MÁA HÙWÀ TÓ YẸ KRISTẸNI
À Ń Fìfẹ́ Hàn Láwọn Àpéjọ Tá À Ń Ṣe Lọ́dọọdún
A máa ń gbádùn àwọn àpéjọ wa ọdọọdún gan-an. Kí nìdí tó fi rí bẹ́ẹ̀? Ìdí ni pé, bíi tàwọn ọmọ Ísírẹ́lì àtijọ́, àwọn àpéjọ tá à ń ṣe lóde òní máa ń jẹ́ ká lè jọ́sìn Jèhófà pa pọ̀ pẹ̀lú ọ̀pọ̀ àwọn ara wa. A máa ń kẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì níbẹ̀, èyí sì ń jẹ́ ká túbọ̀ sún mọ́ Jèhófà. A tún máa ń gbádùn àkókò alárinrin pẹ̀lú àwọn ọ̀rẹ́ àtàwọn ẹbí wa. Torí pé a mọrírì àpéjọ yìí gan-an, a máa ń ríi pé a ò pa ọjọ́ kankan jẹ.
Tá a bá wà nírú àpéjọ bẹ́ẹ̀, ó yẹ ká máa ronú nípa bá a ṣe máa fìfẹ́ hàn sáwọn míì, kó má jẹ́ tara wa nìkan làá máa rò. (Ga 6:10; Heb 10:24, 25) Tá a bá di ilẹ̀kùn mú fún arákùnrin tàbí arábìnrin kan, tó sì jẹ́ pé àyè ìjókòó tá a nílò nìkan la gbà sílẹ̀, ṣe là ń fi hàn pé ire àwọn míì là ń wá. (Flp 2:3, 4) A tún máa ń ní àwọn ọ̀rẹ́ tuntun láwọn àpéjọ wa. Kí ìpàdé tó bẹ̀rẹ̀, lẹ́yìn típàdé bá parí tàbí lásìkò ìsinmi, a lè bá àwọn tá ò mọ̀ rí sọ̀rọ̀ ká lè túbọ̀ mọ̀ wọ́n dáadáa. (2Kọ 6:13) Irú àwọn ẹni bẹ́ẹ̀ lè wá di ọ̀rẹ́ wa tímọ́tímọ́, tí àá sì jọ wà títí láé! Ju gbogbo ẹ̀ lọ, táwọn míì bá rí bá a ṣe ń fìfẹ́ tòótọ́ hàn síra wa, àwọn náà lè pinnu láti wá sin Jèhófà.—Jo 13:35.
WO FÍDÍÒ NÁÀ ÀPÉJỌ ÀGBÁYÉ “ÌFẸ́ KÌ Í YẸ̀ LÁÉ”! KÓ O SÌ DÁHÙN ÀWỌN ÌBÉÈRÈ YÌÍ:
Báwo làwọn ará ṣe fìfẹ́ hàn sáwọn àlejò tó wá láti orílẹ̀-èdè míì nígbà àpéjọ àgbáyé ọdún 2019?
Kí nìdí tí ìfẹ́ àti ìṣọ̀kan tó wà láàárín àwa èèyàn Jèhófà fi ṣàrà-ọ̀tọ̀?
Àwọn nǹkan wo la lè ṣe láti túbọ̀ máa fìfẹ́ hàn táwọn tó wà nínú Ìgbìmọ̀ Olùdarí mẹ́nu kàn?
Báwo nìwọ náà ṣe lè máa fìfẹ́ hàn láwọn àpéjọ wa?
Báwo làwọn ará ṣe fi hàn pé wọ́n nífẹ̀ẹ́ ara wọn lórílẹ̀-èdè Jámánì àti South Korea?
Kí la pinnu láti túbọ̀ máa ṣe?