ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • Jeremáyà 31:31
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 31 “Wò ó! Ọjọ́ ń bọ̀,” ni Jèhófà wí, “tí màá bá ilé Ísírẹ́lì àti ilé Júdà dá májẹ̀mú tuntun.+

  • Mátíù 26:27, 28
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 27 Ó mú ife kan, ó dúpẹ́, ó sì gbé e fún wọn, ó ní: “Gbogbo yín, ẹ mu nínú rẹ̀,+ 28 torí èyí túmọ̀ sí ‘ẹ̀jẹ̀+ májẹ̀mú’ mi,+ tí a máa dà jáde nítorí ọ̀pọ̀ èèyàn,+ kí wọ́n lè rí ìdáríjì àwọn ẹ̀ṣẹ̀.+

  • 1 Kọ́ríńtì 11:25
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 25 Ó ṣe bákan náà ní ti ife náà,+ lẹ́yìn tí wọ́n ti jẹ oúnjẹ alẹ́, ó ní: “Ife yìí túmọ̀ sí májẹ̀mú tuntun+ tí a fi ẹ̀jẹ̀ mi dá.*+ Nígbàkigbà tí ẹ bá ń mu ún, ẹ máa ṣe èyí ní ìrántí mi.”+

  • Hébérù 8:6
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 6 Àmọ́ ní báyìí, Jésù ti gba iṣẹ́ òjíṣẹ́* tó lọ́lá jùyẹn lọ torí òun tún ni alárinà+ májẹ̀mú tó dáa jù,+ tó sì bá a mu rẹ́gí, èyí tí a ti fìdí rẹ̀ múlẹ̀ lọ́nà òfin lórí àwọn ìlérí tó dáa jù.+

  • Hébérù 9:15
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 15 Ìdí nìyẹn tó fi jẹ́ alárinà májẹ̀mú tuntun,+ kí àwọn tí a ti pè lè gba ìlérí ogún àìnípẹ̀kun, torí ẹnì kan ti kú fún wọn, kí wọ́n lè rí ìtúsílẹ̀ nípasẹ̀ ìràpadà+ kúrò lọ́wọ́ àwọn ẹ̀ṣẹ̀ tó wà lábẹ́ májẹ̀mú ti tẹ́lẹ̀.+

  • Hébérù 12:22
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 22 Àmọ́ ẹ ti sún mọ́ Òkè Síónì+ àti ìlú Ọlọ́run alààyè, Jerúsálẹ́mù ti ọ̀run+ àti ọ̀kẹ́ àìmọye* àwọn áńgẹ́lì

  • Hébérù 12:24
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 24 àti Jésù alárinà+ májẹ̀mú tuntun  + àti ẹ̀jẹ̀ tí a wọ́n, tó ń sọ̀rọ̀ lọ́nà tó dáa ju ẹ̀jẹ̀ Ébẹ́lì lọ.+

Yorùbá Publications (1987-2025)
Jáde
Wọlé
  • Yorùbá
  • Fi Ráńṣẹ́
  • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
  • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
  • Àdéhùn Nípa Lílò
  • Òfin
  • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
  • JW.ORG
  • Wọlé
Fi Ráńṣẹ́