ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • km 8/95 ojú ìwé 1
  • Ìwà Kristian ní Ilé-Ẹ̀kọ́

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

  • Ìwà Kristian ní Ilé-Ẹ̀kọ́
  • Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba Wa—1995
  • Àpilẹ̀kọ Míì Tó Jọ ọ́
  • Ẹyin Ọdọ Kristẹni Ẹ Duro Gbọnyin Ninu Igbagbọ
    Ilé-Ìṣọ́nà Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—1991
  • Ṣé O Ní Ìgbàgbọ́ Tó Lágbára Tó?
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa (Ẹ̀dà Tó Wà fún Ìkẹ́kọ̀ọ́)—2021
  • Ṣé Lóòótọ́ Lo Nígbàgbọ́ Nínú Ìhìn Rere?
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2003
  • Bó O Ṣe Lè Mú Kó Túbọ̀ Dá Ẹ Lójú Pé Ìlérí Ọlọ́run Máa Ṣẹ
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa (Ẹ̀dà Tó Wà fún Ìkẹ́kọ̀ọ́)—2016
Àwọn Míì
Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba Wa—1995
km 8/95 ojú ìwé 1

Ìwà Kristian ní Ilé-Ẹ̀kọ́

1 Bí o bá jẹ́ Kristian èwe kan tí ó ṣì wà ní ilé-ẹ̀kọ́, o nílò ìgbàgbọ́ lílágbára láti pa ìwàtítọ́ rẹ mọ́. A ṣí ọ payá sí àwọn alábàákẹ́gbẹ́ búburú àti àwọn ipò tí ó lè dán ìgbàgbọ́ rẹ wò. Ó ṣe pàtàkì pé kí o fi ìmọ̀ràn Peteru sílò láti ‘tọ́jú ìwà rẹ kí ó dára lọ́pọ̀lọpọ̀ láàárín awọn orílẹ̀-èdè, pé, kí wọ́n lè tipa awọn iṣẹ́ rẹ àtàtà èyí tí wọ́n jẹ́ ẹlẹ́rìí olùfojúrí rẹ̀ yin Ọlọrun lógo.’ (1 Pet. 2:12) O nílò ìgboyà àti ìpinnu láti kojú ìpènijà yìí.

2 Nínú ilé-ẹ̀kọ́ tàbí ní òde ilé-ẹ̀kọ́, àwọn ipa ìsọdèérí ti ìbálòpọ̀ ṣáájú ìgbeyàwó, ọ̀rọ̀ rírùn, tábà, àti ìlòkulò oògùn yí ọ ká. Ní ojoojúmọ́, o ń dojúkọ àwọn ìdẹwò tí ń gbìyànjú láti ba àkọsílẹ̀ ìwà rere rẹ jẹ́. Gẹ́gẹ́ bí àwọn àgbàlagbà, o gbọ́dọ̀ “ja ìjà líle fún ìgbàgbọ́” bí o bá níláti foríti irú àwọn àdánwò bẹ́ẹ̀.—Juda 3; wo Ilé-Ìṣọ́nà ti July 15, 1991, ojú-ìwé 23 sí 26.

3 Ní ilé-ẹ̀kọ́, àwọn ayẹyẹ orílẹ̀-èdè àti àwọn ọlidé ayé wà. Ìwọ ha mọ àwọn ọlidé orílẹ̀-èdè àti ti ìsìn tí a ń gbé lárugẹ ní ilé-ẹ̀kọ́ rẹ bí? Bí ipò tí ń peni níjà kan bá dìde, ìwọ ha lè ‘di ẹ̀rí-ọkàn rere mú, pé kí ojú lè ti awọn tí ń bu ẹnu àtẹ́ lu ìwà rere rẹ’?—1 Pet. 3:16.

4 Ìdẹfàmọ́ra àwọn ìgbòkègbodò ere ìdárayá ní ilé-ẹ̀kọ́ tàbí àwọn ìkẹ́gbẹ́pọ̀ lè dẹ ọ́ wò. O gbọ́dọ̀ wà lójúfò láti mọ̀ bí àwọn ìgbòkègbodò tí ó jọ bí èyí tí ń gbádùn mọ́ni wọ̀nyí ṣe lè fi ìgbàgbọ́ rẹ báni dọ́rẹ̀ẹ́. Àìní wà láti yan àwọn alábàákẹ́gbẹ́ tí o lè gbádùn “pàṣípààrọ̀ ìṣírí” pẹ̀lú wọn, tí ìgbàgbọ́ ẹnì kìn-ínní ń gbé ìgbàgbọ́ ẹnì kejì ró.—Romu 1:12.

5 O Lè Forítì í, Pẹ̀lú Ìrànlọ́wọ́ Jehofa: Satani ń fi ìgbà gbogbo dán ìgbàgbọ́ rẹ wò. Àwọn ìdánwò tí o gbọ́dọ̀ forítì lè lekoko, ṣùgbọ́n àwọn èrè-ẹ̀san rẹ̀ mú kí gbogbo rẹ̀ tóyeyẹ. (1 Pet. 1:6, 7) O kò lè dá ṣàṣeyọrí nínú fíforítì í; o gbọ́dọ̀ wo Jehofa fún ìrànlọ́wọ́. Jesu rọ àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ pé: “Ẹ máa bá a nìṣó ní ṣíṣọ́nà kí ẹ sì máa gbàdúrà nígbà gbogbo, kí ẹ má baà bọ́ sínú ìdẹwò.” (Matt. 26:41) Ìbáwí àti ìkóra-ẹni-níjàánu ṣe kókó.—1 Kor. 9:27.

6 Máa fìgbà gbogbo rántí pé ìwọ yóò jíhìn fún Jehofa fún ìwà rẹ. (Oniwasu 11:9) Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé àwọn ẹlòmíràn lè má ṣàkíyèsí ohun tí o ń ṣe, Jehofa mọ ohun tí o ń ṣe, yóò sì ṣe ìdájọ́. (Heb. 4:13) Ìfẹ́-ọkàn olótìítọ́-inú láti ṣe ohun tí ó dùn mọ́ ọn nínú yẹ kí ó sún ọ láti ‘ṣiṣẹ́ ìgbàlà tirẹ yọrí pẹlu ìbẹ̀rù ati ìwárìrì.’ (Filip. 2:12) Kíka Ọ̀rọ̀ Ọlọrun lojoojúmọ́ jẹ́ ìrànwọ́ ńlá. Ó kún fún ìmọ̀ràn àti àwọn àpẹẹrẹ títayọlọ́lá tí a lè ṣàfarawé.—Heb. 12:1-3.

7 Ẹ̀yin òbí, ẹ ń kó ipa ṣíṣekókó. Ẹ níláti bójútó àwọn ọmọ yín, kí ẹ mọ àwọn ìṣòro tí wọ́n ń dojúkọ, kí ẹ sì pèsè ìrànlọ́wọ́ nígbà tí wọ́n bá nílò rẹ̀. Ẹ ha ní àjùmọ̀ṣepọ̀ tí ó dára pẹ̀lú àwọn ọmọ yín bí? Ẹ ha ti gbin òye onímọrírì fún òfin àti ìlànà Ọlọrun sí wọn lọ́kàn bí? Nígbà tí wọ́n bá dojúkọ ìkìmọ́lẹ̀ tàbí ìdẹwò, àwọn ọmọ yín ha lágbára, tàbí wọ́n tètè máa ń juwọ́ sílẹ̀? Ìrẹ̀wẹ̀sì ha máa ń bá wọn nítorí wọ́n níláti dá yàtọ̀ láàárín àwọn ojúgbà wọn bí? Gẹ́gẹ́ bí òbí, ẹ ní ẹrù-iṣẹ́ láti ràn wọ́n lọ́wọ́. (Deut. 6:6, 7) Bí ẹ bá ṣe iṣẹ́ yín dáradára, ẹ lè ràn wọ́n lọ́wọ́ láti jagunmólú nínú ìjà ìgbàgbọ́.—Owe 22:6.

    Yorùbá Publications (1987-2025)
    Jáde
    Wọlé
    • Yorùbá
    • Fi Ráńṣẹ́
    • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
    • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
    • Àdéhùn Nípa Lílò
    • Òfin
    • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
    • JW.ORG
    • Wọlé
    Fi Ráńṣẹ́