ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • Hábákúkù 3
  • Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

Ohun Tó Wà Nínú Ìwé Hábákúkù

      • Wòlíì náà bẹ Jèhófà pé kó gbé ìgbésẹ̀ (1-19)

        • Ọlọ́run yóò gba àwọn ẹni àmì òróró rẹ̀ là (13)

        • Máa yọ̀ nítorí Jèhófà láìka wàhálà sí (17, 18)

Hábákúkù 3:1

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Tàbí “orin ọ̀fọ̀.”

Atọ́ka

  • Ìwé Ìwádìí

    Ilé Ìṣọ́,

    2/1/2000, ojú ìwé 19-20

Hábákúkù 3:2

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Tàbí kó jẹ́, “láàárín àwọn ọdún.”

  • *

    Tàbí kó jẹ́, “láàárín àwọn ọdún.”

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Ida 3:32

Atọ́ka

  • Ìwé Ìwádìí

    Ìparí Ìṣípayá, ojú ìwé 108

    Ilé Ìṣọ́,

    2/1/2000, ojú ìwé 20

Hábákúkù 3:3

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Wo Àlàyé Ọ̀rọ̀.

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Di 33:2; Ond 5:4; Sm 68:7, 8
  • +Ẹk 19:16

Atọ́ka

  • Ìwé Ìwádìí

    Ilé Ìṣọ́,

    2/1/2000, ojú ìwé 20

Hábákúkù 3:4

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Ẹk 13:21

Atọ́ka

  • Ìwé Ìwádìí

    Ilé Ìṣọ́,

    2/1/2000, ojú ìwé 20

Hábákúkù 3:5

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Nọ 14:11, 12; 16:46; 25:1, 9

Atọ́ka

  • Ìwé Ìwádìí

    Ilé Ìṣọ́,

    2/1/2000, ojú ìwé 20-21

Hábákúkù 3:6

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Ais 13:13; Hag 2:21
  • +Ẹk 14:25; 23:27
  • +Sm 114:1, 4; Na 1:5

Atọ́ka

  • Ìwé Ìwádìí

    Ilé Ìṣọ́,

    11/15/2007, ojú ìwé 10

    2/1/2000, ojú ìwé 21

    Ọjọ́ Jèhófà, ojú ìwé 32

    Ìparí Ìṣípayá, ojú ìwé 108

Hábákúkù 3:7

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Ẹk 15:14, 15; Nọ 22:3, 4

Hábákúkù 3:8

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Tàbí “gbani là.”

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Sm 114:1, 3; Ais 50:2; Na 1:4
  • +Di 33:26
  • +Sm 68:17

Hábákúkù 3:9

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Tàbí kó jẹ́, “ọfà.”

  • *

    Tàbí kó jẹ́, “Àwọn ẹ̀yà ti sọ ohun tí wọ́n búra.”

Hábákúkù 3:10

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Ẹk 19:18; Sm 114:1, 4
  • +Sm 77:16

Atọ́ka

  • Ìwé Ìwádìí

    Ilé Ìṣọ́,

    2/1/2000, ojú ìwé 21-22

    Àìléwu Kárí-Ayé, ojú ìwé 156-157

Hábákúkù 3:11

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Joṣ 10:12
  • +Sm 77:17, 18

Atọ́ka

  • Ìwé Ìwádìí

    Ilé Ìṣọ́,

    2/1/2000, ojú ìwé 21-22

    Àìléwu Kárí-Ayé, ojú ìwé 156-157

Hábákúkù 3:12

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Ní Héb., “pa àwọn orílẹ̀-èdè bí ọkà.”

Atọ́ka

  • Ìwé Ìwádìí

    Ìparí Ìṣípayá, ojú ìwé 108

    Ilé Ìṣọ́,

    2/1/2000, ojú ìwé 22

Hábákúkù 3:13

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Ní Héb., “orí.”

  • *

    Ní Héb., “ọrùn.”

Atọ́ka

  • Ìwé Ìwádìí

    Ilé Ìṣọ́,

    11/15/2007, ojú ìwé 10

    2/1/2000, ojú ìwé 22

    “Ete aiyeraiye,” ojú ìwé 95

Hábákúkù 3:14

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Ní Héb., “àwọn ọ̀pá rẹ̀.”

Atọ́ka

  • Ìwé Ìwádìí

    Ilé Ìṣọ́,

    2/1/2000, ojú ìwé 22-23

Hábákúkù 3:15

Atọ́ka

  • Ìwé Ìwádìí

    Ilé Ìṣọ́,

    2/1/2000, ojú ìwé 22-23

Hábákúkù 3:16

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Ní Héb., “ikùn mi gbọ̀n rìrì.”

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Sm 119:120; Jer 23:9; Da 8:27
  • +Sm 42:5; Ais 26:20; Ida 3:26

Atọ́ka

  • Ìwé Ìwádìí

    Ilé Ìṣọ́ (Ẹ̀dà Tó Wà fún Ìkẹ́kọ̀ọ́),

    11/2018, ojú ìwé 17

    Ilé Ìṣọ́,

    2/1/2000, ojú ìwé 23-24

Hábákúkù 3:17

Àlàyé ìsàlẹ́ ìwé

  • *

    Tàbí “ilẹ̀ onípele.”

Atọ́ka

  • Ìwé Ìwádìí

    Ilé Ìṣọ́,

    11/15/2007, ojú ìwé 10

    2/1/2000, ojú ìwé 24

Hábákúkù 3:18

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Ẹk 15:2; 1Sa 2:1; Sm 18:2; 27:1; Ais 61:10

Atọ́ka

  • Ìwé Ìwádìí

    Ilé Ìṣọ́ (Ẹ̀dà Tó Wà fún Ìkẹ́kọ̀ọ́),

    11/2018, ojú ìwé 17

    Ilé Ìṣọ́,

    11/15/2007, ojú ìwé 10

    2/1/2000, ojú ìwé 24

Hábákúkù 3:19

Atọ́ka Àárín Ìwé

  • +Ais 12:2; Flp 4:13
  • +2Sa 22:34

Atọ́ka

  • Ìwé Ìwádìí

    Ilé Ìṣọ́,

    11/15/2007, ojú ìwé 10

    2/1/2000, ojú ìwé 24

Àwọn míì

Háb. 3:2Ida 3:32
Háb. 3:3Di 33:2; Ond 5:4; Sm 68:7, 8
Háb. 3:3Ẹk 19:16
Háb. 3:4Ẹk 13:21
Háb. 3:5Nọ 14:11, 12; 16:46; 25:1, 9
Háb. 3:6Ais 13:13; Hag 2:21
Háb. 3:6Ẹk 14:25; 23:27
Háb. 3:6Sm 114:1, 4; Na 1:5
Háb. 3:7Ẹk 15:14, 15; Nọ 22:3, 4
Háb. 3:8Sm 114:1, 3; Ais 50:2; Na 1:4
Háb. 3:8Di 33:26
Háb. 3:8Sm 68:17
Háb. 3:10Ẹk 19:18; Sm 114:1, 4
Háb. 3:10Sm 77:16
Háb. 3:11Joṣ 10:12
Háb. 3:11Sm 77:17, 18
Háb. 3:16Sm 119:120; Jer 23:9; Da 8:27
Háb. 3:16Sm 42:5; Ais 26:20; Ida 3:26
Háb. 3:18Ẹk 15:2; 1Sa 2:1; Sm 18:2; 27:1; Ais 61:10
Háb. 3:19Ais 12:2; Flp 4:13
Háb. 3:192Sa 22:34
  • Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
  • 1
  • 2
  • 3
  • 4
  • 5
  • 6
  • 7
  • 8
  • 9
  • 10
  • 11
  • 12
  • 13
  • 14
  • 15
  • 16
  • 17
  • 18
  • 19
Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
Hábákúkù 3:1-19

Hábákúkù

3 Àdúrà tí wòlíì Hábákúkù fi orin arò* gbà:

 2 Jèhófà, mo ti gbọ́ ìròyìn nípa rẹ.

Jèhófà, ohun tí o ṣe bà mí lẹ́rù.

Tún ṣe bẹ́ẹ̀ lásìkò wa!*

Jẹ́ ká tún rí iṣẹ́ ọwọ́ rẹ nígbà tiwa.*

Jọ̀ọ́, rántí fi àánú hàn nígbà wàhálà.+

 3 Ọlọ́run wá láti Témánì,

Ẹni Mímọ́ wá láti Òkè Páránì.+ (Sélà)*

Iyì rẹ̀ gba ọ̀run kan;+

Ayé sì kún fún ìyìn rẹ̀.

 4 Ó tàn yòò bí ìmọ́lẹ̀.+

Ìtànṣán méjì jáde láti ọwọ́ rẹ̀,

Níbi tí agbára rẹ̀ wà.

 5 Àjàkálẹ̀ àrùn ń lọ níwájú rẹ̀,+

Akọ ibà sì ń tẹ̀ lé e.

 6 Ó dúró jẹ́ẹ́, ó sì mi ayé jìgìjìgì.+

Ó wo àwọn orílẹ̀-èdè, ó sì mú kí wọ́n gbọ̀n rìrì.+

Ó fọ́ àwọn òkè tó ti wà tipẹ́,

Àwọn òkè àtayébáyé sì tẹrí ba.+

Òun ló ni àwọn ọ̀nà àtijọ́.

 7 Mo rí wàhálà nínú àwọn àgọ́ Kúṣánì.

Àwọn aṣọ àgọ́ ilẹ̀ Mídíánì sì gbọ̀n rìrì.+

 8 Jèhófà, ṣé àwọn odò ni?

Ṣé àwọn odò lò ń bínú sí?

Àbí òkun lò ń kanra mọ́?+

Torí o gun àwọn ẹṣin rẹ;+

Àwọn kẹ̀kẹ́ ẹṣin rẹ ṣẹ́gun.*+

 9 O ti yọ ọfà rẹ síta, o sì ti ṣe tán láti ta á.

Àwọn ọ̀pá* rẹ fẹ́ ṣe ohun tí o búra.* (Sélà)

O fi odò pín ayé.

10 Àwọn òkè jẹ̀rora nígbà tí wọ́n rí ọ.+

Ọ̀gbàrá òjò wọ́ kọjá.

Ibú omi pariwo.+

Ó gbé ọwọ́ rẹ̀ sókè.

11 Oòrùn àti òṣùpá dúró jẹ́ẹ́ níbi tí wọ́n wà lókè.+

Àwọn ọfà rẹ ń yára jáde bí ìmọ́lẹ̀.+

Ọ̀kọ̀ rẹ ń kọ mànà.

12 O fi ìkannú rin ayé já.

O fi ìbínú tẹ àwọn orílẹ̀-èdè mọ́lẹ̀.*

13 O jáde lọ láti gba àwọn èèyàn rẹ là, kí o lè gba ẹni àmì òróró rẹ là.

O tẹ olórí* ilé àwọn ẹni burúkú rẹ́.

O wó ilé náà láti òkè* títí dé ìpìlẹ̀. (Sélà)

14 O fi àwọn ohun ìjà rẹ̀* gún àwọn jagunjagun rẹ̀ ní orí

Nígbà tí wọ́n ya bò mí bí ìjì láti tú mi ká.

Inú wọn dùn láti dúró sí ìkọ̀kọ̀ kí wọ́n lè pa ẹni tí ìyà ń jẹ run.

15 O fi àwọn ẹṣin rẹ rin òkun já,

O fi wọ́n la ibú omi kọjá.

16 Nígbà tí mo gbọ́, jìnnìjìnnì bò mí;*

Ohun tí mo gbọ́ sì mú kí ètè mi gbọ̀n pẹ̀pẹ̀.

Egungun mi bẹ̀rẹ̀ sí í jẹrà;+

Ẹsẹ̀ mi ń gbọ̀n rìrì.

Àmọ́ mò ń fara balẹ̀ dúró de ọjọ́ wàhálà,+

Torí àwọn tó ń gbógun tì wá ni yóò dé bá.

17 Igi ọ̀pọ̀tọ́ lè má rúwé,

Àjàrà sì lè má so èso;

Tí igi ólífì kò bá tiẹ̀ so,

Tí ilẹ̀* kò sì mú èso jáde;

Tí kò bá tiẹ̀ sí agbo ẹran mọ́ nínú ọgbà ẹran,

Tí kò sì sí màlúù mọ́ ní ilé ẹran;

18 Síbẹ̀, ní tèmi, màá yọ̀ gidigidi nínú Jèhófà;

Inú mi yóò dùn nínú Ọlọ́run ìgbàlà mi.+

19 Jèhófà Olúwa Ọba Aláṣẹ ni agbára mi;+

Yóò mú kí ẹsẹ̀ mi dà bíi ti àgbọ̀nrín,

Yóò sì mú kí n rìn lórí àwọn ibi gíga.+

Sí olùdarí; pẹ̀lú àwọn ohun ìkọrin mi olókùn tín-ín-rín.

Yorùbá Publications (1987-2025)
Jáde
Wọlé
  • Yorùbá
  • Fi Ráńṣẹ́
  • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
  • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
  • Àdéhùn Nípa Lílò
  • Òfin
  • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
  • JW.ORG
  • Wọlé
Fi Ráńṣẹ́