ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • Àìsáyà 11:16
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 16 Ọ̀nà kan sì máa jáde+ láti Ásíríà fún àṣẹ́kù àwọn èèyàn rẹ̀ yòókù,+

      Bó ṣe rí fún Ísírẹ́lì ní ọjọ́ tó kúrò ní ilẹ̀ Íjíbítì.

  • Àìsáyà 65:10
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 10 Ṣárónì+ máa di ibi tí àgùntàn á ti máa jẹko,

      Àfonífojì* Ákórì+ sì máa di ibi ìsinmi àwọn màlúù

      Fún àwọn èèyàn mi tó ń wá mi.

  • Jeremáyà 23:3
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 3 “Ìgbà náà ni màá kó àwọn tó ṣẹ́ kù lára àgùntàn mi jọ láti gbogbo ilẹ̀ tí mo fọ́n wọn ká sí,+ màá sì mú wọn pa dà wá sí ibi ìjẹko wọn,+ wọ́n á máa bímọ, wọ́n á sì di púpọ̀.+

  • Jeremáyà 33:7
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 7 Màá mú àwọn ará Júdà àti àwọn ọmọ Ísírẹ́lì tó wà lóko ẹrú pa dà,+ màá sì fún wọn lókun bí mo ti ṣe ní ìbẹ̀rẹ̀.+

  • Ìsíkíẹ́lì 34:14
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 14 Èmi yóò bọ́ wọn ní ibi ìjẹko tó dáa, ilẹ̀ tí wọ́n á sì ti máa jẹko yóò wà lórí àwọn òkè gíga Ísírẹ́lì.+ Wọ́n á dùbúlẹ̀ síbẹ̀, níbi ìjẹko tó dáa,+ orí ilẹ̀ tó sì dáa jù lórí àwọn òkè Ísírẹ́lì ni wọ́n á ti máa jẹ ewéko.”

  • Míkà 2:12
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 12 Ẹ̀yin ilé Jékọ́bù, èmi yóò kó gbogbo yín jọ;

      Ó dájú pé màá kó àwọn tó ṣẹ́ kù ní Ísírẹ́lì jọ.+

      Màá mú kí wọ́n wà ní ìṣọ̀kan, bí àgùntàn ní ilé ẹran,

      Bí agbo ẹran ní pápá ìjẹko wọn;+

      Ariwo àwọn èèyàn máa gba ibẹ̀ kan.’+

Yorùbá Publications (1987-2025)
Jáde
Wọlé
  • Yorùbá
  • Fi Ráńṣẹ́
  • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
  • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
  • Àdéhùn Nípa Lílò
  • Òfin
  • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
  • JW.ORG
  • Wọlé
Fi Ráńṣẹ́