14 Lẹ́yìn náà, ọ̀kan nínú àwọn Méjìlá náà, tí wọ́n ń pè ní Júdásì Ìsìkáríọ́tù,+ lọ sọ́dọ̀ àwọn olórí àlùfáà,+ 15 ó sì sọ pé: “Kí lẹ máa fún mi, kí n lè fà á lé yín lọ́wọ́?”+ Wọ́n bá a ṣe àdéhùn ọgbọ̀n (30) ẹyọ fàdákà.+ 16 Torí náà, látìgbà yẹn lọ, ó ń wá ìgbà tó máa dáa jù láti fà á lé wọn lọ́wọ́.