ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • km 1/11 ojú ìwé 1
  • Iṣẹ́ Tó Gbádùn Mọ́ni Jù Lọ

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

  • Iṣẹ́ Tó Gbádùn Mọ́ni Jù Lọ
  • Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba Wa—2011
  • Àpilẹ̀kọ Míì Tó Jọ ọ́
  • Ṣé Ìwọ Náà Lè Sọ Àwọn Èèyàn Di Ọmọ Ẹ̀yìn?
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa (Ẹ̀dà Tó Wà fún Ìkẹ́kọ̀ọ́)—2021
  • Bá A Ṣe Lè Ran Àwọn Akẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì Wa Lọ́wọ́ Kí Wọ́n Lè Ṣèrìbọmi—Apá Kejì
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa (Ẹ̀dà Tó Wà fún Ìkẹ́kọ̀ọ́)—2020
  • Máa Rí Ìdùnnú Nínú Iṣẹ́ Sísọni Dọmọ Ẹ̀yìn
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2009
  • Apá Kìíní: Bí A Ṣe Lè Darí Ìkẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì Tí Yóò Máa Tẹ̀ Síwájú
    Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba Wa—2004
Àwọn Míì
Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba Wa—2011
km 1/11 ojú ìwé 1

Iṣẹ́ Tó Gbádùn Mọ́ni Jù Lọ

1. Iṣẹ́ ìwòsàn tẹ̀mí wo là ń ṣe lákòókò tá a wà yìí?

1 Ayọ̀ ńláǹlà kúnnú àwọn tó fojú ara wọn rí ìwòsàn nípa tara tó wáyé ní ọ̀rúndún kìíní. (Lúùkù 5:24-26) Lóde òní, inú wa ń dùn bá a ṣe ń mú àwọn èèyàn lára dá nípa tẹ̀mí. (Ìṣí. 22:1, 2, 17) Orí wa máa ń wú bá a ṣe ń ka ìrírí nípa bí Ọ̀rọ̀ Jèhófà àti ẹ̀mí mímọ́ ṣe ń yí ìgbésí ayé àwọn èèyàn pa dà sí rere. Ohun míì tó tún ń fún wa láyọ̀ bá a ṣe ń lọ́wọ́ nínú iṣẹ́ yìí ni dídarí ìkẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì tó ń tẹ̀ síwájú.

2. Àwọn nǹkan wo ló lè fún wa láyọ̀ bá a ṣe ń kọ́ ẹnì kan lẹ́kọ̀ọ́ òtítọ́?

2 Kí ni orúkọ Ọlọ́run? Kí nìdí tó fi fàyè gba ìjìyà? Kí ni Ìjọba Ọlọ́run máa ṣe fún aráyé? Bá a ṣe ń sọ ìdáhùn àwọn ìbéèrè wọ̀nyẹn fún àwọn èèyàn máa ń fún wa láyọ̀, àmọ́ ohun tó máa ń jẹ́ kí ayọ̀ wa túbọ̀ kún ni bá a ṣe ń rí i tí ojú àwọn tá à ń kọ́ lẹ́kọ̀ọ́ ń tàn yanran bí wọ́n ti ń kẹ́kọ̀ọ́ òtítọ́. (Òwe 15:23; Lúùkù 24:32) Bí akẹ́kọ̀ọ́ kan ṣe ń tẹ̀ síwájú, ó lè bẹ̀rẹ̀ sí í lo orúkọ Jèhófà, kó ṣàtúnṣe ìmúra àti ìrísí rẹ̀, kó jáwọ́ nínú àwọn àṣà tí kò tọ́, kó sì bẹ̀rẹ̀ sí í wàásù fún àwọn ẹlòmíì. Bó bá tẹ̀ síwájú tó sì ṣèrìbọmi, á wá di alábàáṣiṣẹ́ àti arákùnrin tàbí arábìnrin wa. Ìdùnnú wa ló máa jẹ́ bí ẹni tá à ń kọ́ lẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì bá gbé àwọn ìgbésẹ̀ wọ̀nyí.—1 Tẹs. 2:19, 20.

3. Àwọn ìgbésẹ̀ tó wúlò wo la lè gbé tá a bá fẹ́ bẹ̀rẹ̀ sí í kọ́ ẹnì kan lẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì?

3 Ǹjẹ́ Ìwọ Náà Lè Lọ́wọ́ Nínú Rẹ̀? Tó o bá fẹ́ máa lọ́wọ́ nínú iṣẹ́ tó gbádùn mọ́ni yìí, bẹ́ Jèhófà pé kó jẹ́ kó ṣeé ṣe fún ẹ láti máa darí ìkẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì, lẹ́yìn náà kó o ṣiṣẹ́ lórí àdúrà tó o bá gbà. (1 Jòh. 5:14) Máa wàásù níbi tó o bá ti lè rí àwọn èèyàn àti nígbà tó o bá lè rí wọn. Máa gbìyànjú láti bẹ̀rẹ̀ ìkẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì nígbàkigbà tí àyè rẹ̀ bá ṣí sílẹ̀. (Oníw. 11:6) Tó o bá pàdé ẹni tó fetí sí ọ̀rọ̀ rẹ̀, tó o sì gbin irúgbìn òtítọ́ sínú rẹ̀, pa dà lọ láti lọ bomi rin ín.—1 Kọ́r. 3:6-9.

4. Kí nìdí tí kò fi yẹ ká fi ọ̀rọ̀ bíbẹ̀rẹ̀ ìkẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì pẹ̀lú àwọn èèyàn falẹ̀?

4 Ọ̀kẹ́ àìmọye àwọn èèyàn ló ṣì wà tí ebi ń pa, tí òǹgbẹ òdodo sì ń gbẹ. Tá ló máa ràn wọ́n lọ́wọ́ láti pèsè àwọn nǹkan tí wọ́n ṣaláìní nípa tẹ̀mí fún wọn nípasẹ̀ kíkọ́ wọn lẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì? (Mát. 5:3, 6) Ẹ jẹ́ ká yọ̀ǹda ara wa tinútinú ká lè parí iṣẹ́ wíwàásù àti sísọni dọmọ ẹ̀yìn kí àkókò ìkórè tó kọjá lọ.—Aísá. 6:8.

    Yorùbá Publications (1987-2025)
    Jáde
    Wọlé
    • Yorùbá
    • Fi Ráńṣẹ́
    • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
    • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
    • Àdéhùn Nípa Lílò
    • Òfin
    • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
    • JW.ORG
    • Wọlé
    Fi Ráńṣẹ́