Jeremáyà
47 Ọ̀rọ̀ tí Jèhófà sọ nìyí fún wòlíì Jeremáyà nípa àwọn Filísínì,+ kí Fáráò tó pa Gásà run. 2 Ohun tí Jèhófà sọ nìyí:
“Wò ó! Omi ń bọ̀ láti àríwá.
Ó máa di ọ̀gbàrá tó kún àkúnya.
Á sì kún bo ilẹ̀ náà àti gbogbo ohun tó wà lórí rẹ̀,
Pẹ̀lú ìlú náà àti àwọn tó ń gbé inú rẹ̀.
Àwọn ọkùnrin á figbe ta,
Gbogbo ẹni tó ń gbé ilẹ̀ náà á sì pohùn réré ẹkún.
3 Nígbà tí pátákò àwọn akọ ẹṣin rẹ̀ bá ń kilẹ̀,
Tí kẹ̀kẹ́ ogun rẹ̀ ń dún
Tí àgbá kẹ̀kẹ́ rẹ̀ ń rọ́ gìrìgìrì,
Àwọn bàbá kò tiẹ̀ ní bojú wẹ̀yìn wo àwọn ọmọ wọn,
Nítorí ọwọ́ wọn ti rọ,
4 Nítorí ọjọ́ ń bọ̀ tí gbogbo Filísínì máa pa run;+
Gbogbo olùrànlọ́wọ́ tó ṣẹ́ kù ní Tírè+ àti Sídónì+ la máa gé kúrò.
5 Orí pípá* máa dé bá Gásà.
A ti pa Áṣíkẹ́lónì lẹ́nu mọ́.+
6 Áà! Idà Jèhófà!+
Ìgbà wo lo máa tó gbé jẹ́ẹ́?
Pa dà sínú àkọ̀ rẹ.
Sinmi, kí o sì dákẹ́.
7 Báwo ló ṣe máa gbé jẹ́ẹ́
Nígbà tí Jèhófà ti pàṣẹ fún un?
Ó ti yàn án pé kí ó gbéjà ko
Áṣíkẹ́lónì àti etí òkun.”+