ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • mwb21 January ojú ìwé 5
  • Ṣe Ohun Tá Jẹ́ Kí Ìgbéyàwó Rẹ Lágbára Sí I

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

  • Ṣe Ohun Tá Jẹ́ Kí Ìgbéyàwó Rẹ Lágbára Sí I
  • Ìgbésí Ayé àti Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Kristẹni—Ìwé Ìpàdé—2021
  • Àpilẹ̀kọ Míì Tó Jọ ọ́
  • Ohun Táá Jẹ́ Kí Tọkọtaya Bára Wọn Kalẹ́
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa (Ẹ̀dà Tó Wà fún Ìkẹ́kọ̀ọ́)—2016
  • Bí Ìgbéyàwó Bá Wà ní Bèbè Àtitúká
    Àṣírí Ayọ̀ Ìdílé
  • Ohun Tí Bíbélì Sọ
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2013
  • Jẹ́ Kí Ayọ̀ Wà Nínú Ilé Rẹ
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2008
Àwọn Míì
Ìgbésí Ayé àti Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Kristẹni—Ìwé Ìpàdé—2021
mwb21 January ojú ìwé 5
Ọkọ kan jókòó ti ìyàwó ẹ̀, inú wọn sì ń dùn bí wọ́n ṣe jọ ń fọṣọ.

MÁA HÙWÀ TÓ YẸ KRISTẸNI

Ṣe Ohun Tá Jẹ́ Kí Ìgbéyàwó Rẹ Lágbára Sí I

Jèhófà ò fọwọ́ kékeré mú ẹ̀jẹ́ ìgbéyàwó. Ó sọ pé àwọn tọkọtaya gbọ́dọ̀ ṣe ara wọn lọ́kan. (Mt 19:5, 6) Láàárín àwa èèyàn Ọlọ́run, ọ̀pọ̀ tọkọtaya ló ń fi àpẹẹrẹ tó dáa lélẹ̀. Àmọ́ ìyẹn ò sọ pé irú àwọn ẹni bẹ́ẹ̀ ò níṣòro nínú ìgbéyàwó wọn, torí kò sí ìgbéyàwó tó dáa tán. Tí ìṣòro bá dé, àwọn kan gbà pé ìpínyà tàbí ìkọ̀sílẹ̀ ló máa yanjú ìṣòro náà, àmọ́ àwa Kristẹni ò gbọ́dọ̀ gba irú èrò bẹ́ẹ̀ láyè. Kí ni tọkọtaya lè ṣe láti mú kí ìgbéyàwó wọn lágbára sí i?

Ohun márùn-ún yìí ṣe pàtàkì.

  1. Má ṣe máa tage pẹ̀lú ẹni tí kì í ṣe ọkọ tàbí aya rẹ, bákàn náà yẹra fún eré ìnàjú tó lè gbé ìṣekúṣe sí ẹ lọ́kàn, torí wọ́n lè ṣàkóbá fún ìgbéyàwó rẹ.​—Mt 5:28; 2Pe 2:14.

  2. Jẹ́ kí àjọṣe rẹ pẹ̀lú Ọlọ́run túbọ̀ máa lágbára sí i, kó o sì pinnu pé wàá túbọ̀ máa ṣe ohun tí Ọlọ́run fẹ́.​—Sm 97:10.

  3. Máa sapá kí ìwà ẹ lè dáa sí i, kó o sì máa ṣe àwọn nǹkan kéékèèké láti ran ẹnì kejì rẹ lọ́wọ́.​—Kol 3:8-10, 12-14.

  4. Ẹ máa bá ara yín sọ̀rọ̀ déédéé, kẹ́ ẹ sì máa ṣe bẹ́ẹ̀ tọ̀wọ̀tọ̀wọ̀.​—Kol 4:6.

  5. Máa fìfẹ́ hàn sí ẹnì kejì rẹ déédéé, má sì máa ro tara ẹ nìkan tó bá dọ̀rọ̀ ìbálòpọ̀.​—1Kọ 7:3, 4; 10:24.

Bí àwa Kristẹni ṣe ń fọwọ́ pàtàkì mú ìgbéyàwó, ṣe là ń bọ̀wọ̀ fún Jèhófà tó dá ìgbéyàwó sílẹ̀.

WO FÍDÍÒ NÁÀ A GBỌ́DỌ̀ ‘FI ÌFARADÀ SÁRÉ’​—MÁA TẸ̀ LÉ ÒFIN ERÉ SÍSÁ, KÓ O SÌ DÁHÙN ÀWỌN ÌBÉÈRÈ YÌÍ:

  • Àwòrán látinú fídíò ‘A Gbọ́dọ̀ ‘Fi Ìfaradà Sáré’​—Máa Tẹ̀ Lé Òfin Eré Sísá.’ Arákùnrin àti arábìnrin Calou ń rẹ́rìn-ín músẹ́ lọ́jọ́ ìgbéyàwó wọn.

    Bó tiẹ̀ jẹ́ pé ìgbéyàwó lè dùn níbẹ̀rẹ̀, àwọn ìṣòro wo ló ṣì lè yọjú?

  • Àwòrán látinú fídíò ‘A Gbọ́dọ̀ ‘Fi Ìfaradà Sáré’​—Máa Tẹ̀ Lé Òfin Eré Sísá.’ Arákùnrin àti arábìnrin Calou ń fara balẹ̀ sọ̀rọ̀ nípa bí wọ́n ṣe máa yanjú ìṣòro tí wọ́n ní. Wọ́n sì ṣí Bíbélì sílẹ̀ lórí tábìlì.

    Báwo ni ìlànà Bíbélì ṣe lè ran tọkọtaya lọ́wọ́ tó bá ń ṣe wọ́n bíi pé wọn ò nífẹ̀ẹ́ ara wọn mọ́?

  • Àwòrán látinú fídíò ‘A Gbọ́dọ̀ ‘Fi Ìfaradà Sáré’​—Máa Tẹ̀ Lé Òfin Eré Sísá.’ Arákùnrin Calou ń ka ‘Ìwé Ìtàn Bíbélì’ fún àwọn ọmọ àti ìyàwó ẹ̀.

    Máa fi àwọn ìlànà Bíbélì sílò kí ìgbéyàwó rẹ lè láyọ̀

    Àwọn ìlànà wo ni Jèhófà fẹ́ kí tọkọtaya máa tẹ̀ lé?

  • Kí ìgbéyàwó tó lè láyọ̀, kí ni tọkọtaya gbọ́dọ̀ máa ṣe?

    Yorùbá Publications (1987-2025)
    Jáde
    Wọlé
    • Yorùbá
    • Fi Ráńṣẹ́
    • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
    • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
    • Àdéhùn Nípa Lílò
    • Òfin
    • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
    • JW.ORG
    • Wọlé
    Fi Ráńṣẹ́