ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • Jóṣúà 23
  • Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

Ohun Tó Wà Nínú Ìwé Jóṣúà

      • Jóṣúà sọ̀rọ̀ ìdágbére fún àwọn olórí Ísírẹ́lì (1-16)

        • Ìkankan nínú ọ̀rọ̀ Jèhófà ò kùnà (14)

Jóṣúà 23:1

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Ẹk 33:14; Le 26:6; Joṣ 21:44
  • +Joṣ 13:1

Jóṣúà 23:2

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Di 31:28
  • +Di 16:18

Atọ́ka

  • Ìwé Ìwádìí

    Ilé-Ìṣọ́nà,

    7/1/1992, ojú ìwé 12-13

Jóṣúà 23:3

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Di 20:4; Joṣ 10:11-14, 40, 42

Jóṣúà 23:4

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Tàbí “mo pín.”

  • *

    Ìyẹn, Òkun Mẹditaréníà.

  • *

    Tàbí “lápá ibi tí oòrùn ti ń wọ̀.”

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Joṣ 18:10
  • +Joṣ 13:2-6
  • +Di 7:1

Jóṣúà 23:5

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Tàbí “ó mú wọn kúrò lórí ilẹ̀ wọn.”

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Ẹk 23:30; 33:2; Di 11:23
  • +Nọ 33:53

Jóṣúà 23:6

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Ẹk 24:7; Di 17:18; 31:26
  • +Di 5:32; 12:32; Joṣ 1:7, 8

Jóṣúà 23:7

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Ẹk 23:33; Di 7:2
  • +Ẹk 23:13
  • +Ẹk 20:5

Jóṣúà 23:8

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Di 10:20; Joṣ 22:5

Jóṣúà 23:9

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Di 11:23
  • +Joṣ 1:3-5

Jóṣúà 23:10

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Le 26:8; Ond 3:31; 2Sa 23:8
  • +Ẹk 23:27; Di 3:22
  • +Di 28:7

Jóṣúà 23:11

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Tàbí “Torí náà, ẹ máa ṣọ́ ọkàn yín lójú méjèèjì.”

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Di 4:9; Joṣ 22:5
  • +Di 6:5

Jóṣúà 23:12

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Tàbí “tí ẹ̀ ń fẹ́ ara yín.”

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Ẹk 23:29; Joṣ 13:2-6
  • +Ẹk 34:16; Di 7:3; Ond 3:6; 1Ọb 11:4; Ẹsr 9:2

Jóṣúà 23:13

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Tàbí “mú àwọn orílẹ̀-èdè yìí kúrò lórí ilẹ̀ wọn.”

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Ond 2:3, 21
  • +Nọ 33:55

Jóṣúà 23:14

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Ní Héb., “Mò ń lọ ní ọ̀nà gbogbo ayé lónìí.”

  • *

    Wo Àlàyé Ọ̀rọ̀, “Ọkàn.”

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Joṣ 21:45; 1Ọb 8:56

Atọ́ka

  • Ìwé Ìwádìí

    Ilé Ìṣọ́,

    1/1/2010, ojú ìwé 12

    5/15/2008, ojú ìwé 17-18

    11/1/2007, ojú ìwé 22-24

Jóṣúà 23:15

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Tàbí “gbogbo ọ̀rọ̀ ibi náà.”

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Le 26:3-12; Di 28:1
  • +Le 26:14-17; Di 28:15, 63

Jóṣúà 23:16

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +2Ọb 24:20
  • +Joṣ 23:12, 13

Àwọn míì

Jóṣ. 23:1Ẹk 33:14; Le 26:6; Joṣ 21:44
Jóṣ. 23:1Joṣ 13:1
Jóṣ. 23:2Di 31:28
Jóṣ. 23:2Di 16:18
Jóṣ. 23:3Di 20:4; Joṣ 10:11-14, 40, 42
Jóṣ. 23:4Joṣ 18:10
Jóṣ. 23:4Joṣ 13:2-6
Jóṣ. 23:4Di 7:1
Jóṣ. 23:5Ẹk 23:30; 33:2; Di 11:23
Jóṣ. 23:5Nọ 33:53
Jóṣ. 23:6Ẹk 24:7; Di 17:18; 31:26
Jóṣ. 23:6Di 5:32; 12:32; Joṣ 1:7, 8
Jóṣ. 23:7Ẹk 23:33; Di 7:2
Jóṣ. 23:7Ẹk 23:13
Jóṣ. 23:7Ẹk 20:5
Jóṣ. 23:8Di 10:20; Joṣ 22:5
Jóṣ. 23:9Di 11:23
Jóṣ. 23:9Joṣ 1:3-5
Jóṣ. 23:10Le 26:8; Ond 3:31; 2Sa 23:8
Jóṣ. 23:10Ẹk 23:27; Di 3:22
Jóṣ. 23:10Di 28:7
Jóṣ. 23:11Di 4:9; Joṣ 22:5
Jóṣ. 23:11Di 6:5
Jóṣ. 23:12Ẹk 23:29; Joṣ 13:2-6
Jóṣ. 23:12Ẹk 34:16; Di 7:3; Ond 3:6; 1Ọb 11:4; Ẹsr 9:2
Jóṣ. 23:13Ond 2:3, 21
Jóṣ. 23:13Nọ 33:55
Jóṣ. 23:14Joṣ 21:45; 1Ọb 8:56
Jóṣ. 23:15Le 26:3-12; Di 28:1
Jóṣ. 23:15Le 26:14-17; Di 28:15, 63
Jóṣ. 23:162Ọb 24:20
Jóṣ. 23:16Joṣ 23:12, 13
  • Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
  • 1
  • 2
  • 3
  • 4
  • 5
  • 6
  • 7
  • 8
  • 9
  • 10
  • 11
  • 12
  • 13
  • 14
  • 15
  • 16
Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
Jóṣúà 23:1-16

Jóṣúà

23 Lẹ́yìn ọ̀pọ̀ ọjọ́ tí Jèhófà ti fún Ísírẹ́lì ní ìsinmi+ lọ́wọ́ gbogbo àwọn ọ̀tá tó yí wọn ká, tí Jóṣúà ti darúgbó, tó sì ti lọ́jọ́ lórí,+ 2 Jóṣúà pe gbogbo Ísírẹ́lì jọ,+ àwọn àgbààgbà wọn, àwọn olórí, àwọn onídàájọ́ àtàwọn aṣojú wọn,+ ó sì sọ fún wọn pé: “Mo ti darúgbó; mo sì ti lọ́jọ́ lórí. 3 Ẹ̀yin fúnra yín ti rí gbogbo ohun tí Jèhófà Ọlọ́run yín ṣe sí gbogbo àwọn orílẹ̀-èdè yìí nítorí yín, torí pé Jèhófà Ọlọ́run yín ló ń jà fún yín.+ 4 Ẹ wò ó, mo fi kèké+ pín* ilẹ̀ àwọn orílẹ̀-èdè tó ṣẹ́ kù fún yín pé kó jẹ́ ogún àwọn ẹ̀yà yín,+ mo sì tún pín ilẹ̀ gbogbo àwọn orílẹ̀-èdè tí mo pa run fún yín,+ láti Jọ́dánì dé Òkun Ńlá* ní ìwọ̀ oòrùn.* 5 Jèhófà Ọlọ́run yín ló ń tì wọ́n kúrò níwájú yín, ó lé wọn kúrò* fún yín,+ ẹ sì gba ilẹ̀ wọn, bí Jèhófà Ọlọ́run yín ti ṣèlérí fún yín gẹ́lẹ́.+

6 “Torí náà, ẹ jẹ́ onígboyà gidigidi kí ẹ lè máa pa gbogbo ohun tí a kọ sínú ìwé Òfin+ Mósè mọ́, kí ẹ sì máa tẹ̀ lé e, kí ẹ má ṣe yà kúrò nínú rẹ̀ sí ọ̀tún tàbí sí òsì,+ 7 ẹ má ṣe bá àwọn orílẹ̀-èdè tó ṣẹ́ kù pẹ̀lú yín yìí ṣe wọlé-wọ̀de.+ Ẹ ò tiẹ̀ gbọ́dọ̀ dárúkọ àwọn ọlọ́run wọn,+ ẹ ò gbọ́dọ̀ fi wọ́n búra, ẹ ò gbọ́dọ̀ sìn wọ́n láé, ẹ ò sì gbọ́dọ̀ forí balẹ̀ fún wọn.+ 8 Àmọ́ kí ẹ rọ̀ mọ́ Jèhófà Ọlọ́run yín,+ bí ẹ ṣe ṣe títí dòní. 9 Jèhófà máa lé àwọn orílẹ̀-èdè tó tóbi tó sì lágbára kúrò níwájú yín,+ torí kò tíì sí ẹni tó lè dojú kọ yín títí dòní.+ 10 Ẹnì kan péré nínú yín máa lé ẹgbẹ̀rún (1,000),+ torí Jèhófà Ọlọ́run yín ń jà fún yín+ bó ṣe ṣèlérí fún yín.+ 11 Torí náà, ẹ máa ṣọ́ra ní gbogbo ìgbà,*+ kí ẹ máa nífẹ̀ẹ́ Jèhófà Ọlọ́run yín.+

12 “Àmọ́ tí ẹ bá yí pa dà pẹ́nrẹ́n, tí ẹ sì rọ̀ mọ́ ìyókù àwọn orílẹ̀-èdè yìí, tí wọ́n ṣẹ́ kù+ pẹ̀lú yín, tí ẹ bá wọn dána,*+ tí ẹ sì ń bára yín ṣọ̀rẹ́, 13 kí ẹ mọ̀ dájú pé Jèhófà Ọlọ́run yín kò ní bá yín lé àwọn orílẹ̀-èdè yìí kúrò* mọ́.+ Wọ́n máa di pańpẹ́ àti ìdẹkùn fún yín, wọ́n máa di pàṣán ní ẹ̀gbẹ́ yín+ àti ẹ̀gún ní ojú yín, títí ẹ fi máa pa run lórí ilẹ̀ dáradára tí Jèhófà Ọlọ́run yín fún yín.

14 “Ẹ wò ó! Mi ò ní pẹ́ kú,* ẹ sì mọ̀ dáadáa pẹ̀lú gbogbo ọkàn yín àti gbogbo ara* yín pé kò sí ìkankan nínú gbogbo ìlérí tó dáa tí Jèhófà Ọlọ́run yín ṣe fún yín tí kò ṣẹ. Gbogbo wọn ló ṣẹ fún yín. Ìkankan nínú wọn ò kùnà.+ 15 Àmọ́ bí gbogbo ìlérí tó dáa tí Jèhófà Ọlọ́run yín ṣe fún yín ṣe ṣẹ sí yín lára,+ bẹ́ẹ̀ ni Jèhófà máa mú gbogbo àjálù tó ṣèlérí* wá sórí yín, ó sì máa pa yín run lórí ilẹ̀ dáradára tí Jèhófà Ọlọ́run yín fún yín.+ 16 Tí ẹ bá da májẹ̀mú Jèhófà Ọlọ́run yín tó pa láṣẹ pé kí ẹ máa pa mọ́, tí ẹ bá sì lọ ń sin àwọn ọlọ́run míì, tí ẹ̀ ń forí balẹ̀ fún wọn, Jèhófà máa bínú sí yín gidigidi,+ ẹ sì máa pa run kíákíá lórí ilẹ̀ dáradára tó fún yín.”+

Yorùbá Publications (1987-2025)
Jáde
Wọlé
  • Yorùbá
  • Fi Ráńṣẹ́
  • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
  • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
  • Àdéhùn Nípa Lílò
  • Òfin
  • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
  • JW.ORG
  • Wọlé
Fi Ráńṣẹ́