ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • mwb17 October ojú ìwé 3
  • Máa Kẹ́kọ̀ọ́ Jinlẹ̀ Nínú Ìwé Mímọ́

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

  • Máa Kẹ́kọ̀ọ́ Jinlẹ̀ Nínú Ìwé Mímọ́
  • Ìgbésí Ayé àti Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Àwa Kristẹni​—Ìwé Ìpàdé (2017)
  • Àpilẹ̀kọ Míì Tó Jọ ọ́
  • Jèhófà Ṣèlérí Èrè Àgbàyanu fún Dáníẹ́lì
    Kíyè sí Àsọtẹ́lẹ̀ Dáníẹ́lì
  • Ǹjẹ́ Ọlọ́run Bìkítà Nípa Rẹ?
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2011
  • Ìwé Dáníẹ́lì àti Ìwọ
    Kíyè sí Àsọtẹ́lẹ̀ Dáníẹ́lì
  • Dídá Àwọn Olùjọsìn Tòótọ́ mọ̀ ní Àkókò Òpin
    Kíyè sí Àsọtẹ́lẹ̀ Dáníẹ́lì
Àwọn Míì
Ìgbésí Ayé àti Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Àwa Kristẹni​—Ìwé Ìpàdé (2017)
mwb17 October ojú ìwé 3

MÁA HÙWÀ TÓ YẸ KRISTẸNI

Máa Kẹ́kọ̀ọ́ Jinlẹ̀ Nínú Ìwé Mímọ́

Ṣé ìwọ náà fẹ́ jẹ́ olóòótọ́ nígbà àdánwò bíi Dáníẹ́lì? Dáníẹ́lì kẹ́kọ̀ọ́ Ọ̀rọ̀ Ọlọ́run jinlẹ̀, títí kan àwọn àsọtẹ́lẹ̀ tó ta kókó. (Da 9:⁠2) Tó o bá ń kẹ́kọ̀ọ́ jinlẹ̀ nínú Bíbélì, báwo nìyẹn ṣe lè mú kó o jẹ́ olóòótọ́? Ó lè jẹ́ kó túbọ̀ dá ẹ lójú pé àwọn ìlérí Jèhófà máa ṣẹ. (Joṣ 23:14) Ó tún lè jẹ́ kó o túbọ̀ nífẹ̀ẹ́ Ọlọ́run, èyí á sì jẹ́ kó máa wù ẹ́ láti ṣe ohun tó tọ́. (Sm 97:10) Àmọ́, ibo ló yẹ kó o ti bẹ̀rẹ̀? Wo àwọn àbá yìí.

Dáníẹ́lì ń kẹ́kọ̀ọ́ Ọ̀rọ̀ Ọlọ́run
  • Àwọn nǹkan wo ni mo lè kẹ́kọ̀ọ́? Ọ̀kan pàtàkì lára ọ̀nà tó o lè máa gbà kẹ́kọ̀ọ́ ni pé kó o máa múra ìpàdé sílẹ̀. Wàá túbọ̀ máa gbádùn Bíbélì kíkà ọ̀sọ̀ọ̀sẹ̀ tó o bá ń wá àyè láti ṣèwádìí nípa àwọn nǹkan tí kò bá yé ẹ. Bákan náà, àwọn kan tún máa ń kẹ́kọ̀ọ́ nípa àwọn àsọtẹ́lẹ̀ Bíbélì, oríṣiríṣi apá tí èso tẹ̀mí pín sí, àwọn ibi tí àpọ́sítélì Pọ́ọ̀lù rìrìn-àjò míṣọ́nnárì dé tàbí àwọn ìṣẹ̀dá Jèhófà. Tí ìbéèrè kan bá wá sí ẹ lọ́kàn tó o sì fẹ́ ṣèwádìí nínú Bíbélì, kọ ọ́ sílẹ̀ kó o sì fi kún ará ohun tó o máa kẹ́kọ̀ọ́.

  • Ibo ni mo ti lè rí ìsọfúnni? Kó o lè mọ ohun tí wàá ṣe, wo fídíò náà Àwọn Ohun Tá A Lè Fi Ṣèwádìí Láti Rí Ìṣúra Tẹ̀mí. Bí àpẹẹrẹ, o lè dán ara rẹ wò, kó o ṣèwádìí nípa àwọn agbára ayé tí ọ̀kọ̀ọ̀kan àwọn ẹranko tó wà nínú Dáníẹ́lì orí ìkeje ń ṣàpẹẹrẹ.

  • Báwo ló ṣe yẹ kí àkókò tí mo fi ń kẹ́kọ̀ọ́ gùn tó? Tó o bá ń kẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì déédéé, àjọṣe rẹ pẹ̀lú Jèhófà á lágbára dáadáa. Tó o bá kọ́kọ́ bẹ̀rẹ̀, o lè máa lo àkókò díẹ̀, tó bá yá o lè máa fi kún àkókò tó o fi ń kẹ́kọ̀ọ́ díẹ̀díẹ̀. Ńṣe ni ìkẹ́kọ̀ọ́ Ọ̀rọ̀ Ọlọ́run dà bí ìgbà tí èèyàn ń wá àwọn ohun iyebíye lábẹ́ ilẹ̀; bí àwọn ohun iyebíye tó ò ń rí bá ṣe ń pọ̀ sí i, bẹ́ẹ̀ ni á ṣe máa wù ẹ́ tó láti túbọ̀ walẹ̀ jìn! (Owe 2:​3-6) Wàá túbọ̀ máa nífẹ̀ẹ́ Ọ̀rọ̀ Ọlọ́run, ìkẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì á sì di ohun tó o yàn láàyò.​—1Pe 2:2.

    O lè rí ìsọfúnni sí i nípa bó o ṣe lè túbọ̀ máa gbádùn ìkẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì nínú Jí! April 2012, ojú ìwé 14-16.

KÍ NI ÀWỌN ẸRANKO ẸHÀNNÀ INÚ DÁNÍẸ́LÌ ORÍ ÌKEJE DÚRÓ FÚN?

  • Ẹranko ẹhànnà tó rí bí kìnnìún tó ní ìyẹ́ apá idì

    Da 7:4

  • Ẹranko ẹhànnà tó rí bí béárì egungun ìhà mẹ́ta ní ẹnu rẹ̀

    Da 7:5

  • Ẹranko ẹhànnà tó rí bí àmọ̀tẹ́kùn tó ní orí mẹ́rin àti ìyẹ́ mẹ́rin ní ẹ̀yìn rẹ̀

    Da 7:6

  • Ẹranko kan tó ń bani lẹ́rù, tó sì ń jáni láyà tí ó ní eyín irin àti ìwo mẹ́wàá

    Da 7:7

ÀFIKÚN ÌBÉÈRÈ:

Báwo ni àsọtẹ́lẹ̀ tó wà ní Dáníẹ́lì 7:8, 24 ṣe ṣẹ?

Ìwo kékeré kan jáde wá tí ó ní ojú àti ẹnu, ó sì fa ìwo mẹ́ta tu

ÌKẸ́KỌ̀Ọ́ TÓ KÀN:

Kí ni àwọn ẹranko tó wà nínú Ìsípayá orí 13 ṣàpẹẹrẹ?

    Yorùbá Publications (1987-2025)
    Jáde
    Wọlé
    • Yorùbá
    • Fi Ráńṣẹ́
    • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
    • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
    • Àdéhùn Nípa Lílò
    • Òfin
    • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
    • JW.ORG
    • Wọlé
    Fi Ráńṣẹ́