ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • Jeremáyà 16
  • Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

Ohun Tó Wà Nínú Ìwé Jeremáyà

      • Jeremáyà kò gbọ́dọ̀ gbéyàwó tàbí kó ṣọ̀fọ̀, kò sì gbọ́dọ̀ jẹ àsè (1-9)

      • Ìjìyà, lẹ́yìn náà ìpadàbọ̀sípò (10-21)

Jeremáyà 16:2

Atọ́ka

  • Ìwé Ìwádìí

    Jeremáyà, ojú ìwé 92-93

Jeremáyà 16:4

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Jer 15:2
  • +Sm 79:2, 3; Ais 5:25; Jer 7:33; 9:22; 36:30
  • +Isk 5:12

Jeremáyà 16:5

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Isk 24:16, 17
  • +Di 31:17; Ais 27:11; 63:10

Jeremáyà 16:6

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Àṣà àwọn abọ̀rìṣà nígbà ọ̀fọ̀ tó jọ pé àwọn ọmọ Ísírẹ́lì apẹ̀yìndà ń tẹ̀ lé.

Jeremáyà 16:9

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Ais 24:7, 8; Jer 7:34; Ifi 18:23

Jeremáyà 16:10

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Jer 5:19

Jeremáyà 16:11

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Ond 2:12
  • +Jer 8:1, 2
  • +Da 9:11; Emọ 2:4

Jeremáyà 16:12

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Jer 7:26
  • +Ne 9:29; Jer 6:28

Jeremáyà 16:13

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +2Kr 7:20; Jer 15:14; 17:4
  • +Di 4:27, 28; 28:36

Jeremáyà 16:14

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Ẹk 20:2; Jer 23:7, 8

Jeremáyà 16:15

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Di 30:1-3; Jer 3:18; 24:6; 30:3; 32:37; Emọ 9:14

Jeremáyà 16:16

Atọ́ka

  • Ìwé Ìwádìí

    Ilé Ìṣọ́ (Ẹ̀dà Tó Wà fún Ìkẹ́kọ̀ọ́),

    4/2020, ojú ìwé 5-6

    Ilé Ìṣọ́,

    3/15/2007, ojú ìwé 9

Jeremáyà 16:17

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Ní Héb., “ní gbogbo ọ̀nà wọn.”

Jeremáyà 16:18

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Ní Héb., “òkú.”

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Ais 40:2
  • +Le 26:30; Sm 106:38

Jeremáyà 16:19

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Jer 17:17
  • +Jer 10:5, 14

Jeremáyà 16:20

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Sm 115:4; Jer 2:11; 1Kọ 8:4

Àwọn míì

Jer. 16:4Jer 15:2
Jer. 16:4Sm 79:2, 3; Ais 5:25; Jer 7:33; 9:22; 36:30
Jer. 16:4Isk 5:12
Jer. 16:5Isk 24:16, 17
Jer. 16:5Di 31:17; Ais 27:11; 63:10
Jer. 16:9Ais 24:7, 8; Jer 7:34; Ifi 18:23
Jer. 16:10Jer 5:19
Jer. 16:11Ond 2:12
Jer. 16:11Jer 8:1, 2
Jer. 16:11Da 9:11; Emọ 2:4
Jer. 16:12Jer 7:26
Jer. 16:12Ne 9:29; Jer 6:28
Jer. 16:132Kr 7:20; Jer 15:14; 17:4
Jer. 16:13Di 4:27, 28; 28:36
Jer. 16:14Ẹk 20:2; Jer 23:7, 8
Jer. 16:15Di 30:1-3; Jer 3:18; 24:6; 30:3; 32:37; Emọ 9:14
Jer. 16:18Ais 40:2
Jer. 16:18Le 26:30; Sm 106:38
Jer. 16:19Jer 17:17
Jer. 16:19Jer 10:5, 14
Jer. 16:20Sm 115:4; Jer 2:11; 1Kọ 8:4
  • Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
  • 1
  • 2
  • 3
  • 4
  • 5
  • 6
  • 7
  • 8
  • 9
  • 10
  • 11
  • 12
  • 13
  • 14
  • 15
  • 16
  • 17
  • 18
  • 19
  • 20
  • 21
Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
Jeremáyà 16:1-21

Jeremáyà

16 Jèhófà bá mi sọ̀rọ̀ lẹ́ẹ̀kan sí i pé: 2 “O ò gbọ́dọ̀ fẹ́ ìyàwó, o ò sì gbọ́dọ̀ ní àwọn ọmọkùnrin àti àwọn ọmọbìnrin ní ibí yìí. 3 Nítorí ohun tí Jèhófà sọ nípa àwọn ọmọkùnrin àti àwọn ọmọbìnrin tí wọ́n bí ní ibí yìí àti nípa àwọn ìyá wọn àti àwọn bàbá wọn tó bí wọn ní ilẹ̀ yìí ni pé: 4 ‘Àrùn burúkú ni yóò pa wọ́n,+ ẹnì kankan ò ní ṣọ̀fọ̀ wọn, bẹ́ẹ̀ ni wọn ò ní sin wọ́n; wọ́n á dà bí ajílẹ̀ lórí ilẹ̀.+ Idà àti ìyàn ni yóò pa wọ́n,+ òkú wọn yóò sì di oúnjẹ fún àwọn ẹyẹ ojú ọ̀run àti àwọn ẹranko orí ilẹ̀.’

 5 Nítorí ohun tí Jèhófà sọ nìyí,

‘Má wọnú ilé tí àwọn tó ń ṣọ̀fọ̀ ti ń jẹ àsè,

Má lọ bá wọn pohùn réré ẹkún, má sì bá wọn kẹ́dùn.’+

‘Torí mo ti mú àlàáfíà mi kúrò lọ́dọ̀ àwọn èèyàn yìí,’ ni Jèhófà wí,

‘Títí kan ìfẹ́ mi tí kì í yẹ̀ àti àánú mi.+

 6 Àti ẹni ńlá àti ẹni kékeré, gbogbo wọn ni yóò kú ní ilẹ̀ yìí.

A kò ní sin wọ́n,

Ẹnì kankan ò ní ṣọ̀fọ̀ wọn,

Bẹ́ẹ̀ ni ẹnì kankan ò ní fi abẹ kọ ara rẹ̀ tàbí kó mú orí ara rẹ̀ pá nítorí wọn.*

 7 Ẹnì kankan ò ní fún àwọn tó ń ṣọ̀fọ̀ lóúnjẹ,

Láti tù wọ́n nínú nítorí èèyàn wọn tó kú;

Bẹ́ẹ̀ ni ẹnì kankan ò ní fún wọn ní ife wáìnì mu láti tù wọ́n nínú

Nítorí bàbá àti ìyá wọn tó ṣaláìsí.

 8 Ìwọ kò sì gbọ́dọ̀ wọ ilé tí wọ́n ti ń se àsè

Láti bá wọn jókòó, láti jẹ àti láti mu.’

9 “Nítorí ohun tí Jèhófà Ọlọ́run àwọn ọmọ ogun, Ọlọ́run Ísírẹ́lì sọ nìyí, ‘Wò ó ní ibí yìí, lójú rẹ àti ní ìgbà ayé rẹ, màá fòpin sí ìró ayọ̀ àti ìdùnnú, ohùn ọkọ ìyàwó àti ohùn ìyàwó.’+

10 “Nígbà tí o bá sọ gbogbo ọ̀rọ̀ yìí fún àwọn èèyàn yìí, wọ́n á béèrè lọ́wọ́ rẹ pé, ‘Kí nìdí tí Jèhófà fi sọ pé kí gbogbo àjálù ńlá yìí dé bá wa? Kí la ṣe, ẹ̀ṣẹ̀ wo la ṣẹ Jèhófà Ọlọ́run wa?’+ 11 Kí o fún wọn lésì pé, ‘“Nítorí pé àwọn baba ńlá yín fi mí sílẹ̀,”+ ni Jèhófà wí, “wọ́n ń tẹ̀ lé àwọn ọlọ́run míì, wọ́n ń sìn wọ́n, wọ́n sì ń forí balẹ̀ fún wọn.+ Ńṣe ni wọ́n fi mí sílẹ̀, wọn kò sì pa òfin mi mọ́.+ 12 Ẹ ti ṣe ohun tó burú gan-an ju ti àwọn baba ńlá yín lọ,+ gbogbo yín ya alágídí, ẹ sì ń ṣe ohun tí ọkàn búburú yín sọ dípò kí ẹ máa ṣègbọràn sí mi.+ 13 Nítorí náà, màá lé yín jáde kúrò ní ilẹ̀ yìí sí ilẹ̀ tí ẹ̀yin tàbí àwọn baba ńlá yín kò mọ̀,+ ibẹ̀ ni ẹ ó ti sin àwọn ọlọ́run míì tọ̀sántòru,+ torí mi ò ní ṣojú rere sí yín.”’

14 “‘Síbẹ̀, ìgbà kan ń bọ̀,’ ni Jèhófà wí, ‘tí wọn ò ní máa sọ pé: “Bí Jèhófà ti wà láàyè, ẹni tó mú àwọn èèyàn Ísírẹ́lì jáde kúrò ní ilẹ̀ Íjíbítì!”+ 15 kàkà bẹ́ẹ̀, wọ́n á máa sọ pé: “Bí Jèhófà ti wà láàyè, ẹni tó mú àwọn èèyàn Ísírẹ́lì jáde kúrò ní ilẹ̀ àríwá àti gbogbo ilẹ̀ tó tú wọn ká sí!” màá sì mú wọn pa dà wá sí ilẹ̀ wọn, èyí tí mo fún àwọn baba ńlá wọn.’+

16 ‘Wò ó, màá ránṣẹ́ pe ọ̀pọ̀ apẹja,’ ni Jèhófà wí,

‘Wọ́n á sì mú wọn bí ẹja.

Lẹ́yìn ìyẹn, màá ránṣẹ́ pe ọ̀pọ̀ ọdẹ,

Wọ́n á sì máa dọdẹ wọn kiri lórí gbogbo òkè ńlá àti gbogbo òkè kéékèèké

Àti nínú àwọn pàlàpálá àpáta.

17 Nítorí ojú mi wà lára gbogbo ohun tí wọ́n ń ṣe.*

Wọn ò pa mọ́ lójú mi,

Bẹ́ẹ̀ ni àṣìṣe wọn kò ṣókùnkùn sí mi.

18 Lákọ̀ọ́kọ́ ná, màá san ẹ̀kúnrẹ́rẹ́ ohun tó yẹ wọ́n nítorí àṣìṣe wọn àti ẹ̀ṣẹ̀ wọn,+

Nítorí wọ́n ti fi àwọn ère aláìlẹ́mìí* ti òrìṣà ẹ̀gbin wọn sọ ilẹ̀ mi di aláìmọ́

Wọ́n sì ti fi àwọn ohun ìríra wọn kún inú ogún mi.’”+

19 Jèhófà, ìwọ ni okun mi àti ibi ààbò mi,

Ibi tí mò ń sá sí ní ọjọ́ ìdààmú,+

Ọ̀dọ̀ rẹ ni àwọn orílẹ̀-èdè yóò wá láti gbogbo ìkángun ayé,

Wọ́n á sì sọ pé: “Kìkìdá èké ni àwọn baba ńlá wa jogún,

Asán àti àwọn nǹkan tí kò wúlò fún ohunkóhun.”+

20 Ǹjẹ́ èèyàn lè ṣe àwọn ọlọ́run fún ara rẹ̀

Nígbà tí wọn kì í ṣe ọlọ́run ní ti gidi?+

21 “Nítorí náà, màá jẹ́ kí wọ́n mọ̀,

Lọ́tẹ̀ yìí, màá jẹ́ kí wọ́n mọ agbára àti okun mi,

Wọ́n á sì gbà pé Jèhófà ni orúkọ mi.”

Yorùbá Publications (1987-2025)
Jáde
Wọlé
  • Yorùbá
  • Fi Ráńṣẹ́
  • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
  • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
  • Àdéhùn Nípa Lílò
  • Òfin
  • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
  • JW.ORG
  • Wọlé
Fi Ráńṣẹ́