náà, bí a ṣe jẹ́ ọmọ* Ọlọ́run,+ kò yẹ kí a rò pé Olú Ọ̀run rí bíi wúrà tàbí fàdákà tàbí òkúta, bí ohun tí a fi ọgbọ́n àti iṣẹ́ ọnà èèyàn gbẹ́ lére.+

  • 1 Kọ́ríńtì 10:19
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 19 Kí ni mo wá ń sọ? Ṣé pé ohun tí a fi rúbọ sí òrìṣà jẹ́ nǹkan kan tàbí pé òrìṣà jẹ́ nǹkan kan ni?

Yorùbá Publications (1987-2025)
Jáde
Wọlé
  • Yorùbá
  • Fi Ráńṣẹ́
  • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
  • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
  • Àdéhùn Nípa Lílò
  • Òfin
  • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
  • JW.ORG
  • Wọlé
Fi Ráńṣẹ́