ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • w14 1/1 ojú ìwé 16
  • Ohun Tí Bíbélì Sọ

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

  • Ohun Tí Bíbélì Sọ
  • Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2014
  • Àpilẹ̀kọ Míì Tó Jọ ọ́
  • Ohun Tó Yẹ Ká Ṣe Táwọn Èèyàn Bá Rẹ́ Wa Jẹ
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa (Tó Wà fún Ìkẹ́kọ̀ọ́)—2025
  • Ṣé Ìdájọ́ Òdodo Máa Wà?
    Àkójọ Àpilẹ̀kọ àti Fídíò
  • O Lè Fara Da Àìṣẹ̀tọ́!
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2007
  • “Ṣé Ọlọ́run Jẹ́ Aláìṣòdodo Ni?”
    Sún Mọ́ Jèhófà
Àwọn Míì
Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2014
w14 1/1 ojú ìwé 16
[Àwòrán tó wà ní ojú ìwé 16]

OHUN TÍ BÍBÉLÌ SỌ

Irú ẹni wo ni Ọlọ́run?

Ẹ̀dá ẹ̀mí tí a kò lè fojú rí ní Ọlọ́run. Òun ló dá ọ̀run, ayé àti gbogbo ohun alààyè. Kò sẹ́ni tó dá Ọlọ́run, torí náà kò ní ìbẹ̀rẹ̀. (Sáàmù 90:2) Ọlọ́run fẹ́ kí àwọn èèyàn wá òun kí wọn sì mọ́ òtítọ́ nípa ẹni tí òun jẹ́.—Ka Ìṣe 17:24-27.

Ọlọ́run ní orúkọ, a sì lè mọ orúkọ yẹn. Yàtọ̀ síyẹn, tí a bá fara balẹ̀ ronú nípa àwọn ìṣẹ̀dá ọwọ́ rẹ̀, ìyẹn lè jẹ́ ká mọ díẹ̀ lára àwọn ìwà rẹ̀. (Róòmù 1:20) Àmọ́, tá a bá fẹ́ mọ Ọlọ́run dáadáa, a ní láti kẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì, Ọ̀rọ̀ rẹ̀. Bíbélì ló jẹ́ ká mọ àwọn ìwà onífẹ̀ẹ́ tí Ọlọ́run ní.—Ka Sáàmù 103:7-10.

Ojú wo ni Ọlọ́run fi ń wo ìwà ìrẹ́jẹ

Jèhófà Ẹlẹ́dàá wa kórìíra ìwà ìrẹ́jẹ. Nígbà tó dá àwa èèyàn, àwòrán ara rẹ̀ ló dá wa. (Diutarónómì 25:16) Ìdí nìyẹn tí ọ̀pọ̀ èèyàn fi kórìíra ìwà ìrẹ́jẹ. Ọlọ́run kọ́ ló ń fa ìwà ìrẹ́jẹ tó ń ṣẹlẹ̀ láyé. Ó fún wa ní òmìnira láti yan ohun tó wù wá. Ṣùgbọ́n, ó bani nínú jẹ́ pé ọ̀pọ̀ ló ń ṣi òmìnira yẹn lò, tí wọ́n sì ń hùwà ìrẹ́jẹ. Ohun tí wọ́n ń ṣe yìí máa ń dun Ọlọ́run gan-an.—Ka Jẹ́nẹ́sísì 6:5, 6; Diutarónómì 32:4, 5.

Jèhófà nífẹ̀ẹ́ ìdájọ́ òdodo, kò sì ní jẹ́ kí ìwà ìrẹ́jẹ máa báa lọ títí láé. (Sáàmù 37:28, 29) Bíbélì ṣèlérí pé, láìpẹ́ Ọlọ́run máa fòpin sí gbogbo ìwà ìrẹ́jẹ.—Ka 2 Pétérù 3:7-9, 13.

Bíbélì ṣèlérí pé, láìpẹ́ Ọlọ́run á mú kí ìdájọ́ òdodo wà kárí ayé

Tó o bá fẹ́ ìsọfúnni síwájú sí i, wo orí 1 nínú ìwé yìí Kí Ni Bíbélì Fi Kọ́ni Gan-an?. Àwa Ẹlẹ́rìí Jèhófà la ṣe é

Ó tún wà lórí ìkànnì www.jw.org/yo

    Yorùbá Publications (1987-2025)
    Jáde
    Wọlé
    • Yorùbá
    • Fi Ráńṣẹ́
    • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
    • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
    • Àdéhùn Nípa Lílò
    • Òfin
    • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
    • JW.ORG
    • Wọlé
    Fi Ráńṣẹ́