ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • Jẹ́nẹ́sísì 1:29
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 29 Ọlọ́run sì sọ pé: “Mo fún yín ní gbogbo ewéko ní gbogbo ayé, àwọn tó ní irúgbìn àti gbogbo igi eléso tó ní irúgbìn. Kí wọ́n jẹ́ oúnjẹ fún yín.+

  • Jẹ́nẹ́sísì 9:3
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 3 Gbogbo ẹran tó ń rìn tó sì wà láàyè lè jẹ́ oúnjẹ fún yín.+ Mo fún yín ní gbogbo wọn bí mo ṣe fún yín ní ewéko tútù.+

  • Sáàmù 144:3
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 3 Jèhófà, kí ni èèyàn jẹ́, tí o fi ń kíyè sí i

      Àti ọmọ ẹni kíkú, tí o fi ń fiyè sí i?+

  • Mátíù 6:25
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 25 “Torí náà, mo sọ fún yín pé: Ẹ yéé ṣàníyàn+ nípa ẹ̀mí* yín, ní ti ohun tí ẹ máa jẹ tàbí tí ẹ máa mu tàbí nípa ara yín, ní ti ohun tí ẹ máa wọ̀.+ Ṣé ẹ̀mí* ò ṣe pàtàkì ju oúnjẹ lọ ni, tí ara sì ṣe pàtàkì ju aṣọ lọ?+

  • Mátíù 6:30
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 30 Tó bá jẹ́ pé báyìí ni Ọlọ́run ṣe ń wọ ewéko pápá láṣọ, tó wà lónìí, tí a sì sọ sínú ààrò lọ́la, ṣé kò wá ní wọ̀ yín láṣọ jù bẹ́ẹ̀ lọ, ẹ̀yin tí ìgbàgbọ́ yín kéré?

  • Jòhánù 3:16
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 16 “Torí Ọlọ́run nífẹ̀ẹ́ ayé gan-an débi pé ó fi Ọmọ bíbí rẹ̀ kan ṣoṣo fúnni,+ kí gbogbo ẹni tó bá ń ní ìgbàgbọ́ nínú rẹ̀ má bàa pa run, ṣùgbọ́n kó lè ní ìyè àìnípẹ̀kun.+

  • Ìṣe 14:17
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 17 bó tilẹ̀ jẹ́ pé, kò ṣàìfi ẹ̀rí irú ẹni tí òun jẹ́ hàn+ ní ti pé ó ń ṣe rere, ó ń rọ òjò fún yín láti ọ̀run, ó sì ń fún yín ní àwọn àsìkò tí irè oko ń jáde,+ ó ń fi oúnjẹ bọ́ yín, ó sì ń fi ayọ̀ kún ọkàn yín.”+

  • Hébérù 2:6-8
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 6 Àmọ́ ibì kan wà tí ẹlẹ́rìí kan ti sọ pé: “Kí ni èèyàn jẹ́ tí o fi ń fi í sọ́kàn tàbí ọmọ aráyé tí o fi ń tọ́jú rẹ̀?+ 7 O mú kí ó rẹlẹ̀ díẹ̀ ju àwọn áńgẹ́lì; o fi ògo àti ọlá dé e ládé, o sì yàn án ṣe olórí àwọn iṣẹ́ ọwọ́ rẹ. 8 O fi ohun gbogbo sábẹ́ ẹsẹ̀ rẹ̀.”+ Bí Ọlọ́run ṣe fi ohun gbogbo sábẹ́ rẹ̀,+ kò sí ohun tí kò fi sábẹ́ rẹ̀.+ Àmọ́, ní báyìí, a ò tíì rí ohun gbogbo lábẹ́ rẹ̀.+

Yorùbá Publications (1987-2025)
Jáde
Wọlé
  • Yorùbá
  • Fi Ráńṣẹ́
  • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
  • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
  • Àdéhùn Nípa Lílò
  • Òfin
  • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
  • JW.ORG
  • Wọlé
Fi Ráńṣẹ́