-
Ẹ́kísódù 40:12Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
-
-
12 “Lẹ́yìn náà, kí o mú Áárónì àti àwọn ọmọ rẹ̀ sún mọ́ ẹnu ọ̀nà àgọ́ ìpàdé, kí o sì fi omi wẹ̀ wọ́n.+
-
-
Ìsíkíẹ́lì 44:15, 16Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
-
-
15 “‘Ní ti àwọn ọmọ Léfì tí wọ́n jẹ́ àlùfáà, àwọn ọmọ Sádókù,+ àwọn tó ń bójú tó iṣẹ́ tí wọ́n ń ṣe nínú ibi mímọ́ mi nígbà tí àwọn ọmọ Ísírẹ́lì fi mí sílẹ̀,+ wọn yóò wá sọ́dọ̀ mi kí wọ́n lè ṣiṣẹ́ fún mi, wọn yóò sì dúró níwájú mi kí wọ́n lè fi ọ̀rá+ àti ẹ̀jẹ̀ rúbọ sí mi,’+ ni Jèhófà Olúwa Ọba Aláṣẹ wí. 16 ‘Àwọn ni yóò wọnú ibi mímọ́ mi, wọ́n á wá síbi tábìlì mi kí wọ́n lè ṣiṣẹ́ fún mi,+ wọ́n á sì bójú tó iṣẹ́ tó yẹ kí wọ́n ṣe fún mi.+
-