ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • Ẹ́kísódù 16
  • Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

Ohun Tó Wà Nínú Ìwé Ẹ́kísódù

      • Àwọn èèyàn ń ráhùn torí oúnjẹ (1-3)

      • Jèhófà gbọ́ ìráhùn wọn (4-12)

      • Ó fún wọn ní ẹyẹ àparò àti mánà (13-21)

      • Kò sí mánà lọ́jọ́ Sábáàtì (22-30)

      • Wọ́n tọ́jú mánà fún ìrántí (31-36)

Ẹ́kísódù 16:1

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Nọ 33:10, 11

Ẹ́kísódù 16:2

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Ẹk 15:24; 1Kọ 10:6, 10

Atọ́ka

  • Ìwé Ìwádìí

    Ilé Ìṣọ́,

    7/15/2006, ojú ìwé 15

    3/15/1993, ojú ìwé 21

Ẹ́kísódù 16:3

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Nọ 11:4; 14:2, 3
  • +Ẹk 17:3; Nọ 16:13

Atọ́ka

  • Ìwé Ìwádìí

    Ilé Ìṣọ́,

    7/15/2006, ojú ìwé 15

    3/15/1993, ojú ìwé 21

Ẹ́kísódù 16:4

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Sm 78:24, 25; 105:40; Jo 6:31, 32, 58; 1Kọ 10:1, 3
  • +Mt 6:11
  • +Di 8:2

Ẹ́kísódù 16:5

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Ẹk 35:2
  • +Ẹk 16:22

Ẹ́kísódù 16:6

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Ẹk 6:7; Nọ 16:28, 29

Ẹ́kísódù 16:8

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Nọ 21:7; 1Sa 8:7

Ẹ́kísódù 16:9

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Ẹk 16:2; Nọ 11:1

Ẹ́kísódù 16:10

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Tàbí “àwọsánmà.”

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Ẹk 13:21; Nọ 16:19; Mt 17:5

Ẹ́kísódù 16:12

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Ní Héb., “Láàárín ìrọ̀lẹ́ méjèèjì.”

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Nọ 14:27
  • +Sm 105:40
  • +Ẹk 4:5; 6:7

Ẹ́kísódù 16:13

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Nọ 11:31, 34; Sm 78:27-29

Atọ́ka

  • Ìwé Ìwádìí

    Ilé Ìṣọ́,

    9/1/2011, ojú ìwé 14

Ẹ́kísódù 16:14

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Nọ 11:7; Di 8:3; Ne 9:15

Ẹ́kísódù 16:15

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Nọ 21:5; Di 8:14, 16; Joṣ 5:11, 12; Jo 6:31, 32, 58; 1Kọ 10:1, 3

Atọ́ka

  • Ìwé Ìwádìí

    Ilé Ìṣọ́,

    8/15/1999, ojú ìwé 25

Ẹ́kísódù 16:16

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Nǹkan bí òṣùwọ̀n tó jẹ́ Lítà 2.2. Wo Àfikún B14.

  • *

    Tàbí “ọkàn.”

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Ẹk 16:36

Ẹ́kísódù 16:18

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +2Kọ 8:15

Ẹ́kísódù 16:19

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Mt 6:11, 34

Ẹ́kísódù 16:22

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Ẹk 16:5

Ẹ́kísódù 16:23

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Tàbí “Gbogbo ọ̀la lẹ máa fi pa sábáàtì mọ́.”

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Ẹk 20:8; 31:15; 35:2; Le 23:3
  • +Nọ 11:7, 8

Ẹ́kísódù 16:26

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Ẹk 20:9, 10; 31:13; Di 5:15

Ẹ́kísódù 16:28

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Nọ 14:11; Sm 78:10; 106:13

Ẹ́kísódù 16:29

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Ẹk 31:13

Atọ́ka

  • Ìwé Ìwádìí

    Ilé Ìṣọ́,

    7/15/1998, ojú ìwé 16

    2/15/1993, ojú ìwé 27

Ẹ́kísódù 16:30

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Tàbí “sinmi.”

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Le 23:3; Di 5:13, 14

Atọ́ka

  • Ìwé Ìwádìí

    Ilé Ìṣọ́,

    7/15/1998, ojú ìwé 16

Ẹ́kísódù 16:31

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Ó lè jẹ́ ọ̀rọ̀ Hébérù tó túmọ̀ sí “Kí nìyí?”

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Ẹk 16:15; Nọ 11:7

Ẹ́kísódù 16:32

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Sm 105:5, 40

Ẹ́kísódù 16:33

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Heb 9:4

Atọ́ka

  • Ìwé Ìwádìí

    Àwọn Ìtẹ̀jáde Tá A Tọ́ka sí Nínú Ìwé Ìpàdé, 9/2020, ojú ìwé 2-3

Ẹ́kísódù 16:34

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Ẹk 27:21

Atọ́ka

  • Ìwé Ìwádìí

    Ilé Ìṣọ́,

    1/15/2006, ojú ìwé 31

Ẹ́kísódù 16:35

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Di 8:2; Ne 9:21; Sm 78:24
  • +Joṣ 5:11, 12
  • +Nọ 33:48; Di 34:1

Ẹ́kísódù 16:36

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Òṣùwọ̀n eéfà kan jẹ́ Lítà 22. Wo Àfikún B14.

Àwọn míì

Ẹ́kís. 16:1Nọ 33:10, 11
Ẹ́kís. 16:2Ẹk 15:24; 1Kọ 10:6, 10
Ẹ́kís. 16:3Nọ 11:4; 14:2, 3
Ẹ́kís. 16:3Ẹk 17:3; Nọ 16:13
Ẹ́kís. 16:4Sm 78:24, 25; 105:40; Jo 6:31, 32, 58; 1Kọ 10:1, 3
Ẹ́kís. 16:4Mt 6:11
Ẹ́kís. 16:4Di 8:2
Ẹ́kís. 16:5Ẹk 35:2
Ẹ́kís. 16:5Ẹk 16:22
Ẹ́kís. 16:6Ẹk 6:7; Nọ 16:28, 29
Ẹ́kís. 16:8Nọ 21:7; 1Sa 8:7
Ẹ́kís. 16:9Ẹk 16:2; Nọ 11:1
Ẹ́kís. 16:10Ẹk 13:21; Nọ 16:19; Mt 17:5
Ẹ́kís. 16:12Nọ 14:27
Ẹ́kís. 16:12Sm 105:40
Ẹ́kís. 16:12Ẹk 4:5; 6:7
Ẹ́kís. 16:13Nọ 11:31, 34; Sm 78:27-29
Ẹ́kís. 16:14Nọ 11:7; Di 8:3; Ne 9:15
Ẹ́kís. 16:15Nọ 21:5; Di 8:14, 16; Joṣ 5:11, 12; Jo 6:31, 32, 58; 1Kọ 10:1, 3
Ẹ́kís. 16:16Ẹk 16:36
Ẹ́kís. 16:182Kọ 8:15
Ẹ́kís. 16:19Mt 6:11, 34
Ẹ́kís. 16:22Ẹk 16:5
Ẹ́kís. 16:23Ẹk 20:8; 31:15; 35:2; Le 23:3
Ẹ́kís. 16:23Nọ 11:7, 8
Ẹ́kís. 16:26Ẹk 20:9, 10; 31:13; Di 5:15
Ẹ́kís. 16:28Nọ 14:11; Sm 78:10; 106:13
Ẹ́kís. 16:29Ẹk 31:13
Ẹ́kís. 16:30Le 23:3; Di 5:13, 14
Ẹ́kís. 16:31Ẹk 16:15; Nọ 11:7
Ẹ́kís. 16:32Sm 105:5, 40
Ẹ́kís. 16:33Heb 9:4
Ẹ́kís. 16:34Ẹk 27:21
Ẹ́kís. 16:35Di 8:2; Ne 9:21; Sm 78:24
Ẹ́kís. 16:35Joṣ 5:11, 12
Ẹ́kís. 16:35Nọ 33:48; Di 34:1
  • Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
  • 1
  • 2
  • 3
  • 4
  • 5
  • 6
  • 7
  • 8
  • 9
  • 10
  • 11
  • 12
  • 13
  • 14
  • 15
  • 16
  • 17
  • 18
  • 19
  • 20
  • 21
  • 22
  • 23
  • 24
  • 25
  • 26
  • 27
  • 28
  • 29
  • 30
  • 31
  • 32
  • 33
  • 34
  • 35
  • 36
Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
Ẹ́kísódù 16:1-36

Ẹ́kísódù

16 Lẹ́yìn tí wọ́n kúrò ní Élímù, gbogbo àpéjọ àwọn ọmọ Ísírẹ́lì dé aginjù Sínì,+ tó wà láàárín Élímù àti Sínáì. Wọ́n dé ibẹ̀ ní ọjọ́ kẹẹ̀ẹ́dógún oṣù kejì tí wọ́n kúrò ní ilẹ̀ Íjíbítì.

2 Gbogbo àpéjọ àwọn ọmọ Ísírẹ́lì sì bẹ̀rẹ̀ sí í kùn sí Mósè àti Áárónì ní aginjù.+ 3 Àwọn ọmọ Ísírẹ́lì ń sọ fún wọn pé: “Jèhófà ì bá ti kúkú pa wá nílẹ̀ Íjíbítì nígbà tí a jókòó ti ìkòkò ẹran,+ tí à ń jẹun ní àjẹtẹ́rùn. Ẹ wá mú wa wá sínú aginjù yìí kí ebi lè pa gbogbo ìjọ yìí kú.”+

4 Lẹ́yìn náà, Jèhófà sọ fún Mósè pé: “Màá rọ̀jò oúnjẹ fún yín láti ọ̀run,+ kí kálukú máa jáde lọ kó iye tó máa tó o lójoojúmọ́,+ kí n lè dán wọn wò, kí n sì rí i bóyá wọ́n á pa òfin mi mọ́ tàbí wọn ò ní pa á mọ́.+ 5 Àmọ́ ní ọjọ́ kẹfà,+ nígbà tí wọ́n bá ń ṣètò ohun tí wọ́n kó, kó jẹ́ ìlọ́po méjì ohun tí wọ́n ń kó ní àwọn ọjọ́ tó kù.”+

6 Mósè àti Áárónì wá sọ fún gbogbo àwọn ọmọ Ísírẹ́lì pé: “Ní alẹ́, ó dájú pé ẹ ó mọ̀ pé Jèhófà ló mú yín kúrò ní ilẹ̀ Íjíbítì.+ 7 Ní àárọ̀, ẹ máa rí ògo Jèhófà, torí Jèhófà ti gbọ́ bí ẹ ṣe ń kùn sí òun. Ta ni àwa jẹ́ tí ẹ ó fi máa kùn sí wa?” 8 Mósè ń bá ọ̀rọ̀ rẹ̀ lọ pé: “Nígbà tí Jèhófà bá fún yín ní ẹran jẹ ní alẹ́, tó sì fún yín ní oúnjẹ ní àárọ̀, tí ẹ jẹ àjẹyó, ẹ máa rí i pé Jèhófà ti gbọ́ bí ẹ ṣe ń kùn sí òun. Ta ni àwa jẹ́? Àwa kọ́ lẹ̀ ń kùn sí, Jèhófà ni.”+

9 Mósè wá sọ fún Áárónì pé: “Sọ fún gbogbo àpéjọ àwọn ọmọ Ísírẹ́lì pé, ‘Ẹ wá síwájú Jèhófà, torí ó ti gbọ́ bí ẹ ṣe ń kùn.’”+ 10 Gbàrà tí Áárónì bá gbogbo àpéjọ àwọn ọmọ Ísírẹ́lì sọ̀rọ̀ tán, wọ́n yíjú pa dà, wọ́n sì dojú kọ aginjù. Wò ó! ògo Jèhófà fara hàn nínú ìkùukùu.*+

11 Jèhófà wá sọ fún Mósè pé: 12 “Mo ti gbọ́ bí àwọn ọmọ Ísírẹ́lì ṣe ń kùn.+ Sọ fún wọn pé, ‘Ní ìrọ̀lẹ́,* ẹ ó jẹ ẹran, tó bá sì di àárọ̀, ẹ ó jẹ oúnjẹ ní àjẹyó,+ ó sì dájú pé ẹ ó mọ̀ pé èmi ni Jèhófà Ọlọ́run yín.’”+

13 Torí náà, ní alẹ́ ọjọ́ yẹn, àwọn àparò fò wá, wọ́n sì bo ibi tí àwọn ọmọ Ísírẹ́lì pàgọ́ sí,+ nígbà tó sì di àárọ̀, ìrì ti sẹ̀ yí ká ibi tí wọ́n pàgọ́ sí. 14 Nígbà tí ìrì náà gbẹ, ohun kan wà lórí ilẹ̀ ní aginjù náà tó rí wínníwínní.+ Ó rí bíi yìnyín tó rọ̀ sórí ilẹ̀. 15 Nígbà tí àwọn ọmọ Ísírẹ́lì rí i, wọ́n ń bi ara wọn pé, “Kí nìyí?” torí wọn ò mọ ohun tó jẹ́. Mósè sọ fún wọn pé: “Oúnjẹ tí Jèhófà fún yín pé kí ẹ jẹ ni.+ 16 Àṣẹ Jèhófà ni pé, ‘Kí kálukú kó ìwọ̀n tó lè jẹ. Kí ẹ kó oúnjẹ tó kún òṣùwọ̀n ómérì kan*+ fún ẹnì kọ̀ọ̀kan bí iye èèyàn* tó wà nínú àgọ́ kálukú yín bá ṣe pọ̀ tó.’” 17 Àwọn ọmọ Ísírẹ́lì wá ń ṣe bẹ́ẹ̀; wọ́n ń kó o, àwọn kan kó púpọ̀, àwọn kan sì kó díẹ̀. 18 Nígbà tí wọ́n fi òṣùwọ̀n ómérì wọ̀n ọ́n, kò ṣẹ́ kù lọ́wọ́ ẹni tó kó púpọ̀, kò sì ṣaláìtó fún ẹni tó kó díẹ̀.+ Ohun tí kálukú wọn máa lè jẹ ni wọ́n kó.

19 Mósè wá sọ fún wọn pé: “Ẹnikẹ́ni ò gbọ́dọ̀ ṣẹ́ oúnjẹ náà kù di àárọ̀ ọjọ́ kejì.”+ 20 Àmọ́ wọn ò fetí sí Mósè. Nígbà tí àwọn kan ṣẹ́ ẹ kù di àárọ̀ ọjọ́ kejì, oúnjẹ náà ti ń yọ ìdin, ó sì ń rùn. Mósè wá bínú sí wọn. 21 Àràárọ̀ ni wọ́n máa ń kó oúnjẹ náà, ohun tí kálukú bá sì lè jẹ ló máa kó. Tí oòrùn bá ti mú, oúnjẹ náà á yọ́.

22 Ní ọjọ́ kẹfà, wọ́n kó ìlọ́po méjì oúnjẹ náà,+ oúnjẹ tó kún òṣùwọ̀n ómérì méjì fún ẹnì kan. Gbogbo ìjòyè àpéjọ náà wá sọ ohun tó ń ṣẹlẹ̀ fún Mósè. 23 Mósè sọ fún wọn pé: “Ohun tí Jèhófà sọ nìyẹn. Gbogbo ọ̀la yóò jẹ́ ọjọ́ ìsinmi,* yóò jẹ́ sábáàtì mímọ́ fún Jèhófà.+ Ẹ yan ohun tí ẹ bá fẹ́ yan, ẹ se ohun tí ẹ bá fẹ́ sè;+ kí ẹ wá tọ́jú oúnjẹ tó bá ṣẹ́ kù di àárọ̀ ọ̀la.” 24 Wọ́n wá ṣẹ́ ẹ kù di àárọ̀ ọjọ́ kejì, bí Mósè ṣe pa á láṣẹ. Kò rùn, kò sì yọ ìdin. 25 Mósè wá sọ pé: “Ẹ jẹ ẹ́ lónìí, torí òní jẹ́ sábáàtì fún Jèhófà. Lónìí, ẹ ò ní rí oúnjẹ kó nílẹ̀. 26 Ọjọ́ mẹ́fà ni ẹ máa fi kó o, àmọ́ ní ọjọ́ keje, ọjọ́ Sábáàtì,+ kò ní sí rárá.” 27 Síbẹ̀, àwọn èèyàn kan jáde lọ ní ọjọ́ keje yẹn láti kó oúnjẹ, àmọ́ wọn ò rí ìkankan.

28 Jèhófà wá sọ fún Mósè pé: “Ọjọ́ wo ni ẹ fẹ́ ṣèyí dà, ẹ ò pa àwọn àṣẹ mi àti òfin mi mọ́?+ 29 Ẹ kíyè sí i pé Jèhófà ti fún yín ní Sábáàtì.+ Ìdí nìyẹn tó fi fún yín ní oúnjẹ ọjọ́ méjì ní ọjọ́ kẹfà. Kí kálukú dúró sí ibi tó bá wà; ẹnikẹ́ni ò gbọ́dọ̀ kúrò ní agbègbè rẹ̀ ní ọjọ́ keje.” 30 Àwọn èèyàn náà wá pa Sábáàtì mọ́* ní ọjọ́ keje.+

31 Ilé Ísírẹ́lì pe oúnjẹ náà ní “mánà.”*+ Ó funfun bí irúgbìn kọriáńdà, ó sì dùn bí àkàrà olóyin pẹlẹbẹ. 32 Mósè sì sọ pé: “Àṣẹ tí Jèhófà pa nìyí, ‘Ẹ kó oúnjẹ náà, kó kún òṣùwọ̀n ómérì kan, kí ẹ tọ́jú rẹ̀ jálẹ̀ àwọn ìran yín,+ kí wọ́n lè rí oúnjẹ tí mo fún yín ní aginjù nígbà tí mo mú yín kúrò ní ilẹ̀ Íjíbítì.’” 33 Mósè wá sọ fún Áárónì pé: “Gbé ìkòkò kan, kí o da mánà tó kún òṣùwọ̀n ómérì kan sínú rẹ̀, kí o sì gbé e síwájú Jèhófà, kí ẹ tọ́jú rẹ̀ jálẹ̀ àwọn ìran yín.”+ 34 Torí náà, Áárónì gbé e síwájú Ẹ̀rí+ kí wọ́n lè tọ́jú rẹ̀ bí Jèhófà ṣe pàṣẹ fún Mósè. 35 Àwọn ọmọ Ísírẹ́lì jẹ mánà fún ogójì (40) ọdún,+ títí wọ́n fi dé ilẹ̀ kan tí àwọn èèyàn ń gbé.+ Wọ́n jẹ mánà títí wọ́n fi dé ààlà ilẹ̀ Kénáánì.+ 36 Òṣùwọ̀n ómérì kan jẹ́ ìdá mẹ́wàá òṣùwọ̀n eéfà.*

Yorùbá Publications (1987-2025)
Jáde
Wọlé
  • Yorùbá
  • Fi Ráńṣẹ́
  • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
  • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
  • Àdéhùn Nípa Lílò
  • Òfin
  • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
  • JW.ORG
  • Wọlé
Fi Ráńṣẹ́