ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • Jeremáyà 12
  • Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

Ohun Tó Wà Nínú Ìwé Jeremáyà

      • Jeremáyà mú ẹjọ́ rẹ̀ wá (1-4)

      • Ohun tí Jèhófà sọ (5-17)

Jeremáyà 12:1

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Jẹ 18:25
  • +Job 12:6; 21:7; Sm 73:3; Jer 5:28

Atọ́ka

  • Ìwé Ìwádìí

    Jeremáyà, ojú ìwé 118-119

Jeremáyà 12:2

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Tàbí “inú wọn lọ́hùn-ún.” Ní Héb., “kíndìnrín wọn.”

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Ais 29:13

Jeremáyà 12:3

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Sm 139:1, 2
  • +2Ọb 20:3; Sm 17:3; Jer 11:20

Jeremáyà 12:4

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Jer 14:6; 23:10

Jeremáyà 12:5

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Jer 4:13

Atọ́ka

  • Ìwé Ìwádìí

    Ilé Ìṣọ́,

    2/1/2012, ojú ìwé 29

    3/15/2011, ojú ìwé 32

Jeremáyà 12:6

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Jer 9:4

Jeremáyà 12:7

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Tàbí “ẹni tí ọkàn mi fẹ́.”

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Lk 13:35
  • +Ẹk 19:5; Ais 47:6
  • +Ida 2:1

Jeremáyà 12:9

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Tàbí “aláwọ̀ tó-tò-tó.”

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +2Ọb 24:2; Isk 16:37
  • +Ais 56:9; Jer 7:33

Jeremáyà 12:10

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Sm 80:8; Ais 5:1, 7; Jer 6:3
  • +Ais 63:18; Jer 3:19

Jeremáyà 12:11

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Tàbí kó jẹ́, “Ó ń ṣọ̀fọ̀.”

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Jer 9:11; 10:22
  • +Ais 42:24, 25

Jeremáyà 12:12

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Ní Héb., “ẹran ara èyíkéyìí.”

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Le 26:33; Jer 15:2

Jeremáyà 12:13

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Tàbí “wíìtì.”

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Le 26:16; Mik 6:15

Jeremáyà 12:14

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Sm 79:4; Jer 48:26; Isk 25:3; Sek 1:15; 2:8
  • +Jer 48:2; 49:2

Jeremáyà 12:17

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Ais 60:12

Àwọn míì

Jer. 12:1Jẹ 18:25
Jer. 12:1Job 12:6; 21:7; Sm 73:3; Jer 5:28
Jer. 12:2Ais 29:13
Jer. 12:3Sm 139:1, 2
Jer. 12:32Ọb 20:3; Sm 17:3; Jer 11:20
Jer. 12:4Jer 14:6; 23:10
Jer. 12:5Jer 4:13
Jer. 12:6Jer 9:4
Jer. 12:7Lk 13:35
Jer. 12:7Ẹk 19:5; Ais 47:6
Jer. 12:7Ida 2:1
Jer. 12:92Ọb 24:2; Isk 16:37
Jer. 12:9Ais 56:9; Jer 7:33
Jer. 12:10Sm 80:8; Ais 5:1, 7; Jer 6:3
Jer. 12:10Ais 63:18; Jer 3:19
Jer. 12:11Jer 9:11; 10:22
Jer. 12:11Ais 42:24, 25
Jer. 12:12Le 26:33; Jer 15:2
Jer. 12:13Le 26:16; Mik 6:15
Jer. 12:14Sm 79:4; Jer 48:26; Isk 25:3; Sek 1:15; 2:8
Jer. 12:14Jer 48:2; 49:2
Jer. 12:17Ais 60:12
  • Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
  • 1
  • 2
  • 3
  • 4
  • 5
  • 6
  • 7
  • 8
  • 9
  • 10
  • 11
  • 12
  • 13
  • 14
  • 15
  • 16
  • 17
Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
Jeremáyà 12:1-17

Jeremáyà

12 Olódodo ni ọ́, Jèhófà,+ nígbà tí mo gbé ẹjọ́ mi wá sọ́dọ̀ rẹ,

Nígbà tí mo sọ nípa ìdájọ́ òdodo fún ọ.

Àmọ́ kí nìdí tí ọ̀nà àwọn ẹni burúkú fi ń yọrí sí rere,+

Kí sì nìdí tí ọkàn àwọn oníbékebèke fi balẹ̀?

 2 O gbìn wọ́n, wọ́n sì ti ta gbòǹgbò.

Wọ́n ti dàgbà, wọ́n sì ti so èso.

O wà lórí ètè wọn, ṣùgbọ́n èrò inú wọn* jìnnà sí ọ.+

 3 Àmọ́, o mọ̀ mí dáadáa, Jèhófà,+ o sì rí mi;

O ti yẹ ọkàn mi wò, o sì rí i pé tìrẹ ni mò ń ṣe.+

Mú wọn bí àgùntàn tí wọ́n fẹ́ lọ pa,

Kí o sì yà wọ́n sọ́tọ̀ fún ọjọ́ pípa.

 4 Ìgbà wo ni ilẹ̀ náà kò ní ṣá mọ́

Tí koríko gbogbo ilẹ̀ kò sì ní gbẹ dà nù?+

Nítorí ìwà ibi àwọn tó ń gbé lórí rẹ̀,

A ti gbá àwọn ẹranko àti àwọn ẹyẹ lọ.

Torí wọ́n sọ pé: “Kò rí ohun tó máa ṣẹlẹ̀ sí wa.”

 5 Tí ó bá rẹ̀ ọ́ nígbà tí ò ń bá èèyàn sáré,

Báwo ni wàá ṣe lè bá ẹṣin sáré?+

Ká tiẹ̀ ní ọkàn rẹ balẹ̀ ní ilẹ̀ tó ní àlàáfíà,

Báwo lo ti máa ṣe é ní àárín igbó kìjikìji tó wà ní ẹ̀gbẹ́ odò Jọ́dánì?

 6 Kódà, àwọn arákùnrin rẹ, ìyẹn àwọn ará ilé bàbá rẹ,

Ti hùwà àìṣòótọ́ sí ọ.+

Wọ́n ti kígbe lé ọ lórí.

Má gbà wọ́n gbọ́,

Kódà tí wọ́n bá tiẹ̀ sọ àwọn ohun rere fún ọ.

 7 “Mo ti pa ilé mi tì,+ mo sì ti pa ogún mi tì.+

Mo ti fa olólùfẹ́ mi ọ̀wọ́n* lé àwọn ọ̀tá rẹ̀ lọ́wọ́.+

 8 Ogún mi ti dà bíi kìnnìún inú igbó sí mi.

Ó ti bú mọ́ mi.

Ìdí nìyẹn tí mo fi kórìíra rẹ̀.

 9 Lójú mi, ogún mi ti dà bí ẹyẹ aṣọdẹ tó ní oríṣiríṣi àwọ̀;*

Àwọn ẹyẹ aṣọdẹ míì yí i ká, wọ́n sì bá a jà.+

Ẹ wá, ẹ kóra jọ, gbogbo ẹ̀yin ẹran inú igbó,

Ẹ wá jẹun.+

10 Ọ̀pọ̀ olùṣọ́ àgùntàn ti ba ọgbà àjàrà mi jẹ́;+

Wọ́n ti tẹ oko mi mọ́lẹ̀.+

Wọ́n ti sọ oko mi tó dára di aginjù.

11 Ó ti di ahoro.

Ó ti rọ;*

Ó ti di ahoro lójú mi.+

Wọ́n ti sọ gbogbo ilẹ̀ náà di ahoro,

Ṣùgbọ́n kò sí ẹni tó fọkàn sí i.+

12 Gbogbo ọ̀nà tó ń dán tó wà ní aginjù ni àwọn apanirun gbà wá,

Idà Jèhófà ń pani run láti ìkángun kan títí dé ìkángun kejì ilẹ̀ náà.+

Kò sí ẹni* tó ní àlàáfíà.

13 Wọ́n ti gbin àlìkámà,* àmọ́ ẹ̀gún ni wọ́n kórè.+

Wọ́n ti ṣiṣẹ́ bí ẹní-máa-kú, àmọ́ wọn ò jèrè nǹkan kan.

Irè oko wọn á dójú tì wọ́n

Nítorí ìbínú Jèhófà tó ń jó fòfò.”

14 Ohun tí Jèhófà sọ nípa gbogbo aládùúgbò mi burúkú, tí wọ́n ń fọwọ́ kan ogún tí mo fún àwọn èèyàn mi, Ísírẹ́lì nìyí:+ “Wò ó, màá fà wọ́n tu kúrò ní ilẹ̀ wọn,+ màá sì fa ilé Júdà tu kúrò ní àárín wọn. 15 Àmọ́ lẹ́yìn tí mo bá fà wọ́n tu, màá tún ṣàánú wọn, màá sì mú kálukú wọn pa dà sí ogún rẹ̀ àti sí ilẹ̀ rẹ̀.”

16 “Tí wọ́n bá sì sapá láti kọ́ ọ̀nà àwọn èèyàn mi, tí wọ́n sì fi orúkọ mi búra pé, ‘Bí Jèhófà ti wà láàyè!’ bí àwọn náà ṣe kọ́ àwọn èèyàn mi láti máa fi Báálì búra, ìgbà náà ni wọn yóò rí àyè láàárín àwọn èèyàn mi. 17 Àmọ́ bí wọn kò bá ṣègbọràn, ńṣe ni màá fa orílẹ̀-èdè yẹn tu, màá fà á tu, màá sì pa á run,” ni Jèhófà wí.+

Yorùbá Publications (1987-2025)
Jáde
Wọlé
  • Yorùbá
  • Fi Ráńṣẹ́
  • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
  • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
  • Àdéhùn Nípa Lílò
  • Òfin
  • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
  • JW.ORG
  • Wọlé
Fi Ráńṣẹ́