ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • 2 Kíróníkà 22
  • Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

Ohun Tó Wà Nínú Ìwé 2 Kíróníkà

      • Ahasáyà di ọba Júdà (1-9)

      • Ataláyà fipá gbàjọba (10-12)

2 Kíróníkà 22:1

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Tàbí “àwọn akónilẹ́rù.”

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +2Kr 21:16, 17
  • +2Ọb 8:24-26

2 Kíróníkà 22:2

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Ní Héb., “ọmọbìnrin.”

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +2Ọb 11:1, 13, 16; 2Kr 24:7
  • +1Ọb 16:28

2 Kíróníkà 22:3

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +1Ọb 16:33; 2Ọb 8:27, 28; Mik 6:16

2 Kíróníkà 22:5

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +2Ọb 8:15; 10:32
  • +1Ọb 22:3; 2Kr 18:14

2 Kíróníkà 22:6

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Wọ́n pè é ní Asaráyà nínú àwọn ìwé àfọwọ́kọ kan lédè Hébérù.

  • *

    Tàbí “ó ń ṣàìsàn.”

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Joṣ 19:18, 23
  • +2Ọb 9:15
  • +2Ọb 8:16
  • +2Ọb 3:1
  • +2Ọb 9:16

2 Kíróníkà 22:7

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Ní Héb., “ọmọkùnrin.”

  • *

    Ní Héb., “ké ilé Áhábù kúrò.”

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +1Ọb 19:16; 2Ọb 9:20, 21
  • +2Ọb 9:6, 7

2 Kíróníkà 22:8

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +2Ọb 10:10-14

2 Kíróníkà 22:9

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +2Ọb 9:27, 28
  • +2Kr 17:3, 4

2 Kíróníkà 22:10

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Ní Héb., “gbogbo èso ìjọba.”

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +2Kr 22:2
  • +2Ọb 11:1-3

2 Kíróníkà 22:11

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +2Ọb 11:21
  • +2Ọb 8:16
  • +2Kr 23:1
  • +2Sa 7:12, 13; 1Ọb 15:4; 2Kr 21:7

Àwọn míì

2 Kíró. 22:12Kr 21:16, 17
2 Kíró. 22:12Ọb 8:24-26
2 Kíró. 22:22Ọb 11:1, 13, 16; 2Kr 24:7
2 Kíró. 22:21Ọb 16:28
2 Kíró. 22:31Ọb 16:33; 2Ọb 8:27, 28; Mik 6:16
2 Kíró. 22:52Ọb 8:15; 10:32
2 Kíró. 22:51Ọb 22:3; 2Kr 18:14
2 Kíró. 22:6Joṣ 19:18, 23
2 Kíró. 22:62Ọb 9:15
2 Kíró. 22:62Ọb 8:16
2 Kíró. 22:62Ọb 3:1
2 Kíró. 22:62Ọb 9:16
2 Kíró. 22:71Ọb 19:16; 2Ọb 9:20, 21
2 Kíró. 22:72Ọb 9:6, 7
2 Kíró. 22:82Ọb 10:10-14
2 Kíró. 22:92Ọb 9:27, 28
2 Kíró. 22:92Kr 17:3, 4
2 Kíró. 22:102Kr 22:2
2 Kíró. 22:102Ọb 11:1-3
2 Kíró. 22:112Ọb 11:21
2 Kíró. 22:112Ọb 8:16
2 Kíró. 22:112Kr 23:1
2 Kíró. 22:112Sa 7:12, 13; 1Ọb 15:4; 2Kr 21:7
  • Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
  • 1
  • 2
  • 3
  • 4
  • 5
  • 6
  • 7
  • 8
  • 9
  • 10
  • 11
  • 12
Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
2 Kíróníkà 22:1-12

Kíróníkà Kejì

22 Nígbà náà, àwọn tó ń gbé Jerúsálẹ́mù fi Ahasáyà ọmọ rẹ̀ àbíkẹ́yìn jọba ní ipò rẹ̀, nítorí àwọn jàǹdùkú* tó tẹ̀ lé àwọn ará Arébíà wá sí ibùdó ti pa gbogbo àwọn ẹ̀gbọ́n rẹ̀.+ Torí náà, Ahasáyà ọmọ Jèhórámù bẹ̀rẹ̀ sí í jọba ní Júdà.+ 2 Ẹni ọdún méjìlélógún (22) ni Ahasáyà nígbà tó jọba, ọdún kan ló sì fi ṣàkóso ní Jerúsálẹ́mù. Orúkọ ìyá rẹ̀ ni Ataláyà+ ọmọ ọmọ* Ómírì.+

3 Òun náà ṣe ohun tí àwọn ará ilé Áhábù ṣe,+ nítorí ìyá rẹ̀ ni agbani-nímọ̀ràn rẹ̀ tó ń gbà á nímọ̀ràn láti máa hùwà burúkú. 4 Ó ń ṣe ohun tó burú ní ojú Jèhófà nìṣó, bí ilé Áhábù ti ṣe, nítorí àwọn ni agbani-nímọ̀ràn rẹ̀ lẹ́yìn tí bàbá rẹ̀ kú, ìyẹn ló sì fa ìparun rẹ̀. 5 Ó tẹ̀ lé ìmọ̀ràn wọn, ó sì bá Jèhórámù ọmọ Áhábù ọba Ísírẹ́lì lọ láti gbéjà ko Hásáẹ́lì+ ọba Síríà ní Ramoti-gílíádì,+ ibẹ̀ ni àwọn tafàtafà ti ṣe Jèhórámù léṣe. 6 Ó pa dà sí Jésírẹ́lì+ kó lè tọ́jú ọgbẹ́ tí wọ́n dá sí i lára ní Rámà nígbà tó ń bá Hásáẹ́lì ọba Síríà jà.+

Ahasáyà* ọmọ Jèhórámù+ ọba Júdà lọ wo Jèhórámù+ ọmọ Áhábù ní Jésírẹ́lì, torí wọ́n ti ṣe é léṣe.*+ 7 Ṣùgbọ́n Ọlọ́run fa ìṣubú Ahasáyà bó ṣe wá sọ́dọ̀ Jèhórámù; nígbà tó dé, ó tẹ̀ lé Jèhórámù lọ sọ́dọ̀ Jéhù+ ọmọ ọmọ* Nímúṣì, ẹni tí Jèhófà ti fòróró yàn láti pa ilé Áhábù run.*+ 8 Nígbà tí Jéhù bẹ̀rẹ̀ sí í mú ìdájọ́ ṣẹ lórí ilé Áhábù, ó rí àwọn ìjòyè Júdà àti àwọn ọmọ àwọn arákùnrin Ahasáyà pẹ̀lú àwọn òjíṣẹ́ Ahasáyà, ó sì pa wọ́n.+ 9 Lẹ́yìn náà, ó wá Ahasáyà; wọ́n mú un níbi tó sá pa mọ́ sí ní Samáríà, wọ́n sì mú un wá sọ́dọ̀ Jéhù. Wọ́n pa á, wọ́n sì sin ín,+ torí wọ́n sọ pé: “Ọmọ ọmọ Jèhóṣáfátì ni, ẹni tó fi gbogbo ọkàn rẹ̀ wá Jèhófà.” + Kò sẹ́nì kankan nínú ilé Ahasáyà tó lágbára láti ṣàkóso ilẹ̀ náà.

10 Nígbà tí Ataláyà,+ ìyá Ahasáyà rí i pé ọmọ òun ti kú, ó dìde, ó sì pa gbogbo ìdílé ọba* ilé Júdà run.+ 11 Àmọ́, Jèhóṣábéátì ọmọbìnrin ọba gbé Jèhóáṣì+ ọmọ Ahasáyà, ó jí i gbé láàárín àwọn ọmọ ọba tí wọ́n fẹ́ pa, ó sì fi òun àti obìnrin tó ń tọ́jú rẹ̀ sínú yàrá inú lọ́hùn-ún. Jèhóṣábéátì ọmọbìnrin Ọba Jèhórámù+ (òun ni ìyàwó àlùfáà Jèhóádà,+ òun náà sì ni arábìnrin Ahasáyà) rọ́nà fi í pa mọ́ nítorí Ataláyà, kó má bàa pa á.+ 12 Ọdún mẹ́fà ló fi wà lọ́dọ̀ wọn, tí wọ́n tọ́jú rẹ̀ pa mọ́ sí ilé Ọlọ́run tòótọ́, Ataláyà sì ń ṣàkóso ilẹ̀ náà.

Yorùbá Publications (1987-2025)
Jáde
Wọlé
  • Yorùbá
  • Fi Ráńṣẹ́
  • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
  • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
  • Àdéhùn Nípa Lílò
  • Òfin
  • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
  • JW.ORG
  • Wọlé
Fi Ráńṣẹ́