ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • g 7/08 ojú ìwé 31
  • Kí Ni Ìdáhùn Rẹ?

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

  • Kí Ni Ìdáhùn Rẹ?
  • Jí!—2008
  • Ìsọ̀rí
  • Àpilẹ̀kọ Míì Tó Jọ ọ́
  • Kí Ni Àlá Náà Túmọ̀ Sí?
  • Nínú Ìtẹ̀jáde Yìí
  • Àwọn Wo Ló Wà Lára Ìdílé Jésù?
  • ÌDÁHÙN SÍ ÌBÉÈRÈ
  • Kí Ni Ìdáhùn Rẹ?
    Jí!—2008
  • Kí Ni Ìdáhùn Rẹ?
    Jí!—2009
  • Bí Sódómù àti Gòmórà Ṣe Pa Run
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2008
  • Àtúnyẹ̀wò fún Ìdílé
    Jí!—2010
Àwọn Míì
Jí!—2008
g 7/08 ojú ìwé 31

Kí Ni Ìdáhùn Rẹ?

Kí Ni Àlá Náà Túmọ̀ Sí?

Ka Dáníẹ́lì 2:25-45, kó o sì dáhùn àwọn ìbéèrè tó tẹ̀ lé e yìí.

1. Àwọn mẹ́táàlì mẹ́rin wo ni wọ́n fi ṣe ère náà?

․․․․․

․․․․․

․․․․․

․․․․․

2. Kí ni àwọn mẹ́táàlì náà dúró fún?

․․․․․

3. Kí ló ṣẹlẹ̀ sí ère náà?

․․․․․

4. Kí ló rọ́pò ère náà, báwo sì làkókò tó fi rọ́pò rẹ̀ ṣe gùn tó?

․․․․․

․․․․․

FÚN ÌJÍRÒRÒ:

Báwo ni àkọsílẹ̀ yìí ṣe fi hàn pé Dáníẹ́lì jẹ́ ẹni tó mọ̀wọ̀n ara ẹ̀? Bó o bá mọ iṣẹ́ kan dáadáa tàbí tó o ní àwọn ẹ̀bùn kan, kí nìdí tó fi yẹ kó o mọ̀wọ̀n ara ẹ?

Nínú Ìtẹ̀jáde Yìí

Dáhùn àwọn ìbéèrè wọ̀nyí, kó o sì kọ (àwọn) ẹsẹ Bíbélì tó yẹ sínú àlàfo.

OJÚ ÌWÉ 8 Kí ni tọkọtaya gbọ́dọ̀ yẹra fún? Éfésù 4:․․․

OJÚ ÌWÉ 9 Kí ló yẹ kí tọkọtaya máa mójú tó? Fílípì 2:․․․

OJÚ ÌWÉ 15 Kí ni ohun tí Ọlọ́run sọ pé káwọn ìránṣẹ́ òun má ṣe? Diutarónómì 18:․․․

OJÚ ÌWÉ 25 Bí ọ̀dọ́ kan kì í bá ṣe olùgbọ́ nìkan, àmọ́ tó tún jẹ́ olùṣe ọ̀rọ̀ náà, kí ló máa ní? Jákọ́bù 1:․․․

Àwọn Wo Ló Wà Lára Ìdílé Jésù?

Kọ́kọ́ wo ohun tá a kọ síwájú amọ̀nà. Ka ẹsẹ Ìwé Mímọ́ tá a tọ́ka sí. Lẹ́yìn náà, kọ orúkọ tó tọ̀nà sínú àlàfo.

5. ․․․․․

AMỌ̀NÀ: Ọmọ, ọmọ mi ni ọba kejì nílẹ̀ Ísírẹ́lì.

Ka 1 Sámúẹ́lì 16:13, 14; 1 Kíróníkà 2:12-15.

6. ․․․․․

AMỌ̀NÀ: Aísáyà sọ àsọtẹ́lẹ̀ pé ọ̀kan lára àwọn àtọmọdọ́mọ mi yóò ‘dìde dúró gẹ́gẹ́ bí àmì àfiyèsí fún àwọn ènìyàn.’

Ka Aísáyà 11:10.

7. ․․․․․

AMỌ̀NÀ: Àwọn èèyàn mọ̀ pé mo máa ń ṣe àwọn ohun èlò orin.

Ka 2 Kíróníkà 7:6.

ÌDÁHÙN SÍ ÌBÉÈRÈ

1. Wúrà, fàdákà, bàbà, irin.

2. Ìjọba mẹ́rin.

3. A rún un wómúwómú.

4. Ìjọba Ọlọ́run; yóò wà fún àkókò tí ó lọ kánrin.

5. Óbédì.—Lúùkù 3:31, 32.

6. Jésè.—Lúùkù 3:32.

7. Dáfídì.—Lúùkù 3:31.

    Yorùbá Publications (1987-2025)
    Jáde
    Wọlé
    • Yorùbá
    • Fi Ráńṣẹ́
    • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
    • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
    • Àdéhùn Nípa Lílò
    • Òfin
    • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
    • JW.ORG
    • Wọlé
    Fi Ráńṣẹ́