ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • km 3/97 ojú ìwé 6
  • “Ìrànlọ́wọ́ Ní Àkókò Tí Ó Tọ́”

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

  • “Ìrànlọ́wọ́ Ní Àkókò Tí Ó Tọ́”
  • Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba Wa—1997
  • Àpilẹ̀kọ Míì Tó Jọ ọ́
  • Máa Lépa Àlàáfíà Ọlọ́run Nínú Ìgbésí Ayé Ìdílé
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—1997
  • Ṣíṣàjọpín Àṣírí Ayọ̀ Ìdílé Pẹ̀lú Àwọn Ẹlòmíràn
    Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba Wa—1997
  • Ríran Àwọn Ìdílé Lọ́wọ́ Láti Ní Ọjọ́ Ọ̀la Wíwà Pẹ́ Títí
    Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba Wa—1997
  • Àwọn Ońṣẹ́ Àlàáfíà Ọlọ́run Péjọ
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—1997
Àwọn Míì
Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba Wa—1997
km 3/97 ojú ìwé 6

“Ìrànlọ́wọ́ Ní Àkókò Tí Ó Tọ́”

1 Ẹ wo bí ó ti ń tuni lára tó láti rí ìrànlọ́wọ́ gbà lákòókò tí a nílò rẹ̀ gẹ́lẹ́! (Héb. 4:16) Ní Àpéjọpọ̀ Àgbègbè “Àwọn Ońṣẹ́ Àlàáfíà Ọlọ́run,” a láyọ̀ nígbà tí a fún wa ní àkànṣe ìpèsè ìrànwọ́ méjì ní àkókò tí ó tọ́ gan-an.

2 Ìwé tuntun náà, Àṣírí Ayọ̀ Ìdílé, dé ní àkókò tí ó bá a mu wẹ́kú. Ó darí àfiyèsí sí àwọn ohun pàtàkì mẹ́rin tí ń gbé ìgbésí ayé ìdílé aláyọ̀ lárugẹ: (1) Ìkóra-ẹni-níjàánu, (2) dídá ipò orí mọ̀, (3) ìjùmọ̀sọ̀rọ̀pọ̀ rere, àti (4) ìfẹ́. Ìṣílétí tí a fúnni nínú ìwé Ayọ̀ Ìdílé yóò ran gbogbo ìdílé tí ó bá fi í sílò lọ́wọ́ láti rí àlàáfíà Ọlọ́run. Ya àkókò sọ́tọ̀ láti fara balẹ̀ ka ìwé tuntun náà, kí ẹ sì kẹ́kọ̀ọ́ rẹ̀ pa pọ̀ gẹ́gẹ́ bí ìdílé. Dojúlùmọ̀ àwọn apá fífani mọ́ra rẹ̀ dáradára kí o baà lè múra sílẹ̀ láti lò ó lọ́nà gbígbéṣẹ́ nígbà tí a bá ń fi lọni ní gbangba fún ìgbà àkọ́kọ́, ní March.

3 Ìwé pẹlẹbẹ tuntun náà, Kí Ni Ọlọrun Ń Béèrè Lọ́wọ́ Wa?, dé ní àkókò tí ó tọ́ láti ṣèrànwọ́ láti mú kí iṣẹ́ sísọni di ọmọ ẹ̀yìn tí a ń ṣe yára kánkán. Nígbà tí ó jẹ́ pé a lè lò ó ní pàtàkì láti ran àwọn ènìyàn tí kò lè kàwé dáradára lọ́wọ́, ọ̀pọ̀ àwọn àgbà àti ọ̀dọ́mọdé tí wọ́n mọ̀ọ́kọmọ̀ọ́kà yóò jàǹfààní láti inú àlàyé rírọrùn tí ó ṣe nípa àwọn ìpìlẹ̀ ẹ̀kọ́ Bíbélì pẹ̀lú. Ó lè jẹ́ ohun tí a nílò gan-an láti bẹ̀rẹ̀ ìkẹ́kọ̀ọ́ kan gẹ́gẹ́ bí àtẹ̀gùn sínú ìwé Ìmọ̀. Ó dájú pé ìpèsè yí yóò ran púpọ̀ sí i lọ́wọ́ láti mọrírì bí a ṣe lè bù kún wọn ní jìngbìnnì tó nípa ṣíṣe ohun tí Ọlọ́run ń béèrè.

4 Dáfídì sọ ìmọ̀lára wa jáde lọ́nà pípé nígbà tí ó polongo pé, ‘òun kò ṣe aláìní ohunkóhun, a tu ọkàn òun lára, ife òun sì kún àkúnwọ́sílẹ̀!’ (Orin Dá. 23:1, 3, 5) A fi ìdùnnú wọ̀nà fún mímú àgbàyanu ìrànwọ́ tẹ̀mí yìí lọ fún ọ̀pọ̀ ẹlòmíràn tí wọ́n ní ìfẹ́ ọkàn aláìlábòsí láti mọ Ọlọ́run tòótọ́ náà, Jèhófà, kí wọ́n sì ṣiṣẹ́ sìn ín.

    Yorùbá Publications (1987-2025)
    Jáde
    Wọlé
    • Yorùbá
    • Fi Ráńṣẹ́
    • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
    • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
    • Àdéhùn Nípa Lílò
    • Òfin
    • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
    • JW.ORG
    • Wọlé
    Fi Ráńṣẹ́