ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • g19 No. 2 ojú ìwé 12-13
  • Ìmọ̀ràn Àgbàlagbà Ṣe Pàtàkì

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

  • Ìmọ̀ràn Àgbàlagbà Ṣe Pàtàkì
  • Jí!—2019
  • Ìsọ̀rí
  • Àpilẹ̀kọ Míì Tó Jọ ọ́
  • ÌMỌ̀RÀN ÀGBÀLAGBÀ
  • KÍ NÌDÍ TÍ ÌMỌ̀RÀN ÀGBÀLAGBÀ FI ṢE PÀTÀKÌ?
  • BÓ O ṢE LÈ TỌ́ ỌMỌ RẸ SỌ́NÀ
  • Bí Àwọn Òbí Ṣe Lè Tọ́ Àwọn Ọmọ Sọ́nà
    Ìrànlọ́wọ́ fún Ìdílé
  • Bí Àwọn Òbí Ṣe Lè Ṣèrànwọ́ Fún Àwọn Ọmọ Wọn Tó Ti Bàlágà
    Jí!—2011
  • Ìmọ̀ràn Tó Ṣeé Gbára Lé Lórí Ọ̀rọ̀ Ọmọ Títọ́
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2006
  • Àwọn Ìbéèrè Tí Àwọn Òbí Ń Béèrè
    Àwọn Ìbéèrè Tí Àwọn Ọ̀dọ́ Ń Béèrè—Àwọn Ìdáhùn Tí Ó Gbéṣẹ́, Apá Kìíní
Àwọn Míì
Jí!—2019
g19 No. 2 ojú ìwé 12-13
Obìnrin kan ń fí fọ́tò rẹ̀ àtijọ́ han ọmọbìnrin kan

Ẹ̀KỌ́ 5

Ìmọ̀ràn Àgbàlagbà Ṣe Pàtàkì

ÌMỌ̀RÀN ÀGBÀLAGBÀ

Àwọn ọmọ nílò ìtọ́sọ́nà àti ìmọ̀ràn àgbàlagbà kí ayé wọn lè lójú. Ìwọ tó o jẹ́ òbí wọn lo sì wà ní ipò tó dáa jù láti fún wọn ní ìmọ̀ràn kó o sì tọ́ wọn sọ́nà, ojúṣe rẹ ni. Àmọ́, àwọn àgbàlagbà míì náà tún lè fún ọmọ rẹ ní ìmọ̀ràn.

KÍ NÌDÍ TÍ ÌMỌ̀RÀN ÀGBÀLAGBÀ FI ṢE PÀTÀKÌ?

Ní ọ̀pọ̀ orílẹ̀-èdè, àwọn ọ̀dọ́ kì í fi bẹ́ẹ̀ lo àkókò pẹ̀lú àwọn àgbàlagbà. Bí àpẹẹrẹ:

  • Ilé ìwé làwọn ọmọdé ti sábà máa ń lo àkókò wọn jù, kò sì fi bẹ́ẹ̀ sí àwọn àgbàlagbà nílé ìwé.

  • Lọ́pọ̀ ìgbà táwọn ọmọ bá fi máa pa dà sílé, wọn kì í dé bá ẹnikẹ́ni torí pé àwọn òbí wọn ti lọ síbi iṣẹ́.

  • Ìwádìí kan tí wọ́n ṣe lórílẹ̀-èdè Amẹ́ríkà fi hàn pé àwọn ọmọ tí ọjọ́ orí wọn wà ní ọdún mẹ́jọ sí méjìlá sábà máa ń lo nǹkan bí wákàtí mẹ́fà lójoojúmọ́ nídìí tẹlifísọ̀n, orin tàbí géèmù.a

Ìwé kan tó ń jẹ́ Hold On to Your Kids sọ pé: “Kàkà kí àwọn ọ̀dọ́ máa wá ìmọ̀ràn àti ìtọ́ni lọ sọ́dọ̀ ìyá wọn, bàbá wọn àti olùkọ́ wọn tàbí àgbàlagbà míì, ọ̀dọ̀ àwọn ọ̀dọ́ bíi tiwọn ni wọ́n ti ń gbàmọ̀ràn.”

BÓ O ṢE LÈ TỌ́ ỌMỌ RẸ SỌ́NÀ

Lo àkókò pẹ̀lú àwọn ọmọ rẹ.

ÌLÀNÀ BÍBÉLÌ: “Tọ́ ọmọdé ní ọ̀nà tó yẹ kó tọ̀; kódà tó bá dàgbà, kò ní kúrò nínú rẹ̀.”​—Òwe 22:6, àlàyé ìsàlẹ̀ ìwé.

Lọ́pọ̀ ìgbà, àwọn ọmọ máa ń fẹ́ kí àwọn òbí wọn tọ́ wọn sọ́nà. Kódà, àwọn olùṣèwádìí sọ pé tí àwọn ọmọ bá ti ń sún mọ́ ìgbà ọ̀dọ́, wọ́n máa ń fẹ́ gba ìmọ̀ràn àwọn òbí wọn dípò tàwọn ẹgbẹ́ wọn. Dr. Laurence Steinberg tiẹ̀ sọ nínú ìwé You and Your Adolescent pé: “Àwọn òbí máa ń nípa tó lágbára lórí ìwà táwọn ọmọ wọn ń hù láti ìgbà èwe títí dé ìgbà ọ̀dọ́.” Ó tún sọ pé: “Àwọn ọ̀dọ́ máa ń fẹ́ mọ èrò àwọn òbí wọn kódà tí wọ́n ò bá tiẹ̀ ṣe tán láti tẹ̀ lé ohun tí wọn bá sọ.”

Ní báyìí tí ọmọ ẹ ń wojú rẹ fún ìmọ̀ràn, lo àǹfààní yìí láti tọ́ ọ sọ́nà. Lo àkókò pẹ̀lú ọmọ rẹ, máa sọ èrò rẹ fún un, jẹ́ kó mọ àwọn ohun tó ṣe pàtàkì, kó o sì sọ àwọn ohun tí ojú ẹ ti rí àtàwọn ẹ̀kọ́ tó o ti kọ́.

Yan ọ̀rẹ́ kan tó jẹ́ àgbàlagbà fún ọmọ rẹ.

ÌLÀNÀ BÍBÉLÌ: “Ẹni tó ń bá ọlọ́gbọ́n rìn yóò gbọ́n.” ​—Òwe 13:20.

Ṣé o mọ ẹnì kan tó níwà àgbà, tó máa ń fúnni nímọ̀ràn tó dára, tó sì lè jẹ́ àpẹẹrẹ rere fún ọmọ rẹ? Ó máa dáa kó o ṣètò fún ọmọ rẹ láti máa lo àkókò díẹ̀ pẹ̀lú ẹni náà. Ìyẹn ò túmọ̀ sí pé o gbé ojúṣe rẹ gẹ́gẹ́ bí òbí fún ẹlòmíì. Kàkà bẹ́ẹ̀, àfikún ni ìmọ̀ràn tí ẹni náà bá ń fún ọmọ rẹ máa jẹ́ sí ẹ̀kọ́ tó ò ń kọ́ ọ. Ọ̀kan lára àwọn tó ní irú àǹfààní yẹn nínú Bíbélì ni Tímótì. Bó tilẹ̀ jẹ́ pé ọ̀dọ́ ni, ó jàǹfààní nínú àjọṣe tó ní pẹ̀lú Pọ́ọ̀lù, bákan náà Pọ́ọ̀lù jàǹfààní nínú bó ṣe bá Tímótì ṣọ̀rẹ́.​—Fílípì 2:20, 22.

Nígbà àtijọ́, ọ̀pọ̀ ìdílé máa ń gbé pa pọ̀, àmọ́ ní báyìí kò rí bẹ́ẹ̀ mọ́ torí pé ọ̀pọ̀ àwọn òbí, òbí àgbà àtàwọn mọ̀lẹ́bí míì ń gbé níbi tó jìnnà síra. Tó bá jẹ́ pé bẹ́ẹ̀ lọ̀rọ̀ tìẹ rí, ran ọmọ rẹ lọ́wọ́ láti kẹ́kọ̀ọ́ lára àwọn tó ní irú ìwà tí wàá fẹ́ kí ọmọ rẹ ní.

a Ìwádìí yẹn fi hàn pé, àwọn ọ̀dọ́ ní tiwọn máa ń lo nǹkan bí wákàtí mẹ́sàn-án lójoojúmọ́ nídìí tẹlifísọ̀n, orin tàbí géèmù. Èyí kò sí lára àkókò tí wọ́n ń lò lórí ìkànnì nílé ìwé tàbí fún iṣẹ́ ilé ìwé wọn.

Obìnrin kan ń fí fọ́tò rẹ̀ àtijọ́ han ọmọbìnrin kan

TÈTÈ BẸ̀RẸ̀ SÍ Í KỌ́ ỌMỌ RẸ

Ọmọ tó bá ń gba ìmọ̀ràn látọ̀dọ̀ àwọn àgbàlagbà sábà máa ń hùwà ọgbọ́n, ó sì máa ń ṣeé gbára lé tó bá dàgbà

Jẹ́ Àpẹẹrẹ Rere

  • Ṣé mo jẹ́ àpẹẹrẹ rere fún àwọn ọmọ mi?

  • Ṣé àwọn ọmọ mi mọ̀ mí sí ẹni tó máa ń gba ìmọ̀ràn lọ́wọ́ àwọn tó dàgbà jù mí lọ?

  • Ṣé àkókò tí mò ń lò pẹ̀lú àwọn ọmọ mi fi hàn pé mo nífẹ̀ẹ́ wọn, ọ̀rọ̀ wọn sì jẹ mí lọ́kàn?

Ohun Tá A Ṣe . . .

“Nígbà míì tí ọwọ́ mi bá dí, ọmọbìnrin mi á sọ fún mi pé òun fẹ́ bá mi sọ̀rọ̀. Mo máa ń fẹ́ tẹ́tí sílẹ̀ sí i, kódà tó bá gba pé kí n sọ fún un pé kó fún mi ní ìṣẹ́jú díẹ̀ kí n lè fara balẹ̀ gbọ́ ohun tó fẹ́ bá mi sọ. Èmi àti ìyàwó mi náà máa ń fi àpẹẹrẹ rere lélẹ̀, kó ba lè mọ̀ pé ohun tá à ń kọ́ ọ làwa náà ń ṣe.”​—David.

“Nígbà tí a bí ọmọbìnrin wa, èmi àti ọkọ mi pinnu pé màá máa tọ́ ọmọ wa nílé, mi ò sì ní ṣiṣẹ́. Mi ò kábàámọ̀ ìpinnu tá a ṣe yẹn. Ó ṣe pàtàkì gan-an láti lo àkókò púpọ̀ pẹ̀lú ọmọ téèyàn ń tọ́, kéèyàn bàa lè mójú tó o, kó sì lè tọ́ ọ sọ́nà. Pàtàkì ibẹ̀ ni pé, tó o bá ń ṣe bẹ́ẹ̀ ìyẹn á fi hàn pé o nífẹ̀ẹ́ ọmọ rẹ.”​—Lisa.

JẸ́ KÍ ÀWỌN ỌMỌ RẸ MÁA LO ÀKÓKÒ PẸ̀LÚ ÀWỌN ÀGBÀLAGBÀ

“Àárín àwọn àgbàlagbà tí ọjọ́ orí àti ìwà wọn yàtọ̀ síra làwọn ọmọ mi dàgbà sí, èyí sì ti jẹ́ kí wọ́n kẹ́kọ̀ọ́ lára ọ̀pọ̀ èèyàn. Bí àpẹẹrẹ, ó yà wọ́n lẹ́nu nígbà tí ìyá mi àgbà sọ fún wọn pé nígbà táwọn ṣì kéré, ìdílé àwọn ló kọ́kọ́ ní iná mànàmáná. Wọ́n tún sọ fún àwọn ọmọ mi pé àwọn aládùúgbò àwọn sábà máa ń wá sí ilé àwọn láti wá wo bí wọ́n ṣe ń tan iná náà àti bí wọ́n ṣe ń pa á. Ìtàn yẹn ti jẹ́ káwọn ọmọ mi rí bí nǹkan ṣe rí láyé ìgbà yẹn. Yàtọ̀ síyẹn, àwọn ọ̀rọ̀ tí wọ́n ń gbọ́ lẹ́nu ìyá àgbà ti jẹ́ kí wọ́n túbọ̀ bọ̀wọ̀ fún wọn àti fún àwọn àgbàlagbà míì. Ìyẹn fi hàn pé táwọn ọmọdé bá ń lo àkókò tó pọ̀ pẹ̀lú àwọn àgbàlagbà ju èyí tí wọ́n ń lò pẹ̀lú àwọn ẹgbẹ́ wọn lọ, ọ̀pọ̀ ẹ̀kọ́ tó máa ṣe wọ́n láǹfààní ni wọ́n máa kọ́.”​—Maranda.

    Yorùbá Publications (1987-2025)
    Jáde
    Wọlé
    • Yorùbá
    • Fi Ráńṣẹ́
    • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
    • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
    • Àdéhùn Nípa Lílò
    • Òfin
    • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
    • JW.ORG
    • Wọlé
    Fi Ráńṣẹ́