27 Ẹ má ṣiṣẹ́ fún oúnjẹ tó ń ṣègbé, àmọ́ ẹ ṣiṣẹ́ fún oúnjẹ tó wà fún ìyè àìnípẹ̀kun,+ èyí tí Ọmọ èèyàn máa fún yín; torí pé Baba, ìyẹn Ọlọ́run fúnra rẹ̀, ti gbé èdìdì ìtẹ́wọ́gbà rẹ̀ lé ẹni yìí.”+
17 Torí ó gba ọlá àti ògo láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run tó jẹ́ Baba, nígbà tí ògo ọlá ńlá sọ irú ọ̀rọ̀ yìí fún un* pé: “Èyí ni Ọmọ mi, àyànfẹ́ mi, ẹni tí èmi fúnra mi tẹ́wọ́ gbà.”+