ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • km 10/97 ojú ìwé 7
  • Ìwọ Ha Jẹ́ Ẹlẹ́rìí Alákòókò Kíkún Bí?

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

  • Ìwọ Ha Jẹ́ Ẹlẹ́rìí Alákòókò Kíkún Bí?
  • Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba Wa—1997
  • Àpilẹ̀kọ Míì Tó Jọ ọ́
  • Ẹ Máa Rántí Àwọn Tó Ń Ṣe Iṣẹ́ Ìsìn Alákòókò Kíkún
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2014
  • Kí Lo Fi Ń Díwọ̀n Àṣeyọrí?
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2000
  • Jèhófà Máa Jẹ́ Kí Àwọn Ìpinnu Rẹ Yọrí Sí Rere
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa (Ẹ̀dà Tó Wà fún Ìkẹ́kọ̀ọ́)—2017
  • “Ẹ Máa Ṣe Ohun Gbogbo fún Ògo Ọlọ́run”
    A Ṣètò Wa Láti Ṣe Ìfẹ́ Jèhófà
Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba Wa—1997
km 10/97 ojú ìwé 7

Ìwọ Ha Jẹ́ Ẹlẹ́rìí Alákòókò Kíkún Bí?

1 Ìwọ ha lè dáhùn bẹ́ẹ̀ ni sí ìbéèrè yí bí? Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé kì í ṣe gbogbo àwọn ìránṣẹ́ Jèhófà olùṣèyàsímímọ́ ni ó lè forúkọ sílẹ̀ nínú iṣẹ́ òjíṣẹ́ alákòókò kíkún, kò ha bọ́gbọ́n mu láti retí pé kí gbogbo wa wo ara wa gẹ́gẹ́ bí Ẹlẹ́rìí rẹ̀ alákòókò kíkún bí? Dájúdájú, ó yẹ kí a ṣe bẹ́ẹ̀.

2 Kò gbọ́dọ̀ sí irú ohun tí a ń pè ní Kristẹni aláàbọ̀ àkókò. Jésù sọ nípa Bàbá rẹ̀ pé: “Nígbà gbogbo ni mo ń ṣe ohun tí ó wù ú.” (Jòh. 8:29) Pọ́ọ̀lù, ẹni tí ó nímọ̀lára bẹ́ẹ̀, rọ̀ wá láti “máa ṣe ohun gbogbo fún ògo Ọlọ́run.” (1 Kọ́r. 10:31) Nítorí náà, ní gbogbo ọ̀nà, gbogbo wa gbọ́dọ̀ ka ara wa sí Ẹlẹ́rìí Jèhófà alákòókò kíkún. Ríronú tí a bá ń ronú lọ́nà yí yóò nípa lórí wa fún rere nínú gbogbo ìgbòkègbodò tí a bá ń lépa.

3 Gbé Ẹ̀rí náà Yẹ̀ Wò: Ìrísí, ọ̀rọ̀, àti ìwà wa lè fi han àwọn ẹlòmíràn pé a jẹ́ Ẹlẹ́rìí Jèhófà ní tòótọ́. A máa ń wà lójúfò nípa àìní náà fún ìrísí oníwọ̀ntúnwọ̀nsì, ọ̀rọ̀ tí ó gbámúṣé, àti ìwà tí ó bẹ́tọ̀ọ́ mu nígbàkigbà tí a bá ń lọ́wọ́ nínú iṣẹ́ ìsìn pápá tàbí tí a bá pésẹ̀ sí àwọn ìpàdé Kristẹni. Ṣùgbọ́n, yálà a ń lọ sí ilé ẹ̀kọ́, a ń ṣiṣẹ́ níbi iṣẹ́ oúnjẹ òòjọ́ wa, tàbí a ń kópa nínú eré ìnàjú, ohun gbogbo tí a bá ń ṣe gbọ́dọ̀ fúnni ní ẹ̀rí pé a ń gbé ní ìbámu pẹ̀lú ọ̀pá ìdiwọ̀n òdodo Jèhófà.

4 Jésù sọ pé: “Ìlú ńlá kan kò lè fara sin nígbà tí ó bá wà lórí òkè ńlá. . . . Kí ìmọ́lẹ̀ yín máa tàn níwájú àwọn ènìyàn, kí wọ́n lè rí àwọn iṣẹ́ àtàtà yín kí wọ́n sì lè fi ògo fún Bàbá yín tí ń bẹ ní àwọn ọ̀run.” (Mát. 5:14-16) Èyí gbọ́dọ̀ rí bẹ́ẹ̀ nínú gbogbo ohun tí a bá ń ṣe àti nígbà gbogbo. Bí ó bá ṣẹlẹ̀ láé pé a ń lọ́ tìkọ̀ láti jẹ́rìí nítorí ibi tí a wà tàbí ohun tí a ń ṣe, ó yẹ kí a béèrè lọ́wọ́ ara wa pé, ‘Èmi ha ń sin Jèhófà ní àkókò kíkún tàbí ní ààbọ̀ àkókò bí?’ Ǹjẹ́ kí a má ṣe jẹ́ kí àǹfààní láti bá àwọn ẹlòmíràn sọ̀rọ̀ nípa ìhìn rere Ìjọba Ọlọ́run kọjá wa láé.

5 Rántí pé a ń bọlá fún Jèhófà a sì ń mú inú rẹ̀ dùn nígbà tí a bá lè fi “Bẹ́ẹ̀ ni!” tí ó dún lọ réré dáhùn ìbéèrè náà, “Ìwọ Ha Jẹ́ Ẹlẹ́rìí Alákòókò Kíkún Bí?”

    Yorùbá Publications (1987-2025)
    Jáde
    Wọlé
    • Yorùbá
    • Fi Ráńṣẹ́
    • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
    • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
    • Àdéhùn Nípa Lílò
    • Òfin
    • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
    • JW.ORG
    • Wọlé
    Fi Ráńṣẹ́