-
Àìsáyà 11:11, 12Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
-
-
11 Ní ọjọ́ yẹn, Jèhófà tún máa na ọwọ́ rẹ̀ lẹ́ẹ̀kejì, láti gba àṣẹ́kù àwọn èèyàn rẹ̀ pa dà, àwọn tó ṣẹ́ kù láti Ásíríà,+ Íjíbítì,+ Pátírọ́sì,+ Kúṣì,+ Élámù,+ Ṣínárì,* Hámátì àti àwọn erékùṣù òkun.+ 12 Ó máa gbé àmì* kan sókè fún àwọn orílẹ̀-èdè, ó sì máa kó àwọn tó fọ́n ká lára Ísírẹ́lì jọ,+ ó máa kó àwọn tó tú ká lára Júdà jọ láti ìkángun mẹ́rẹ̀ẹ̀rin ayé.+
-
-
Àìsáyà 43:5, 6Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
-
-
5 Má bẹ̀rù, torí mo wà pẹ̀lú rẹ.+
6 Màá sọ fún àríwá pé, ‘Dá wọn sílẹ̀!’+
Màá sì sọ fún gúúsù pé, ‘Má ṣe dá wọn dúró.
Mú àwọn ọmọkùnrin mi wá láti ọ̀nà jíjìn àti àwọn ọmọbìnrin mi láti àwọn ìkángun ayé,+
-
Jeremáyà 23:7, 8Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
-
-
7 “Síbẹ̀, ìgbà kan ń bọ̀,” ni Jèhófà wí, “tí wọn ò ní máa sọ pé: ‘Bí Jèhófà ti wà láàyè, ẹni tó mú àwọn èèyàn Ísírẹ́lì jáde kúrò ní ilẹ̀ Íjíbítì!’+ 8 kàkà bẹ́ẹ̀, wọ́n á máa sọ pé: ‘Bí Jèhófà ti wà láàyè, ẹni tó mú àwọn ọmọ ilé Ísírẹ́lì jáde kúrò, tó sì mú wọn wọlé wá láti ilẹ̀ àríwá àti gbogbo ilẹ̀ tó tú wọn ká sí!’ wọ́n á sì máa gbé lórí ilẹ̀ tiwọn.”+
-
-
-