-
Diutarónómì 23:25Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
-
-
25 “Tí o bá wọ inú oko ọkà ọmọnìkejì rẹ, o lè fọwọ́ ya àwọn ṣírí ọkà tó ti gbó, àmọ́ má yọ dòjé ti ọkà ọmọnìkejì rẹ.+
-
-
Máàkù 2:23-28Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
-
-
23 Bó ṣe ń gba oko ọkà kọjá ní Sábáàtì, àwọn ọmọ ẹ̀yìn rẹ̀ bẹ̀rẹ̀ sí í ya àwọn erín ọkà* jẹ bí wọ́n ṣe ń lọ.+ 24 Àwọn Farisí wá sọ fún un pé: “Wò ó! Kí ló dé tí wọ́n ń ṣe ohun tí kò bófin mu lọ́jọ́ Sábáàtì?” 25 Àmọ́ ó sọ fún wọn pé: “Ṣé ẹ ò tíì ka ohun tí Dáfídì ṣe rí ni, nígbà tó ṣaláìní, tí ebi sì ń pa òun àti àwọn ọkùnrin tó wà pẹ̀lú rẹ̀?+ 26 Nínú ìtàn Ábíátárì+ olórí àlùfáà, bó ṣe wọ ilé Ọlọ́run, tó sì jẹ àwọn búrẹ́dì tí wọ́n ń gbé síwájú,* èyí tí kò bófin mu fún ẹnikẹ́ni láti jẹ àfi àwọn àlùfáà,+ tó sì tún fún àwọn ọkùnrin tó wà pẹ̀lú rẹ̀ jẹ lára rẹ̀?” 27 Ó wá sọ fún wọn pé: “A dá Sábáàtì torí èèyàn,+ a ò dá èèyàn torí Sábáàtì. 28 Torí náà, Ọmọ èèyàn ni Olúwa, àní Olúwa Sábáàtì.”+
-
-
Lúùkù 6:1-5Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
-
-
6 Ní sábáàtì kan, ó ń gba oko ọkà kọjá, àwọn ọmọ ẹ̀yìn rẹ̀ ń ya àwọn erín ọkà* jẹ,+ wọ́n sì ń fi ọwọ́ ra á.+ 2 Ni àwọn kan nínú àwọn Farisí bá sọ pé: “Kí ló dé tí ẹ̀ ń ṣe ohun tí kò bófin mu lọ́jọ́ Sábáàtì?”+ 3 Àmọ́ Jésù fún wọn lésì pé: “Ṣé ẹ ò tíì ka ohun tí Dáfídì ṣe rí ni, nígbà tí ebi ń pa òun àti àwọn ọkùnrin tó wà pẹ̀lú rẹ̀?+ 4 Bó ṣe wọ ilé Ọlọ́run, tó gba àwọn búrẹ́dì tí wọ́n ń gbé síwájú,* tó sì jẹ ẹ́, tó tún fún àwọn ọkùnrin tó wà pẹ̀lú rẹ̀ jẹ, èyí tí kò bófin mu fún ẹnì kankan láti jẹ, àfi àwọn àlùfáà nìkan?”+ 5 Ó wá sọ fún wọn pé: “Ọmọ èèyàn ni Olúwa Sábáàtì.”+
-