ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • 1 Àwọn Ọba 17:9, 10
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 9 “Dìde, lọ sí Sáréfátì, ti Sídónì, kí o sì máa gbé ibẹ̀. Wò ó! Màá pàṣẹ fún opó kan níbẹ̀, pé kí ó máa gbé oúnjẹ wá fún ọ.”+ 10 Torí náà, ó dìde, ó sì lọ sí Sáréfátì. Nígbà tó dé ẹnu ọ̀nà ìlú náà, opó kan wà níbẹ̀ tó ń ṣa igi jọ. Torí náà, ó pè é, ó sì sọ pé: “Jọ̀wọ́, bá mi fi ife bu omi díẹ̀ wá kí n mu.”+

  • 1 Àwọn Ọba 17:20-23
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 20 Ó ké pe Jèhófà pé: “Jèhófà Ọlọ́run mi,+ ṣé wàá tún mú àjálù bá opó tí mò ń gbé lọ́dọ̀ rẹ̀ ni, tí o fi jẹ́ kí ọmọ rẹ̀ kú?” 21 Lẹ́yìn náà, ó nà sórí ọmọ náà ní ìgbà mẹ́ta, ó sì ké pe Jèhófà pé: “Jèhófà Ọlọ́run mi, jọ̀wọ́, mú kí ẹ̀mí* ọmọ yìí sọ jí.” 22 Jèhófà gbọ́ ẹ̀bẹ̀ Èlíjà,+ ẹ̀mí* ọmọ náà sọ jí, ó sì yè.+ 23 Èlíjà gbé ọmọ náà, ó gbé e sọ̀ kalẹ̀ láti yàrá orí òrùlé wá sínú ilé, ó sì gbé e fún ìyá rẹ̀; Èlíjà wá sọ pé: “Wò ó, ọmọ rẹ yè.”+

  • 2 Àwọn Ọba 4:8
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 8 Lọ́jọ́ kan, Èlíṣà lọ sí Ṣúnémù,+ níbi tí gbajúmọ̀ obìnrin kan wà, obìnrin náà sì rọ̀ ọ́ pé kó jẹun níbẹ̀.+ Nígbàkigbà tó bá kọjá, ó máa ń dúró jẹun níbẹ̀.

  • 2 Àwọn Ọba 4:13-17
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 13 Lẹ́yìn náà, ó sọ fún Géhásì pé: “Jọ̀ọ́, sọ fún un pé, ‘O ti ṣe wàhálà gan-an nítorí wa.+ Kí ni kí n ṣe fún ọ?+ Ṣé ohun kan wà tí o fẹ́ kí n bá ọ sọ fún ọba+ tàbí fún olórí àwọn ọmọ ogun?’” Àmọ́, obìnrin náà fèsì pé: “Àárín àwọn èèyàn mi ni mò ń gbé.” 14 Torí náà, Èlíṣà sọ pé: “Kí wá ni a lè ṣe fún un?” Géhásì bá sọ pé: “Mo rí i pé kò ní ọmọ kankan,+ ọkọ rẹ̀ sì ti darúgbó.” 15 Lẹ́sẹ̀kẹsẹ̀, ó sọ pé: “Pè é wá.” Torí náà, ó pè é, obìnrin náà sì dúró lẹ́nu ọ̀nà. 16 Ó wá sọ pé: “Ní ìwòyí ọdún tó ń bọ̀, wàá fi ọwọ́ rẹ gbé ọmọkùnrin.”+ Àmọ́, obìnrin náà sọ pé: “Rárá, ọ̀gá mi, èèyàn Ọlọ́run tòótọ́! Má parọ́ fún ìránṣẹ́ rẹ.”

      17 Ṣùgbọ́n, obìnrin náà lóyún, ó sì bí ọmọkùnrin kan ní àkókò kan náà ní ọdún tó tẹ̀ lé e, gẹ́gẹ́ bí Èlíṣà ṣe sọ fún un.

Yorùbá Publications (1987-2025)
Jáde
Wọlé
  • Yorùbá
  • Fi Ráńṣẹ́
  • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
  • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
  • Àdéhùn Nípa Lílò
  • Òfin
  • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
  • JW.ORG
  • Wọlé
Fi Ráńṣẹ́