18 Iwájú Jèhófà Ọlọ́run yín ni kí ẹ ti jẹ ẹ́, níbi tí Jèhófà Ọlọ́run yín bá yàn,+ ẹ̀yin àti ọmọkùnrin yín, ọmọbìnrin yín, ẹrúkùnrin yín àti ẹrúbìnrin yín àti ọmọ Léfì tó wà nínú àwọn ìlú* yín; kí ẹ sì máa yọ̀ níwájú Jèhófà Ọlọ́run yín nínú gbogbo ohun tí ẹ bá dáwọ́ lé.
22 Mo sì rí i pé kò sí ohun tó dáa fún èèyàn ju pé kó gbádùn iṣẹ́ rẹ̀,+ nítorí ìyẹn ni èrè* rẹ̀; torí ta ló lè mú kó rí ohun tó máa ṣẹlẹ̀ lẹ́yìn tó bá ti lọ?+
15 Nítorí náà, ìmọ̀ràn mi ni pé kéèyàn máa yọ̀,+ torí kò sí ohun tó dára fún èèyàn lábẹ́ ọ̀run* ju pé kó jẹ, kó mu, kó sì máa yọ̀; kí inú rẹ̀ máa dùn bó ṣe ń ṣiṣẹ́ àṣekára ní gbogbo ọjọ́ ayé rẹ̀,+ tí Ọlọ́run tòótọ́ fún un lábẹ́ ọ̀run.
17 bó tilẹ̀ jẹ́ pé, kò ṣàìfi ẹ̀rí irú ẹni tí òun jẹ́ hàn+ ní ti pé ó ń ṣe rere, ó ń rọ òjò fún yín láti ọ̀run, ó sì ń fún yín ní àwọn àsìkò tí irè oko ń jáde,+ ó ń fi oúnjẹ bọ́ yín, ó sì ń fi ayọ̀ kún ọkàn yín.”+