ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • Orin Sólómọ́nì 3
  • Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

Ohun Tó Wà Nínú Ìwé Orin Sólómọ́nì

    • Ọ̀DỌ́BÌNRIN ṢÚLÁMÁÍTÌ WÀ NÍNÚ ÀGỌ́ ỌBA SÓLÓMỌ́NÌ (1:1–3:5)

    • Ọ̀DỌ́BÌNRIN ṢÚLÁMÁÍTÌ WÀ NÍ JERÚSÁLẸ́MÙ (3:6–8:4)

        • Àwọn ọmọbìnrin Síónì (6-11)

          • Sólómọ́nì àti àwọn tó ń tẹ̀ lé e

Orin Sólómọ́nì 3:1

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Tàbí “tí ọkàn mi fẹ́.”

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Sol 1:7
  • +Sol 5:6

Orin Sólómọ́nì 3:2

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Tàbí “tí ọkàn mi fẹ́.”

Orin Sólómọ́nì 3:3

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Tàbí “ẹni tí ọkàn mi fẹ́.”

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Sol 5:7

Orin Sólómọ́nì 3:4

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Tàbí “ẹni tí ọkàn mi fẹ́.”

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Sol 8:2

Orin Sólómọ́nì 3:5

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Sol 2:7; 8:4

Atọ́ka

  • Ìwé Ìwádìí

    Ilé Ìṣọ́,

    1/15/2015, ojú ìwé 31

    11/15/2006, ojú ìwé 18-19

Orin Sólómọ́nì 3:6

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Ẹk 30:23, 24, 34

Orin Sólómọ́nì 3:7

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +1Ọb 9:22

Orin Sólómọ́nì 3:9

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Àga tí wọ́n fi nǹkan bò lórí, tí wọ́n fi ń gbé èèyàn pàtàkì.

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +1Ọb 5:8, 9

Orin Sólómọ́nì 3:11

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Tàbí “adé tí wọ́n fi òdòdó hun.”

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +2Sa 12:24; Owe 4:3

Àwọn míì

Orin Sól. 3:1Sol 1:7
Orin Sól. 3:1Sol 5:6
Orin Sól. 3:3Sol 5:7
Orin Sól. 3:4Sol 8:2
Orin Sól. 3:5Sol 2:7; 8:4
Orin Sól. 3:6Ẹk 30:23, 24, 34
Orin Sól. 3:71Ọb 9:22
Orin Sól. 3:91Ọb 5:8, 9
Orin Sól. 3:112Sa 12:24; Owe 4:3
  • Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
  • 1
  • 2
  • 3
  • 4
  • 5
  • 6
  • 7
  • 8
  • 9
  • 10
  • 11
Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
Orin Sólómọ́nì 3:1-11

Orin Sólómọ́nì

3 “Lórí ibùsùn mi ní òru,

Mo wá ẹni tí mo nífẹ̀ẹ́.*+

Mo wá a, àmọ́ mi ò rí i.+

 2 Màá dìde, màá sì lọ káàkiri inú ìlú;

Kí n lè wá ẹni tí mo nífẹ̀ẹ́,*

Ní ojú ọ̀nà àti ní àwọn ojúde ìlú.

Mo wá a, àmọ́ mi ò rí i.

 3 Àwọn tó ń ṣọ́ ìlú rí mi nígbà tí wọ́n ń lọ yí ká.+

Mo bi wọ́n pé, ‘Ṣé ẹ bá mi rí olólùfẹ́ mi?’*

 4 Bí mo ṣe ní kí n kúrò lọ́dọ̀ wọn báyìí

Ni mo rí olólùfẹ́ mi.*

Mo rọ̀ mọ́ ọn, mi ò sì jẹ́ kó lọ,

Títí mo fi mú un wá sínú ilé ìyá mi,+

Sínú yàrá ẹni tó lóyún mi.

 5 Mo mú kí ẹ búra, ẹ̀yin ọmọbìnrin Jerúsálẹ́mù,

Kí ẹ fi àwọn egbin àti àwọn abo àgbọ̀nrín inú pápá búra:

Pé kí ẹ má ṣe ta ìfẹ́ jí, ẹ má sì ru ìfẹ́ sókè nínú mi, títí á fi wá fúnra rẹ̀.”+

 6 “Kí ló ń jáde látinú aginjù yìí, tó ń rú túú bí èéfín,

Tí òjíá àti tùràrí ń ta sánsán lára rẹ̀,

Pẹ̀lú gbogbo àtíkè oníṣòwò tó ń ta sánsán?”+

 7 “Wò ó! Ìtẹ́ Sólómọ́nì ni.

Ọgọ́ta (60) alágbára ọkùnrin ló yí i ká,

Lára àwọn alágbára ọkùnrin ní Ísírẹ́lì,+

 8 Gbogbo wọn ló ní idà,

Gbogbo wọn kọ́ṣẹ́ ogun jíjà,

Kálukú fi idà rẹ̀ sẹ́gbẹ̀ẹ́

Torí ewu ní òru.”

 9 “Ìtẹ́* Ọba Sólómọ́nì ni,

Tó fi igi Lẹ́bánónì+ ṣe fún ara rẹ̀.

10 Fàdákà ló fi ṣe àwọn òpó rẹ̀,

Wúrà ló fi gbé e ró.

Òwú aláwọ̀ pọ́pù ló fi ṣe ìjókòó rẹ̀;

Àwọn ọmọbìnrin Jerúsálẹ́mù

Ṣe inú rẹ̀ lọ́ṣọ̀ọ́ tìfẹ́tìfẹ́.”

11 “Ẹ jáde lọ, ẹ̀yin ọmọbìnrin Síónì,

Kí ẹ lọ wo Ọba Sólómọ́nì

Tó dé adé ọkọ ìyàwó* tí ìyá rẹ̀+ ṣe fún un

Ní ọjọ́ ìgbéyàwó rẹ̀,

Ní ọjọ́ tí inú rẹ̀ ń dùn.”

Yorùbá Publications (1987-2025)
Jáde
Wọlé
  • Yorùbá
  • Fi Ráńṣẹ́
  • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
  • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
  • Àdéhùn Nípa Lílò
  • Òfin
  • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
  • JW.ORG
  • Wọlé
Fi Ráńṣẹ́