Àwọn Ìtẹ̀jáde Tá A Tọ́ka sí Nínú Ìwé Ìpàdé Ìgbésí Ayé àti Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Àwa Kristẹni
NOVEMBER 13-19
ÀWỌN ÌṢÚRA INÚ Ọ̀RỌ̀ ỌLỌ́RUN | ỌBADÁYÀ 1–JÓNÀ 4
“Kẹ́kọ̀ọ́ Nínú Àwọn Àṣìṣe Rẹ”
Àwọn Kókó Pàtàkì Látinú Ìwé Ọbadáyà, Ìwé Jónà, àti Ìwé Míkà
10—Báwo la ṣe “ké [Édómù] kúrò fún àkókò tí ó lọ kánrin?” Gẹ́gẹ́ bó ṣe wà nínú àsọtẹ́lẹ̀ yẹn, orílẹ̀-èdè Édómù, tó ní ìjọba tirẹ̀ àti ibi pàtó táwọn èèyàn rẹ̀ ń gbé láyé, di èyí tí kò sí mọ́. Nábónídọ́sì tó jẹ́ ọba Bábílónì ṣẹ́gun Édómù ní nǹkan bí ìdajì ọ̀rúndún kẹfà ṣáájú Sànmánì Kristẹni. Nígbà tó fi máa di ọ̀rúndún kẹrin ṣáájú Sànmánì Kristẹni, àgbègbè tó jẹ́ ti àwọn ará Édómù wá di ibi táwọn ará Nabataea ń gbé, àwọn ará Édómù sì ní láti lọ máa gbé lápá gúúsù ilẹ̀ Jùdíà, ìyẹn àgbègbè Négébù tó wá di Ídúmíà nígbà tó yá. Ẹ̀yìn ìgbà táwọn ará Róòmù pa ìlú Jerúsálẹ́mù run lọ́dún 70 Sànmánì Kristẹni làwọn ará Édómù dẹni tí kò sí mọ́.
NOVEMBER 20-26
ÀWỌN ÌṢÚRA INÚ Ọ̀RỌ̀ ỌLỌ́RUN | MÍKÀ 1-7
“Kí Ni Jèhófà Ń Béèrè Lọ́wọ́ Wa?”
Báwo Ló Ṣe Yẹ Ká Máa Ṣe Sáwọn Èèyàn?
20 Lójú Ọlọ́run, níní àjọṣe tó dán mọ́rán pẹ̀lú àwọn ará wa jẹ́ apá pàtàkì ìjọsìn tòótọ́. Táwọn èèyàn bá ń fi ẹran rúbọ, àmọ́ tí wọn ò ṣe dáadáa sáwọn èèyàn bíi tiwọn, irú ẹbọ bẹ́ẹ̀ kò ṣètẹ́wọ́gbà lọ́dọ̀ Jèhófà. (Míkà 6:6-8) Ìdí nìyẹn tí Jésù fi rọ àwọn ọmọ ẹ̀yìn rẹ̀ pé kí wọ́n “bẹ̀rẹ̀ sí yanjú àwọn ọ̀ràn ní kíákíá.” (Mát. 5:25) Pọ́ọ̀lù sọ ohun kan tó jọ bẹ́ẹ̀, ó ní: “Ẹ fi ìrunú hàn, síbẹ̀ kí ẹ má ṣẹ̀; ẹ má ṣe jẹ́ kí oòrùn wọ̀ bá yín nínú ipò ìbínú, bẹ́ẹ̀ ni kí ẹ má ṣe fi àyè sílẹ̀ fún Èṣù.” (Éfé. 4:26, 27) Tẹ́nì kan bá ṣe nǹkan kan fún wa tó yẹ ká torí ẹ̀ bínú, ó yẹ ká tètè yanjú ọ̀rọ̀ náà kíákíá kó má bàa di pé ìbínú yẹn pẹ́ nínú wa ká sì tipa bẹ́ẹ̀ gba Èṣù láyè.—Lúùkù 17:3, 4.
Àwọn Kókó Pàtàkì Látinú Ìwé Ọbadáyà, Ìwé Jónà, àti Ìwé Míkà
2:12—Ìgbà wo ni àsọtẹ́lẹ̀ nípa ‘kíkó àwọn tí ó ṣẹ́ kù nínú Ísírẹ́lì jọpọ̀’ nímùúṣẹ? Ọdún 537 ṣáájú Sànmánì Kristẹni ni àsọtẹ́lẹ̀ yìí kọ́kọ́ nímùúṣẹ nígbà táwọn Júù tó ṣẹ́ kù nígbèkùn Bábílónì padà sí ìlú wọn. Lóde òní, àsọtẹ́lẹ̀ yìí tún ń nímùúṣẹ sára àwọn “Ísírẹ́lì Ọlọ́run.” (Gálátíà 6:16) Látọdún 1919 ni Ọlọ́run ti ń kó àwọn Kristẹni ẹni àmì òróró jọpọ̀ “bí agbo ẹran nínú ọgbà ẹran.” Níwọ̀n bí “ogunlọ́gọ̀ ńlá” tó jẹ́ “àwọn àgùntàn mìíràn” ti ń dara pọ̀ mọ́ wọn, pàápàá látọdún 1935, “ariwo” wọn wá pọ̀ gan-an. (Ìṣípayá 7:9; Jòhánù 10:16) Gbogbo wọn jọ ń fi tọkàntara ṣètìlẹ́yìn fún ìjọsìn tòótọ́.
Kí Ni Jèhófà Ń Retí Pé Ká Máa Ṣe?
20 Ìbùkún Jèhófà tá à ń rí gbà ń mú ká fara wé irú ẹ̀mí tí Míkà ní. Ó sọ pé: “Dájúdájú, èmi yóò fi ẹ̀mí ìdúródeni hàn sí Ọlọ́run ìgbàlà mi.” (Míkà 7:7) Báwo lọ̀rọ̀ yìí ṣe kan ọ̀ràn pé ká máa fi ìmẹ̀tọ́mọ̀wà bá Ọlọ́run rìn? Níní ẹ̀mí ìdúródeni tàbí ẹ̀mí sùúrù yóò ràn wá lọ́wọ́ láti yẹra fún níní ìrẹ̀wẹ̀sì pé ọjọ́ Jèhófà kò tíì dé títí di báyìí. (Òwe 13:12) Ká sòótọ́ gbogbo wa là ń fẹ́ kí òpin ayé burúkú yìí ti dé. Àmọ́, ọ̀sọ̀ọ̀sẹ̀ là ń rí ẹgbẹẹgbẹ̀rún èèyàn tó ṣẹ̀ṣẹ̀ bẹ̀rẹ̀ sí bá Ọlọ́run rìn. Èyí ló wá jẹ́ ká rí ìdí tó fi yẹ ká lẹ́mìí ìdúródeni. Ẹlẹ́rìí kan tó pẹ́ tó ti wà lẹ́nu iṣẹ́ yìí sọ nípa èyí pé: “Bí mo ṣe ń fojú inú wo ohun tó lé ní ọdún márùndínlọ́gọ́ta tí mo ti fi ṣe iṣẹ́ ìwàásù, ó dá mi lójú pé mi ò pàdánù ohunkóhun nítorí dídúró tí mò ń dúró de Jèhófà. Kàkà bẹ́ẹ̀, ńṣe ló jẹ́ kí n bọ́ lọ́wọ́ onírúurú ìdààmú ọkàn.” Ṣé bó ṣe rí fún ìwọ náà nìyẹn?
NOVEMBER 27–DECEMBER 3
ÀWỌN ÌṢÚRA INÚ Ọ̀RỌ̀ ỌLỌ́RUN | NÁHÚMÙ 1–HÁBÁKÚKÙ 3
“Wà Lójúfò Kó O sì Máa Bá Iṣẹ́ Ìsìn Rẹ sí Jèhófà Lọ”
Àwọn Kókó Pàtàkì Látinú Ìwé Náhúmù, Hábákúkù àti Sefanáyà
2:1. Bíi ti Hábákúkù, àwa náà ní láti wà lójúfò ká sì máa bá iṣẹ́ ìsìn wa sí Jèhófà lọ. A ní láti múra tán láti tún èrò wa ṣe tẹ́nì kan bá ‘fi ìbáwí tọ́ wa sọ́nà’ tàbí tó fi ibi tá a ti nílò àtúnṣe hàn wá.
2:3; 3:16. Bá a ṣe ń fìgbàgbọ́ dúró de ọjọ́ Jèhófà, ẹ má ṣe jẹ́ ká dẹwọ́ lẹ́nu iṣẹ́ ìsìn wa.
2:4. Láti lè la ọjọ́ ìdájọ́ Jèhófà tó ń bọ̀ já, a gbọ́dọ̀ máa bá ìṣòtítọ́ nìṣó.—Hébérù 10:36-38.