Kíróníkà Kejì
22 Nígbà náà, àwọn tó ń gbé Jerúsálẹ́mù fi Ahasáyà ọmọ rẹ̀ àbíkẹ́yìn jọba ní ipò rẹ̀, nítorí àwọn jàǹdùkú* tó tẹ̀ lé àwọn ará Arébíà wá sí ibùdó ti pa gbogbo àwọn ẹ̀gbọ́n rẹ̀.+ Torí náà, Ahasáyà ọmọ Jèhórámù bẹ̀rẹ̀ sí í jọba ní Júdà.+ 2 Ẹni ọdún méjìlélógún (22) ni Ahasáyà nígbà tó jọba, ọdún kan ló sì fi ṣàkóso ní Jerúsálẹ́mù. Orúkọ ìyá rẹ̀ ni Ataláyà+ ọmọ ọmọ* Ómírì.+
3 Òun náà ṣe ohun tí àwọn ará ilé Áhábù ṣe,+ nítorí ìyá rẹ̀ ni agbani-nímọ̀ràn rẹ̀ tó ń gbà á nímọ̀ràn láti máa hùwà burúkú. 4 Ó ń ṣe ohun tó burú ní ojú Jèhófà nìṣó, bí ilé Áhábù ti ṣe, nítorí àwọn ni agbani-nímọ̀ràn rẹ̀ lẹ́yìn tí bàbá rẹ̀ kú, ìyẹn ló sì fa ìparun rẹ̀. 5 Ó tẹ̀ lé ìmọ̀ràn wọn, ó sì bá Jèhórámù ọmọ Áhábù ọba Ísírẹ́lì lọ láti gbéjà ko Hásáẹ́lì+ ọba Síríà ní Ramoti-gílíádì,+ ibẹ̀ ni àwọn tafàtafà ti ṣe Jèhórámù léṣe. 6 Ó pa dà sí Jésírẹ́lì+ kó lè tọ́jú ọgbẹ́ tí wọ́n dá sí i lára ní Rámà nígbà tó ń bá Hásáẹ́lì ọba Síríà jà.+
Ahasáyà* ọmọ Jèhórámù+ ọba Júdà lọ wo Jèhórámù+ ọmọ Áhábù ní Jésírẹ́lì, torí wọ́n ti ṣe é léṣe.*+ 7 Ṣùgbọ́n Ọlọ́run fa ìṣubú Ahasáyà bó ṣe wá sọ́dọ̀ Jèhórámù; nígbà tó dé, ó tẹ̀ lé Jèhórámù lọ sọ́dọ̀ Jéhù+ ọmọ ọmọ* Nímúṣì, ẹni tí Jèhófà ti fòróró yàn láti pa ilé Áhábù run.*+ 8 Nígbà tí Jéhù bẹ̀rẹ̀ sí í mú ìdájọ́ ṣẹ lórí ilé Áhábù, ó rí àwọn ìjòyè Júdà àti àwọn ọmọ àwọn arákùnrin Ahasáyà pẹ̀lú àwọn òjíṣẹ́ Ahasáyà, ó sì pa wọ́n.+ 9 Lẹ́yìn náà, ó wá Ahasáyà; wọ́n mú un níbi tó sá pa mọ́ sí ní Samáríà, wọ́n sì mú un wá sọ́dọ̀ Jéhù. Wọ́n pa á, wọ́n sì sin ín,+ torí wọ́n sọ pé: “Ọmọ ọmọ Jèhóṣáfátì ni, ẹni tó fi gbogbo ọkàn rẹ̀ wá Jèhófà.” + Kò sẹ́nì kankan nínú ilé Ahasáyà tó lágbára láti ṣàkóso ilẹ̀ náà.
10 Nígbà tí Ataláyà,+ ìyá Ahasáyà rí i pé ọmọ òun ti kú, ó dìde, ó sì pa gbogbo ìdílé ọba* ilé Júdà run.+ 11 Àmọ́, Jèhóṣábéátì ọmọbìnrin ọba gbé Jèhóáṣì+ ọmọ Ahasáyà, ó jí i gbé láàárín àwọn ọmọ ọba tí wọ́n fẹ́ pa, ó sì fi òun àti obìnrin tó ń tọ́jú rẹ̀ sínú yàrá inú lọ́hùn-ún. Jèhóṣábéátì ọmọbìnrin Ọba Jèhórámù+ (òun ni ìyàwó àlùfáà Jèhóádà,+ òun náà sì ni arábìnrin Ahasáyà) rọ́nà fi í pa mọ́ nítorí Ataláyà, kó má bàa pa á.+ 12 Ọdún mẹ́fà ló fi wà lọ́dọ̀ wọn, tí wọ́n tọ́jú rẹ̀ pa mọ́ sí ilé Ọlọ́run tòótọ́, Ataláyà sì ń ṣàkóso ilẹ̀ náà.