ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • 1 Sámúẹ́lì 16:6, 7
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 6 Bí wọ́n ṣe wọlé, tí ó sì rí Élíábù,+ ó sọ pé: “Ó dájú pé ẹni àmì òróró Jèhófà ló dúró yìí.” 7 Ṣùgbọ́n Jèhófà sọ fún Sámúẹ́lì pé: “Má wo ìrísí rẹ̀ àti bí ó ṣe ga tó,+ torí pé mo ti kọ̀ ọ́. Nítorí ọ̀nà tí èèyàn gbà ń wo nǹkan kọ́ ni Ọlọ́run gbà ń wo nǹkan, torí pé ohun tí ó bá hàn síta ni èèyàn ń rí, ṣùgbọ́n Jèhófà ń rí ohun tó wà nínú ọkàn.”+

  • 1 Kíróníkà 28:9
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 9 “Ìwọ Sólómọ́nì ọmọ mi, mọ Ọlọ́run bàbá rẹ, kí o sì fi gbogbo ọkàn*+ àti inú dídùn* sìn ín, nítorí gbogbo ọkàn ni Jèhófà ń wá,+ ó sì ń fi òye mọ gbogbo èrò àti ìfẹ́ ọkàn.+ Tí o bá wá a, á jẹ́ kí o rí òun,+ àmọ́ tí o bá fi í sílẹ̀, á kọ̀ ẹ́ sílẹ̀ títí láé.+

  • Sáàmù 17:3
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    •  3 O ti ṣàyẹ̀wò ọkàn mi, o ti bẹ̀ mí wò ní òru;+

      O ti yọ́ mi mọ́;+

      Wàá rí i pé mi ò ní èrò ibi kankan lọ́kàn,

      Ẹnu mi kò sì dẹ́ṣẹ̀.

  • Sáàmù 139:23
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 23 Yẹ̀ mí wò látòkè délẹ̀, Ọlọ́run, kí o sì mọ ọkàn mi.+

      Ṣàyẹ̀wò mi, kí o sì mọ àwọn ohun tó ń gbé mi lọ́kàn sókè.*+

  • Jeremáyà 20:12
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 12 Ṣùgbọ́n ìwọ, Jèhófà Ọlọ́run àwọn ọmọ ogun, ń ṣàyẹ̀wò àwọn olódodo;

      Ò ń rí èrò inú* àti ọkàn.+

      Jẹ́ kí n rí ẹ̀san rẹ lára wọn,+

      Nítorí ọwọ́ rẹ ni mo fi ẹjọ́ mi lé.+

Yorùbá Publications (1987-2025)
Jáde
Wọlé
  • Yorùbá
  • Fi Ráńṣẹ́
  • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
  • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
  • Àdéhùn Nípa Lílò
  • Òfin
  • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
  • JW.ORG
  • Wọlé
Fi Ráńṣẹ́