Orin Sólómọ́nì
Mo wá a, àmọ́ mi ò rí i.+
2 Màá dìde, màá sì lọ káàkiri inú ìlú;
Kí n lè wá ẹni tí mo nífẹ̀ẹ́,*
Ní ojú ọ̀nà àti ní àwọn ojúde ìlú.
Mo wá a, àmọ́ mi ò rí i.
3 Àwọn tó ń ṣọ́ ìlú rí mi nígbà tí wọ́n ń lọ yí ká.+
Mo bi wọ́n pé, ‘Ṣé ẹ bá mi rí olólùfẹ́ mi?’*
4 Bí mo ṣe ní kí n kúrò lọ́dọ̀ wọn báyìí
Ni mo rí olólùfẹ́ mi.*
5 Mo mú kí ẹ búra, ẹ̀yin ọmọbìnrin Jerúsálẹ́mù,
Kí ẹ fi àwọn egbin àti àwọn abo àgbọ̀nrín inú pápá búra:
Pé kí ẹ má ṣe ta ìfẹ́ jí, ẹ má sì ru ìfẹ́ sókè nínú mi, títí á fi wá fúnra rẹ̀.”+
6 “Kí ló ń jáde látinú aginjù yìí, tó ń rú túú bí èéfín,
Tí òjíá àti tùràrí ń ta sánsán lára rẹ̀,
Pẹ̀lú gbogbo àtíkè oníṣòwò tó ń ta sánsán?”+
7 “Wò ó! Ìtẹ́ Sólómọ́nì ni.
Ọgọ́ta (60) alágbára ọkùnrin ló yí i ká,
Lára àwọn alágbára ọkùnrin ní Ísírẹ́lì,+
8 Gbogbo wọn ló ní idà,
Gbogbo wọn kọ́ṣẹ́ ogun jíjà,
Kálukú fi idà rẹ̀ sẹ́gbẹ̀ẹ́
Torí ewu ní òru.”
10 Fàdákà ló fi ṣe àwọn òpó rẹ̀,
Wúrà ló fi gbé e ró.
Òwú aláwọ̀ pọ́pù ló fi ṣe ìjókòó rẹ̀;
Àwọn ọmọbìnrin Jerúsálẹ́mù
Ṣe inú rẹ̀ lọ́ṣọ̀ọ́ tìfẹ́tìfẹ́.”